< Psalms 7 >

1 Ode of David: which he sang unto Yahweh, on account of the words of Cush the Benjamite. O Yahweh my God, in thee, have I sought refuge, —Save me from all my pursuers, and deliver me:
Ṣiggaioni ti Dafidi, èyí tí ó kọ sí Olúwa nípa Kuṣi, ará Benjamini. Olúwa Ọlọ́run mi, ààbò mi wà nínú rẹ; gba mí là kí o sì tú mi sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tó ń lé mi,
2 Lest one tear, as a lion, my soul, —and there be no deliverer to rescue.
kí wọn ó má ba à fa ọkàn mi ya gẹ́gẹ́ bí kìnnìún, wọ́n á ya á pẹ́rẹpẹ̀rẹ láìsí ẹni tí yóò gbà mí.
3 O Yahweh my God, If I have done this, If there hath been perversity in my hands:
Olúwa Ọlọ́run mi, tí èmi bá ṣe èyí tí ẹ̀bi sì wà ní ọwọ́ mi.
4 If I have requited my friend with wrong, —or have oppressed mine adversary without need,
bí èmi bá ṣe ibi sí ẹni tí ń wá àlàáfíà pẹ̀lú mi, tí mo ja ọ̀tá mi lólè láìnídìí,
5 Let an enemy pursue my soul, and overtake it, that he may tread down, to the earth, my life, —and, mine honour—in the dust, he may cause to dwell. (Selah)
nígbà náà, jẹ́ kí ọ̀tá mi lé mi kí wọn sì mú mi; jẹ́ kí òun kí ó tẹ ọkàn mi mọ́lẹ̀ kí wọn sì mú mi sùn nínú eruku. (Sela)
6 Rise! Yahweh! in thine anger, Lift thyself up, because of the haughty outbursts of mine adversaries, Stir up for me the justice thou hast commanded:
Dìde, Olúwa, nínú ìbínú rẹ; dìde lòdì sí ìrunú àwọn ọ̀tá mi. Jí, Ọlọ́run mi; kéde òdodo.
7 When, the assembly of peoples, gather round thee, then, above it—on high, do thou return!
Kí ìpéjọ àwọn ènìyàn yíká. Jọba lórí wọn láti òkè wá.
8 Yahweh, will judge the peoples, —Do me justice, O Yahweh, according to my righteousness, and according to mine integrity upon me,
Jẹ́ kí Olúwa ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn. Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òdodo mi, gẹ́gẹ́ bí ìwà òtítọ́, ẹni gíga jùlọ.
9 Let the wrong of the lawless, I pray thee, come to an end, and establish thou him that is righteous, —for, a trier of hearts and reins, is God the righteous one.
Ọlọ́run Olódodo, Ẹni tí ó ń wo inú àti ọkàn, tí ó ń mú òpin sí ìwà ipá ẹni búburú tí ó sì ń pa àwọn olódodo mọ́.
10 My shield, is held by God, who is ready to save the upright in heart:
Ààbò mi ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí ń ṣe ìgbàlà òtítọ́ ní àyà.
11 A God to vindicate the righteous, —And yet a God to be indignant throughout every day.
Ọlọ́run ni onídàájọ́ òtítọ́, Ọlọ́run tí ń sọ ìrunú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́.
12 If he turn not, his sword, will he whet, —his bow, hath he bent, and made ready:
Bí kò bá yípadà, Òun yóò pọ́n idà rẹ̀ mú; ó ti fa ọrun rẹ̀ le ná, ó ti múra rẹ̀ sílẹ̀.
13 But, for himself, hath he made ready the weapons so deadly, His arrows, he, so fiery, would make:
Ó ti pèsè ohun ìjà ikú sílẹ̀; ó ti pèsè ọfà iná sílẹ̀.
14 Lo! he gendereth trouble, and conceiveth mischief, but giveth birth to a disappointment:
Ẹni tí ó lóyún ohun búburú, tí ó sì lóyún wàhálà, ó bí èké jáde.
15 A pit, he cut out, and digged it, and then fell into the ditch he had made:
Ẹni tí ó gbẹ́ ọ̀fìn, tí ó kó o jáde jì sí kòtò tí ó gbẹ́ sílẹ̀.
16 His mischief, turneth back, on his own head, —and, on his own crown, his violence, descendeth.
Wàhálà tí ó fà padà sórí rẹ̀; ìwà ipá rẹ̀ padà sórí ara rẹ̀.
17 I will praise Yahweh according to his righteousness, —and will praise in song the Name of Yahweh Most High.
Èmi ó fi ọpẹ́ fún Olúwa nítorí òdodo rẹ̀, èmi ó kọrin ìyìn sí Olúwa Ọ̀gá-ògo jùlọ.

< Psalms 7 >