< Psalms 147 >
1 Praise ye Yah, For it is good, to make melody to our GOD, —For it is delightful, seemly is praise!
Ẹ fi ìyìn fún Olúwa. Nítorí ohun rere ni láti máa kọrin ìyìn sí Ọlọ́run wa, ó yẹ láti kọrin ìyìn sí i!
2 Yahweh, is building Jerusalem, The outcasts of Israel, will he gather together.
Olúwa kọ́ Jerusalẹmu; Ó kó àwọn Israẹli tí a lé sọnù jọ.
3 He is healing the broken in heart, —and binding up their hurts.
Ó wo àwọn tí ọkàn wọ́n bàjẹ́ sàn ó sì di ọgbẹ́ wọ́n.
4 Counting the number of the stars, To all of them—names, he giveth.
Ó ka iye àwọn ìràwọ̀ ó sì pe ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní orúkọ.
5 Great is our Lord, and of abounding strength, And, his knowledge, cannot be expressed.
Títóbi ni Olúwa wa ó sì pọ̀ ní agbára òye rẹ̀ kò sì ní òpin.
6 Yahweh, relieveth the humbled! casting the lawless down to the earth.
Olúwa wa pẹ̀lú àwọn onírẹ̀lẹ̀ bẹ́ẹ̀ ni ó rẹ̀ àwọn ènìyàn búburú sílẹ̀.
7 Respond to Yahweh with thanksgiving, Make melody to our God with the lyre.
Fi ọpẹ́ kọrin sí Olúwa fi ohun èlò orin olókùn yin Ọlọ́run.
8 Who covereth the heavens with clouds, preparing rain for the earth, who causeth the mountains to sprout grass:
Ó fi ìkùùkuu bo àwọ̀ sánmọ̀ ó rọ òjò sí orílẹ̀ ayé ó mú kí koríko hù lórí àwọn òkè
9 Giving, to the beast, its food, to the young ravens, when they cry.
Ó pèsè oúnjẹ fún àwọn ẹranko àti fún àwọn ọmọ ẹyẹ ìwò ní ìgbà tí wọ́n bá ń ké.
10 Not in the strength of the horse, doth he delight, Not in the legs of a man, hath he pleasure:
Òun kò ní inú dídùn nínú agbára ẹṣin, bẹ́ẹ̀ ni Òun kò ní ayọ̀ sí ẹ̀ṣẹ̀ ọkùnrin
11 Yahweh, hath pleasure, in them who revere him, in them who wait for his lovingkindness.
Olúwa ni ayọ̀ nínú àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, sí àwọn tí ó ní ìrètí nínú àánú rẹ̀.
12 Laud thou, O Jerusalem, Yahweh, Praise thy God, O Zion:
Yin Olúwa, ìwọ Jerusalẹmu; yin Ọlọ́run rẹ, ìwọ Sioni.
13 For he hath strengthened the bars of thy gates, He hath blessed thy children in thy midst:
Nítorí tí ó ti mú ọ̀pá ìdábùú ibodè rẹ̀ lágbára, Òun sì ti bùkún fún àwọn ọmọ rẹ̀ nínú rẹ
14 Who maketh thy boundaries to be peace, With the marrow of wheat, doth he satisfy thee:
Òun jẹ́ kí àlàáfíà wà ní àwọn ẹnu ibodè rẹ̀, òun sì fi jéró dáradára tẹ́ ọ lọ́rùn.
15 Who sendeth his utterance to the earth, How swiftly, runneth his word!
Òun sì rán àṣẹ rẹ̀ sí ayé ọ̀rọ̀ rẹ̀ sáré tete.
16 Who giveth snow like wool, Hoar-frost—like ashes, he scattereth:
Ó fi yìnyín fún ni bi irun àgùntàn ó sì fọ́n ìrì dídì ká bí eérú
17 Casting forth his ice like crumbs, Before his cold, who can stand?
Ó rọ òjò yìnyín rẹ̀ bí òkúta wẹ́wẹ́ ta ni ó lè dúró níwájú òtútù rẹ̀
18 He sendeth forth his word and melteth them, He causeth his wind to blow, the waters, stream along:
Ó rán ọ̀rọ̀ rẹ̀ jáde ó sì mú wọn yọ̀ ó mú kí afẹ́fẹ́ rẹ̀ fẹ́ ó sì mú odò rẹ̀ sàn.
19 Declaring his word unto Jacob, His statutes and his regulations, unto Israel.
Ó sọ ọ̀rọ̀ rẹ̀ di mí mọ̀ fún Jakọbu àwọn òfin àti ìlànà rẹ̀ fún Israẹli.
20 He hath not dealt so with any nation, and, his regulations, he maketh not known to them. Praise ye Yah!
Òun kó tí ṣe irú èyí sí orílẹ̀-èdè kan rí, bí ó ṣe ti ìdájọ́ rẹ̀ wọn ko mọ òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.