< Psalms 145 >

1 A Psalm of Praise. David’s. I will extol thee, my God, O King, and will bless thy Name, to times age-abiding and beyond:
Saamu ìyìn. Ti Dafidi. Èmi yóò gbé ọ ga, Ọlọ́run ọba mi; èmi yóò yin orúkọ rẹ̀ láé àti láéláé.
2 Every day, will I bless thee, and praise thy Name, to times age-abiding and beyond.
Ní ojoojúmọ́ èmi yóò yìn ọ́ èmi yóò sì pòkìkí orúkọ rẹ láé àti láéláé.
3 Great is Yahweh—and worthy to be heartily praised, And, his greatness, is unsearchable.
Títóbi ni Olúwa. Òun sì ni ó yẹ láti fi ìyìn fún púpọ̀púpọ̀: kò sí ẹni tí ó lè wọn títóbi rẹ̀.
4 Generation unto generation, shall celebrate thy works, and, thy mighty deeds, shall they tell:
Ìran kan yóò máa yin iṣẹ́ rẹ dé ìran mìíràn; wọn yóò máa sọ iṣẹ́ agbára rẹ.
5 The splendour of the glory of thy majesty, shall they speak, and, thy wonders, will I utter.
Wọn yóò máa sọ ìyìn ọláńlá rẹ tí ó lógo, èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú iṣẹ́ ìyanu rẹ.
6 And, the might of thy terrible acts, shall men speak, and, as for thy greatness, I will recount it.
Wọn yóò sọ iṣẹ́ agbára rẹ tí ó ní ẹ̀rù èmi yóò kéde iṣẹ́ ńlá rẹ̀.
7 The memory of thy great goodness, shall men pour forth, and, thy righteousness, shall they shout aloud.
Wọn yóò ṣe ìrántí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìwà rere rẹ àti orin ayọ̀ òdodo rẹ.
8 Gracious and compassionate, is Yahweh, —slow to anger, and of great lovingkindness.
Olóore-ọ̀fẹ́ ni Olúwa àti aláàánú ó lọ́ra láti bínú ó sì ní ìfẹ́ púpọ̀.
9 Good is Yahweh to all, and, his tender compassions, are over all his works.
Olúwa dára sí ẹni gbogbo; ó ní àánú lórí ohun gbogbo tí ó dá.
10 All thy works, O Yahweh, will give thanks unto thee, —and, thy men of lovingkindness, will bless thee:
Gbogbo ohun tí ìwọ ti dá ni yóò máa yìn ọ́ Olúwa; àwọn ẹni mímọ́ yóò máa pòkìkí rẹ.
11 The glory of thy kingdom, will they tell, —and, thy power, will they speak.
Wọn yóò sọ ògo ìjọba rẹ wọn yóò sì sọ̀rọ̀ agbára rẹ,
12 To make known to the sons of men, his mighty deeds, and the splendid glory of his kingdom.
kí gbogbo ènìyàn le mọ iṣẹ́ agbára rẹ̀ àti ọláńlá ìjọba rẹ tí ó lógo.
13 Thy kingdom, is a kingdom of all ages, —and, thy dominion, is over generation after generation.
Ìjọba rẹ ìjọba ayérayé ni, àti ìjọba rẹ wà ní gbogbo ìrandíran.
14 Yahweh is ready to uphold all who are falling, and to raise all who are laid prostrate.
Olúwa mú gbogbo àwọn tí ó ṣubú ró ó sì gbé gbogbo àwọn tí ó tẹríba dìde.
15 The eyes of all, for thee, do wait, and, thou, givest them their food in its season.
Ojú gbogbo ènìyàn ń wò ọ́, ó sì fún wọn ní oúnjẹ wọn ní àkókò tí ó yẹ.
16 Thou, openest thy hand, and fillest every living thing with gladness.
Ìwọ ṣí ọwọ́ rẹ ìwọ sì tẹ́ ìfẹ́ gbogbo ohun alààyè lọ́rùn.
17 Righteous is Yahweh in all his ways, and kind in all his works.
Olúwa jẹ́ olódodo ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìfẹ́ rẹ̀ sí gbogbo ohun tí o dá.
18 Near is Yahweh to all who call upon him, —to all them who call upon him in faithfulness.
Olúwa wà ní tòsí gbogbo àwọn tí ń ké pè é, sí gbogbo ẹni tí ń ké pè é ní òtítọ́.
19 The desire of them who revere him, will he fulfil, and, their cry, will he hear, and will save them.
Ó mú ìfẹ́ àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ṣẹ; ó gbọ́ igbe wọn, ó sì gbà wọ́n.
20 Yahweh preserveth all who love him, but, all the lawless, will he destroy.
Olúwa dá gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́ sẹ sí ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ẹni búburú ní yóò parun.
21 The praise of Yahweh, my mouth shall speak, That all flesh may bless his holy Name, Unto times age-abiding and beyond.
Ẹnu mi yóò sọ̀rọ̀ ìyìn Olúwa. Jẹ́ kí gbogbo ẹ̀dá yín orúkọ rẹ̀ mímọ́ láé àti láéláé.

< Psalms 145 >