< Psalms 66 >
1 To the Chief Musician. A Melodious Song. Make a joyful noise unto God, all the earth;
Fún adarí orin. Orin. Saamu. Ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ilẹ̀ gbogbo!
2 Praise ye in song the glory of his Name, Celebrate the glory of his praise:
Ẹ kọrin ọlá orúkọ rẹ̀; ẹ kọrin ìyìnsí i.
3 Say unto God—How fearful in thy doings, Through the abounding of thy power, shall thy foes come cringing unto thee;
Ẹ wí fún Ọlọ́run pé, “Ìwọ ti ní ẹ̀rù tó nínú iṣẹ́ rẹ! Nípa ọ̀pọ̀ agbára rẹ ni àwọn ọ̀tá rẹ yóò fi sìn ọ́.
4 All the earth, shall bow themselves down to thee, And sing praises unto thee, Shall praise in song thy Name. (Selah)
Gbogbo ayé ń wólẹ̀ fún ọ; wọn ń kọrin ìyìn sí ọ, wọ́n ń kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ.” (Sela)
5 Come and see the doings of God, —Fearful in deed toward the sons of men:
Ẹ wá wo ohun tí Ọlọ́run ṣe, iṣẹ́ rẹ̀ ti ní ẹ̀rù tó sí àwọn ọmọ ènìyàn!
6 He turned the sea into dry land, Through the stream, crossed they over on foot, There did we rejoice in him:
Ó yí òkun padà sí ilẹ̀ gbígbẹ, wọ́n fi ẹsẹ̀ rin inú omi kọjá, níbẹ̀ ni àwa yọ̀ nínú rẹ̀.
7 Who ruleth, in his might, unto times age abiding, His eyes, over the nations, keep watch, The rebellious, let them not exalt themselves. (Selah)
Ó ń jẹ ọba títí láé nípa agbára rẹ̀, ojú rẹ̀ ń wo orílẹ̀-èdè kí àwọn ọlọ̀tẹ̀ má ṣe gbé ara wọn ga. (Sela)
8 Bless our God, O ye peoples, And cause to be heard, the sound of his praise; —
Ẹ yin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn, jẹ́ kí a mú ni gbọ́ ohùn ìyìn rẹ̀;
9 Who hath set our soul among the living, And hath not suffered, our foot, to slip.
Ó ti dá ààbò bo ẹ̀mí wa, kò sì jẹ́ kí ẹsẹ̀ wa kí ó yẹ̀.
10 For thou didst prove us, O God, Thou didst refine us, according to the refining of silver:
Nítorí ìwọ, Ọlọ́run, dán wa wò; ìwọ dán wa bí a tí ń dán fàdákà wò.
11 Thou didst bring us into the hunter’s net, Thou didst lay a load upon our loins;
Ìwọ mú wa wá sínú ẹ̀wọ̀n o sì di ẹrù lé ẹ̀yìn wa.
12 Thou didst let men ride at our head; We went into fire and into water, But thou didst bring us forth into freedom.
Ìwọ mú àwọn ènìyàn gún wá ní orí àwa la iná àti omi kọjá ṣùgbọ́n ìwọ mú wa dé ibi ọ̀pọ̀.
13 I will enter thy house with ascending-sacrifices, I will pay unto thee my vows,
Èmi ó wá sí tẹmpili rẹ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, kí n sì mú ẹ̀jẹ́ mi ṣẹ sí ọ,
14 Which my lips uttered, And my mouth spake, in my distress.
ẹ̀jẹ́ tí ètè mi jẹ́, tí ẹnu mi sì sọ nígbà tí mo wà nínú ìṣòro.
15 Ascending-sacrifices of fatlings, will I cause to ascend unto thee, With the perfume of rams, I will offer bulls, with he-goats. (Selah)
Èmi ó rú ẹbọ sísun ọlọ́ràá sí ọ, àti ẹbọ ọ̀rá àgbò; èmi ó rú akọ màlúù àti ewúrẹ́. (Sela)
16 Come! hearken—that I may recount, all ye reverers of God, What he hath done for my soul: —
Ẹ wá gbọ́ gbogbo ẹ̀yin tí ó bẹ̀rù Ọlọ́run; ẹ jẹ́ kí n sọ ohun tí ó ṣe fún mi.
17 Unto him—with my mouth, did I cry, And high praise was under my tongue.
Mo fi ẹnu mi kígbe sókè sí i, ìyìn rẹ̀ wà ní ẹnu mi.
18 If, iniquity, I had cared for in my heart, My Lord, had not heard me!
Bí èmi bá gba ẹ̀ṣẹ̀ ní àyà mi, Olúwa kì yóò gbọ́ ohùn mi;
19 But in truth, God hath heard, He hath attended to the voice of my prayer.
ṣùgbọ́n Ọlọ́run gbọ́ nítòótọ́ ó ti gbọ́ ohùn mi nínú àdúrà.
20 Blessed be God, Who hath not turned away my prayer, Nor his own lovingkindness from me.
Ìyìn ni fún Ọlọ́run ẹni tí kò kọ àdúrà mi tàbí mú ìfẹ́ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ mi!