< Ruth 4 >

1 Now, Boaz, went up to the gate, and sat him down there, and lo! the kinsman, passing by, of whom Boaz had spoken, so he said—Turn aside! and sit down here, such a one! And he turned aside, and sat down.
Nígbà náà ni Boasi gòkè lọ sí ẹnu ibodè ìlú, ó sì jókòó síbẹ̀. Nígbà tí ìbátan tí ó súnmọ́ Elimeleki jùlọ, arákùnrin tí Boasi ti sọ̀rọ̀ rẹ̀ ń kọjá, Boasi pè é wí pé, “Máa bọ̀ wá síbí ìwọ ọ̀rẹ́ mi, kí o sì jókòó.” Ó sì lọ jókòó.
2 Then fetched he ten men of the elders of the city, and said—Sit ye down here. And they sat down.
Boasi sì pe mẹ́wàá nínú àwọn àgbàgbà ìlú, wí pé ki wọn jókòó, wọn sí ṣe bẹ́ẹ̀,
3 Then said he to the kinsman, The parcel of land that was our brother Elimelech’s, is to be disposed of by Naomi, who hath returned out of the country of Moab;
ó sì sọ fún ìbátan rẹ̀ náà pé, “Arábìnrin Naomi tí ó dé láti ilẹ̀ Moabu fẹ́ ta ilẹ̀, èyí tí ó ṣe ti arákùnrin Elimeleki wa.
4 and, I, thought, I would unveil thine ear, saying—Take it over in presence of such as are here seated, and in presence of the elders of my people. If thou wilt act as kinsman, act as kinsman, but, if thou wilt not so act, only tell me—that I may know, for there is none who can set thee aside as kinsman, but, I, am after thee. And he said, I, will act as kinsman.
Mó sì rò wí pé ó yẹ kí n mú ọ̀rọ̀ náà wá sí etí ìgbọ́ rẹ, wí pé kí o rà á ní iwájú gbogbo àwọn tí ó jókòó sí ibi yìí. Bí ìwọ yóò bá rà á padà rà á. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá ní rà á padà, sọ fún mi, kí èmi ó le è mọ̀. Nítorí pé kò sí ẹlòmíràn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti rà á ju ìwọ lọ, èmi sì ni ẹni tí ó tún kàn lẹ́yìn rẹ̀.” Ọkùnrin náà sì sọ wí pé, “Èmi yóò rà á padà.”
5 Then said Boaz, What day thou takest over the land from the hand of Naomi, also, of Ruth the Moabitess, wife of the dead, dost thou take [it], to raise up the name of the dead upon his inheritance.
Nígbà náà ni Boasi sọ wí pé, “Bí ìwọ bá ti ra ilẹ̀ náà lọ́wọ́ Naomi àti lọ́wọ́ Rutu ará Moabu, ìwọ gbọdọ̀ fẹ́ opó ọkùnrin náà, kí orúkọ ọkùnrin tí ó kú náà má ba à parẹ́ pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀ àti kí o le è bímọ ní orúkọ rẹ̀.”
6 Then said the kinsman—I cannot act as kinsman for myself, lest I mar my own inheritance, —do, thou, for thyself act as kinsman in my right, for I cannot so redeem.
Nígbà náà ni ọkùnrin náà dáhùn sí èyí pé, “Nípa ti èyí, èmi kò le è rà á padà, nítorí pé, ọmọ rẹ̀, ọkùnrin yóò wá jẹ́ ajogún àwọn ohun ìní mi pẹ̀lú. Rà á fún ara rẹ, èmi kò le ṣe é.”
7 Now, this aforetime, [was the way] in Israel, at a redeeming, and at an exchanging, to confirm every word: A man drew off his shoe, and gave it to his neighbour, —yea, this, was the way of taking to witness, in Israel.
Ní ayé ìgbàanì, kí a tó le sọ wí pé ohun ìràpadà tàbí pàṣípàrọ̀ ohun ìní fi ìdí múlẹ̀ ní ilẹ̀ Israẹli, ẹnìkan ni láti yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀ kí ó sì fi fún ẹnìkejì, ó jẹ́ òfin fún ẹni tí ó fẹ́ rà á. Nípa ṣíṣe èyí, àwọn ará Israẹli fihàn wí pé ọ̀rọ̀ náà ti fìdímúlẹ̀.
8 So the kinsman said unto Boaz, Take it over for thyself, —and he drew off his shoe.
Nítorí náà, nígbà tí ọkùnrin náà sọ fún Boasi wí pé, “Ìwọ rà á fúnra rẹ̀,” ó yọ bàtà rẹ̀ kúrò ní ẹsẹ̀ rẹ̀.
9 Then said Boaz to the elders, and all the people—Witnesses, are ye to-day, that I have taken over all that was Elimelech’s, and all that was Chilion’s, and Mahlon’s, —from the hand of Naomi:
Nígbà náà ni Boasi wí fún àwọn àgbàgbà àti àwọn mìíràn tí ó wà ní ibẹ̀ pé, “Gbogbo yín jẹ́ ẹlẹ́rìí mi ní òní wí pé mo ti ra ohun gbogbo tí í ṣe ti Elimeleki àti àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin méjèèjì: Maloni àti Kilioni lọ́wọ́ Naomi.
10 Moreover, Ruth the Moabitess, wife of Mahlon, have I taken over, to be my wife, to raise up the name of the dead upon his inheritance, that the name of the dead be not cut off—from among his brethren, and from the gate of his dwelling- place, —Witnesses, are ye to-day!
Ní àfikún, mo ra Rutu ará Moabu opó Maloni padà láti di aya mi. Èyí tí yóò mú kí orúkọ ọkùnrin òkú náà wà pẹ̀lú ohun ìní rẹ̀, kí ìran rẹ̀ má ba à lè parẹ́ láàrín àwọn ẹbí rẹ̀ àti ìlú rẹ̀. Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí ní òní.”
11 Then said all the people who were in the gate, and the elders—Witnesses!, —Yahweh grant the woman who is coming into thy house, to be as Rachel, and as Leah, which two of them did build the house of Israel. Do thou bravely, then, in Ephrathah, and proclaim thou a name in Bethlehem,
Nígbà náà ni àwọn àgbàgbà àti àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀ dáhùn wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, àwa ni ẹlẹ́rìí, kí Olúwa jẹ́ kí obìnrin tí ó ń bọ̀ wá sí inú ilẹ̀ rẹ dàbí Rakeli àti Lea láti ara àwọn ẹni tí gbogbo ìdílé Israẹli ti jáde wá. Kí ìwọ sì di ọlọ́rọ̀ ní ìran Efrata àti olókìkí ní ìlú Bẹtilẹhẹmu.
12 And let thy house be like the house of Perez, whom Tamar bare to Judah, —of the seed which—may Yahweh give thee, of this young woman.
Kí Olúwa fún ọ ní ọmọ tí yóò mú ìdílé rẹ dàbí ti Peresi ọmọkùnrin tí Tamari bí fún Juda láti ipasẹ̀ ọ̀dọ́mọbìnrin yìí.”
13 So Boaz took Ruth, and she became his wife, and he went in unto her, —and Yahweh granted her conception, and she bare a son.
Báyìí ni Boasi ṣe mú Rutu, tí ó sì di aya rẹ̀. Nígbà náà ni ó wọlé tọ aya rẹ̀, Olúwa sì mú kí ó lóyún, ó sì bí ọmọ ọkùnrin kan.
14 Then said the women unto Naomi, Blessed, be Yahweh! who hath not let thee fail of a kinsman to-day, —and may his name, be proclaimed, in Israel;
Àwọn obìnrin sì wí fún Naomi pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí kò fi ọ sílẹ̀ ní òní yìí láìní ìbátan, Olùràpadà. Kí ọmọ náà di olókìkí ní Israẹli.
15 So shall he become a restorer of thy life, and a nourisher of thine old age, —for, thy daughter-in-law who loveth thee, hath borne him, even, she, who is better to thee than seven sons.
Yóò tún ayé rẹ ṣe, yóò sì dáàbò bò ọ́ ní ọjọ́ ogbó rẹ. Nítorí pé ìyàwó ọmọ rẹ, èyí tí ó sàn fún ọ ju ọmọkùnrin méje lọ, tí ó sì fẹ́ràn rẹ ni ó bí ọmọ yìí fún.”
16 So Naomi took the boy, and laid him in her bosom, and she became his nurse.
Naomi sì gbé ọmọ náà lé orí ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì ń tọ́jú rẹ̀.
17 And the women, her neighbours, gave him a name, saying, There is born a son to Naomi, —So they called his name Obed, he, was, the father of Jesse, the father of David.
Àwọn obìnrin àdúgbò sì wí pé, “A bí ọmọkùnrin kan fún Naomi.” Wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Obedi. Òun sì ni baba Jese tí í ṣe baba Dafidi.
18 These, then, are the generations of Perez: Perez, begat, Hezron;
Èyí ni ìran Peresi: Peresi ni baba Hesroni,
19 And, Hezron, begat, Ram, and, Ram, begat, Amminadab;
Hesroni ni baba Ramu, Ramu ni baba Amminadabu
20 And, Amminadab, begat Nahshon, and, Nahshon, begat, Salmon,
Amminadabu ni baba Nahiṣoni, Nahiṣoni ni baba Salmoni,
21 And, Salmon, begat, Boaz, and, Boaz, begat, Obed;
Salmoni ni baba Boasi, Boasi ni baba Obedi,
22 And, Obed, begat, Jesse, and, Jesse, begat, David.
Obedi ní baba Jese, Jese ni baba Dafidi.

< Ruth 4 >