< Zechariah 10 >

1 Ask ye from Yahweh rain, in the time of the latter rain, Yahweh, who causeth flashes of lightning, —and, rain in abundant showers, giveth he unto them, to every man, herbage in the field;
Ẹ béèrè òjò nígbà àrọ̀kúrò ni ọwọ́ Olúwa; Olúwa tí o dá mọ̀nàmọ́ná, tí ó sì fi ọ̀pọ̀ òjò fún ènìyàn, fún olúkúlùkù koríko ní pápá.
2 For, the household gods, have spoken vanity, and, the diviners, have had vision of falsehood, and, deceitful dreams, do they relate, vainly, do they console, —for this reason, have they moved about like a flock, they suffer ill, because there is no shepherd.
Nítorí àwọn òrìṣà tí sọ̀rọ̀ asán, àwọn aláfọ̀ṣẹ sì tí rí èké, wọn sì tí rọ àlá èké; wọ́n ń tu ni nínú lásán, nítorí náà àwọn ènìyàn náà ṣáko lọ bí àgùntàn, a ṣẹ wọn níṣẹ̀ẹ́, nítorí Olùṣọ́-àgùntàn kò sí.
3 Against the shepherds, is kindled mine anger, and, upon the leaders of the flock, will I bring punishment, —for Yahweh of hosts hath visited his flock, the house of Judah, and will make them like his noble horse in battle:
“Ìbínú mi ru sí àwọn darandaran, èmi o sì jẹ àwọn olórí ní yà nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti bẹ agbo rẹ̀, ilé Juda wò, yóò sì fi wọn ṣe ẹṣin rẹ̀ dáradára ní ogun.
4 From him, the commander, from him, the supporter, from him, the war-bow, —from him, shall proceed every one that driveth on, together;
Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni òkúta igun ilé ti jáde wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni èèkàn àgọ́ tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrún ogun tí wá, láti ọ̀dọ̀ rẹ ni àwọn akóniṣiṣẹ́ gbogbo tí wá.
5 So shall they become like mighty ones, trampling on the mire of lanes, in battle, and they will fight because, Yahweh, is with them, —and will abash the riders of horses.
Gbogbo wọn yóò sì dàbí ọkùnrin alágbára ni ogun tí ń tẹ àwọn ọ̀tá wọn mọ́lẹ̀ ní ìgboro, wọn ó sì jagun, nítorí Olúwa wà pẹ̀lú wọn, wọn ó sì dààmú àwọn tí ń gun ẹṣin.
6 So will I make mighty ones of the house of Judah, and, the house of Joseph, will I save, and will cause them to continue, because I have had compassion upon them, So shall they be as though I had not rejected them, —for, I, Yahweh, will be their God, and will answer them;
“Èmi o sì mú ilé Juda ní agbára, èmi o sì gba ilé Josẹfu là, èmi ó sì tún mú wọn padà nítorí mo tí ṣàánú fún wọn, ó sì dàbí ẹni pé èmi kò ì tì í ta wọ́n nù; nítorí èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn, èmi o sì gbọ́ tiwọn
7 And they shall be as the mighty one of Ephraim, and their heart, shall rejoice, as through wine, —yea, their children, shall see and rejoice, their heart, shall exult, in Yahweh.
Efraimu yóò sì ṣe bí alágbára, ọkàn wọn yóò sì yọ̀ bi ẹni pé nípa ọtí wáìnì: àní àwọn ọmọ wọn yóò rí í, wọn o sì yọ̀, inú wọn ó sì dùn nínú Olúwa.
8 I will signal for them, and will gather them, because I have ransomed them, —and they shall multiply, according as they have multiplied;
Èmi ó kọ sí wọn, èmi ó sì ṣà wọ́n jọ; nítorí èmi tí rà wọ́n padà; wọn ó sì pọ̀ sí i gẹ́gẹ́ bí wọ́n tí ń pọ̀ sí í rí.
9 Though I scatter them among the peoples, yet, in places far away, shall they remember me, —and they shall live with their children, and shall return;
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo tú wọn káàkiri orílẹ̀-èdè: síbẹ̀ wọn ó sì rántí mi ni ilẹ̀ jíjìn; wọn ó sì gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn, wọn ó sì tún padà.
10 And I will bring them back out of the land of Egypt, and, out of Assyria, will I gather them, —and, into the land of Gilead and Lebanon, will I bring them, and [room] shall not be found for them:
Èmi ó sì tún mú wọn padà kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú, èmi ó sì ṣà wọn jọ kúrò ni ilẹ̀ Asiria. Èmi ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ Gileadi àti Lebanoni; a kì yóò sì rí ààyè fún wọn bí ó ti yẹ.
11 Though he pass through a sea of affliction, yet shall he smite the sea, with its waves, and the roaring depths of the Nile, shall appear dry, —So shall be brought down the pride of Assyria, and, the sceptre of Egypt, shall depart;
Wọn yóò sì la Òkun wàhálà já, yóò sì bori rírú omi nínú Òkun, gbogbo ibú odò ni yóò sì gbẹ, a ó sì rẹ ìgbéraga Asiria sílẹ̀, ọ̀pá aládé Ejibiti yóò sí lọ kúrò.
12 And I will make them mighty in Yahweh, and, in his name, shall they march to and fro, —Declareth Yahweh.
Èmi ó sì mú wọn ní agbára nínú Olúwa; wọn ó sì rìn sókè rìn sódò ni orúkọ rẹ̀,” ni Olúwa wí.

< Zechariah 10 >