< Psalms 81 >
1 To the Chief Musician. On "the Gittith." Asaph’s. Shout ye for joy, unto God our strength, Sound the note of triumph, to the God of Jacob;
Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Ti Asafu. Kọrin sókè sí Ọlọ́run agbára wa ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run Jakọbu!
2 Raise a melody, and strike the timbrel, The lyre so sweet, with the harp:
Ẹ mú orin mímọ́, kí ẹ sì mú ìlù wá, tẹ dùùrù dídùn pẹ̀lú ohun èlò orin mímọ́.
3 Blow, at the new moon, the horn, At the full moon, for the day of our sacred festival:
Ẹ fún ìpè ní oṣù tuntun àní nígbà tí a yàn; ní ọjọ́ àjọ wa tí ó ní ìrònú.
4 For, a statute to Israel, it is, A regulation, by the God of Jacob;
Èyí ni àṣẹ fún Israẹli, àti òfin Ọlọ́run Jakọbu.
5 A testimony in Joseph, he appointed it, When he went forth over the land of Egypt: A language I liked not, used I to hear;
Ó fi múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà fún Josẹfu nígbà tí ó la ilẹ̀ Ejibiti já. Níbi tí a ti gbọ́ èdè tí kò yé wa.
6 I took away, from the burden, his shoulder, his hands, from the clay, were set free.
Ó wí pé, “Mo gbé àjàgà kúrò ní èjìká yín, a tú ọwọ́ wọn sílẹ̀ kúrò nínú apẹ̀rẹ̀.
7 In distress, thou didst cry, and I delivered thee, —I answered thee, within a hiding-place of thunder, I proved thee by the waters of Meribah. (Selah)
Nínú ìnilára ni ẹ pè mo sì gbà yín là, mo dá a yín lóhùn nínú ìkọ̀kọ̀ àrá, mo dán an yín wò ní odò Meriba. (Sela)
8 Hear, O my people, and I will adjure thee, O Israel, if thou wilt hearken unto me!
“Gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi ó sì kìlọ̀ fún un yín, bí ìwọ bá fetí sí mi, ìwọ Israẹli.
9 There shall not be, within thee, a foreign GOD, —Neither shalt thou bow down to a strange GOD:
Ẹ̀yin kì yóò ní Ọlọ́run ilẹ̀ mìíràn láàrín yín; ẹ̀yin kì yóò foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run àjèjì.
10 I, Yahweh, am thy God, Who brought thee up out of the land of Egypt, —Open wide thy mouth, that I may fill it.
Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti. Ẹ la ẹnu yín gbòòrò, èmi yóò sì kún un.
11 But my people, hearkened not, unto my voice, Even, Israel, inclined not unto me.
“Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kì yóò gbọ́ tèmi; Israẹli kò ní tẹríba fún mi.
12 So then I let them go on in the stubbornness of their own heart, They might walk in their own counsels!
Nítorí náà ni mo ṣe fi wọ́n fún ọkàn líle wọn láti máa rìn ní ọ̀nà ẹ̀tàn wọn.
13 If, my people, were hearkening unto me, [If, ] Israel, in my ways, would walk,
“Bí àwọn ènìyàn mi yóò bá gbọ́ tèmi bí Israẹli yóò bá tẹ̀lé ọ̀nà mi,
14 Right soon, their foes, would I subdue, And, against their adversaries, would I turn my hand:
ní kánkán ni èmi yóò ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá wọn kí n sì yí ọwọ́ mi padà sí ọ̀tá wọn!
15 The haters of Yahweh, should come cringing unto him, Then let their own good time be age-abiding!
Àwọn tí ó kórìíra Olúwa yóò tẹríba níwájú rẹ̀. Ìjìyà wọn yóò sì pẹ́ títí láé.
16 Then would he feed them from the marrow of the wheat, Yea, out of the rock—with honey, would I satisfy thee.
Ṣùgbọ́n a ó fi ọkà tí ó dára bọ́ ọ yín èmi ó tẹ́ ẹ yín lọ́rùn pẹ̀lú oyin inú àpáta.”