< Psalms 96 >

1 Sing to Yahweh, a song that is new, Sing to Yahweh, all the earth;
Ẹ kọrin tuntun sí Olúwa, ẹ kọrin sí Olúwa gbogbo ayé.
2 Sing to Yahweh, bless ye his Name, —Tell the tidings, from day to day, of his salvation:
Ẹ kọrin sí Olúwa, yin orúkọ rẹ̀ ẹ sọ ti ìgbàlà rẹ̀ ní ọjọ́ dé ọjọ́.
3 Recount, Among the nations, his glory, Among all the peoples, his wonders.
Ẹ sọ ti ògo rẹ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè àti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ láàrín gbogbo ènìyàn.
4 For great is Yahweh, and worthy to be mightily praised, To be revered is he above all gods;
Nítorí títóbi ní Olúwa ẹni tí ìyìn tọ́ sí; òun ní o yẹ kí a bẹ̀rù ju gbogbo òrìṣà lọ.
5 For, all the gods of the peoples, are things of nought—But, Yahweh, made, the heavens.
Nítorí asán ni gbogbo àwọn òrìṣà orílẹ̀-èdè ṣùgbọ́n Olúwa dá àwọn ọ̀run.
6 Praise and majesty, are before him, Strength and beauty, are in his sanctuary.
Ọlá àti ọláńlá wà ní iwájú rẹ̀ agbára àti ògo wà ní ibi mímọ́ rẹ̀.
7 Give to Yahweh, ye families of the peoples, Give to Yahweh, glory and strength;
Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ìbátan ènìyàn, ẹ fi agbára àti ògo fún Olúwa.
8 Give to Yahweh, the glory of his Name, Bring a present, and enter his courts;
Ẹ fi ògo tí ó tọ́ sí Olúwa fún un; ẹ mú ọrẹ wá, kí ẹ sì wá sí àgbàlá rẹ̀.
9 Bow down to Yahweh, in the adornment of holiness, Be in anguish at his presence, all the earth!
Ẹ máa sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́ rẹ̀; ẹ wárìrì níwájú rẹ̀ gbogbo ayé.
10 Say among the nations, Yahweh, hath become King, Surely he hath fixed the world, it shall not be shaken, He will judge the peoples with equity.
Sọ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, “Olúwa jẹ ọba.” A fi ìdí ayé múlẹ̀, tí kò sì lè yí; ẹni tí yóò fi òtítọ́ ṣe ìdájọ́ ènìyàn.
11 Let the heavens rejoice, and the earth exult, Let the sea roar, and the fulness thereof;
Jẹ́ kí àwọn ọ̀run kí ó yọ̀, kí ayé sì pariwo jẹ́ kí pápá òkun kí ó hó pẹ̀lú ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀.
12 Let the field, leap for joy, and all that is therein, Then, shall all the trees of the forest, shout in triumph,
Jẹ́ kí oko kún fún ayọ̀, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀; nígbà náà ni gbogbo igi igbó yóò máa yọ̀.
13 Before Yahweh, for he is coming, For he is coming to judge the earth, —He will judge the world, in righteousness, And the peoples, in his faithfulness.
Wọn yóò kọrin níwájú Olúwa, nítorí tí ó ń bọ̀ wá, ó ń bọ̀ wá ṣe ìdájọ́ ayé. Yóò fi òdodo ṣe ìdájọ́ ayé àti ti àwọn ènìyàn ni yóò fi òtítọ́ rẹ̀ ṣe.

< Psalms 96 >