< Psalms 33 >
1 Shout for joy, ye righteous, in Yahweh, To the upright, seemly is praise.
Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olódodo; ìyìn si yẹ fún ẹni dídúró ṣinṣin.
2 Give ye thanks unto Yahweh with the lyre, With a harp of ten strings, make ye music unto him.
Ẹ yin Olúwa pẹ̀lú dùùrù; ẹ máa fi ohun èlò olókùn mẹ́wàá kọrin sí i.
3 Sing unto him, a song that is new, With skill, sweep the strings, with loud noise.
Ẹ kọ orin tuntun sí i; ẹ máa fi ọgbọọgbọ́n lu ohun èlò orin sí i, pẹ̀lú ariwo.
4 For right is the word of Yahweh, and, all his work, is in faithfulness:
Nítorí pé ọ̀rọ̀ Olúwa dúró ṣinṣin, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ni à ń ṣe nínú òtítọ́.
5 Who loveth righteousness and justice, With the lovingkindness of Yahweh, the earth is full.
Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́; ilé ayé kún fún ìdúró ṣinṣin àti àánú Olúwa.
6 By the word of Yahweh, the heavens were made, and, by the spirit of his mouth, all their host:
Nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ṣe dá àwọn ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹgbẹ́ ogun wọn nípa ìmísí ẹnu rẹ̀.
7 Who gathered as into a skin-bottle the waters of the sea, Delivering, into treasuries, the roaring deeps.
Ó kó àwọn omi òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò; ó sì fi ibú ṣe ilé ìṣúra gbogbo.
8 Let all the earth, stand in awe of Yahweh, Of him, be in dread, all ye inhabitants of the world;
Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù Olúwa: jẹ́ kí gbogbo àwọn olùgbé ayé kí ó wà nínú ìbẹ̀rù rẹ̀.
9 For, he, spake, and it was, He, commanded, and it stood forth.
Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀; ó pàṣẹ ó sì dúró ṣinṣin.
10 Yahweh, hath frustrated the counsel of nations, hath brought to nothing the devices of peoples.
Olúwa ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀-èdè wá sí asán; ó sì mú àrékérekè àwọn ènìyàn di ṣíṣákì í.
11 The counsel of Yahweh, to times age-abiding, shall stand, The devices of his heart, from generation to generation.
Ìgbìmọ̀ Olúwa dúró títí ayérayé, àní ìrò inú rẹ̀ láti ìrandíran ni.
12 How happy the nation whose God is, Yahweh, The people he hath chosen as his own inheritance!
Ìbùkún ni fún orílẹ̀-èdè náà, Ọlọ́run ẹni tí Olúwa jẹ́ tirẹ̀, àti àwọn ènìyàn náà tí ó ti yàn ṣe ìní rẹ̀.
13 Out of the heavens, hath Yahweh looked, He hath seen all the sons of men:
Olúwa wò láti ọ̀run wá; Ó sì rí gbogbo ìran ènìyàn.
14 Out of his settled place of abode, hath he fixed his gaze on all the inhabitants of the earth:
Níbi tí ó ti jókòó lórí ìtẹ́ Ó wo gbogbo àwọn olùgbé ayé
15 Who fashioneth their heart all together, Who understandeth all their doings.
ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà, ó sì kíyèsi ìṣe wọn.
16 Not a king, can be saved by greatness of force, nor, hero, deliver himself by greatness of strength:
A kò gba ọba kan là nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun; kò sì sí jagunjagun tí a gbà sílẹ̀ nípa agbára ńlá rẹ̀.
17 A deception, is the horse, for victory, and, by his great strength, shall he not deliver.
Ohun asán ni ẹṣin fún ìṣẹ́gun; bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fi agbára ńlá rẹ̀ gbani sílẹ̀.
18 Lo! the eye of Yahweh, is toward them who revere him, unto such as are waiting for his lovingkindness:
Wò ó, ojú Olúwa wà lára àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti lára àwọn tí ó ní ìrètí nínú ìfẹ́ rẹ̀ tí ó dúró ṣinṣin.
19 To rescue, from death, their soul, and to keep them alive in famine.
Láti gba ọkàn wọn kúrò lọ́wọ́ ikú àti láti pa wọ́n mọ́ láààyè lọ́wọ́ ìyàn.
20 Our own soul, hath waited for Yahweh, Our help and our shield, is he!
Ọkàn wa dúró de Olúwa; òun ni ìrànlọ́wọ́ wa àti asà wa.
21 For, in him, shall our heart rejoice, For, in his holy Name, have we trusted.
Ọkàn wa yọ̀ nínú rẹ̀, nítorí pé, àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ rẹ mímọ́.
22 Be thy lovingkindness, O Yahweh, upon us, According as we have waited for thee.
Kí àánú rẹ, Olúwa, kí ó wà lára wa, àní gẹ́gẹ́ bí àwa ti ń ṣe ìrètí nínú rẹ.