< Psalms 63 >
1 A Melody of David. When he was in the Wilderness of Judah. O God, my GOD, thou art, Earnestly do I desire thee, —My soul thirsteth for thee, My flesh fainteth for thee, In a land—dry, and weary for want of water, —
Saamu ti Dafidi. Nígbà tí ó wà nínú aginjù Juda. Ọlọ́run, ìwọ ni Ọlọ́run mi, nígbà gbogbo ni mo ń ṣàfẹ́rí rẹ, òǹgbẹ rẹ ń gbẹ ọkàn mi, ara mi fà sí ọ, ní ilẹ̀ gbígbẹ àti ilẹ̀ tí ń ṣàárẹ̀ níbi tí kò sí omi.
2 In like manner as, in the sanctuary, I have had vision of thee, To behold thy power and thy glory.
Èmi ti rí ọ ní ibi mímọ́, mo rí agbára àti ògo rẹ.
3 Because better is thy lovingkindness than life, My lips, aloud shall praise thee!
Nítorí ìfẹ́ rẹ dára ju ayé lọ, ètè mi yóò fògo fún ọ.
4 Thus, will I bless thee while I live, In thy Name, will I lift up mine outspread hands:
Èmi ó yìn ọ́ níwọ̀n ìgbà tí mo wà láààyè, èmi ó gbé ọwọ́ sókè, èmi ó sì pe orúkọ rẹ.
5 As with fatness and richness, shall my soul be satisfied, And, with joyfully shouting lips, shall my mouth utter praise.
A ó tẹ́ ọkàn mi lọ́rùn bí ọlọ́ràá oúnjẹ; pẹ̀lú ètè ìyìn, ẹnu mi yóò yìn ọ́.
6 Should I call thee to mind upon my couch, In the watches of the night, would I breathe soft speech of thee.
Nígbà tí mo rántí rẹ lórí ibùsùn mi; èmi ń ronú rẹ títí ìṣọ́ òru.
7 For thou hast become a help unto me, —And, in the shadow of thy wings, will I shout for joy.
Nítorí ìwọ ni ìrànlọ́wọ́ mi, mo kọrin níbi òjìji ìyẹ́ apá rẹ.
8 My soul hath run clinging to thee, On me, hath thy right hand laid hold.
Ọkàn mí fà sí ọ: ọwọ́ ọ̀tún rẹ gbé mi ró.
9 When, they, to crush it, would seek my life, They shall go into the lower parts of the earth:
Àwọn tí ó ń wá ọkàn mí ni a ó parun; wọn ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀ ayé.
10 Every one shall be given up into the power of the sword, The portion of jackals, shall they become.
Wọn ó ti ọwọ́ idà ṣubú wọn ó sì di jíjẹ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀.
11 But, the king, shall rejoice in God, —Every one shall glory who sweareth by him, For the mouth of them who speak falsehood, shall be stopped.
Ṣùgbọ́n ọba yóò yọ̀ nínú Ọlọ́run ẹni tí ó fi orúkọ Ọlọ́run búra yóò ṣògo ṣùgbọ́n ẹnu àwọn òpùrọ́ la ó pamọ́.