< Psalms 141 >

1 A Melody of David. O Yahweh, I have cried unto thee, Make thou haste to me, Give ear unto my voice, when I cry to thee.
Saamu ti Dafidi. Olúwa, èmi ké pè ọ́; yára wá sí ọ̀dọ̀ mi. Gbọ́ ohùn mi, nígbà tí mo bá ń ké pè ọ́.
2 Let my prayer be set in order like incense before thee, —the lifting up of my hands, as the evening gift.
Jẹ́ kí àdúrà mi ó wá sí iwájú rẹ bí ẹbọ tùràrí àti ìgbé ọwọ́ mi si òkè rí bí ẹbọ àṣálẹ́.
3 Set thou, O Yahweh, a watch at my mouth, Keep thou guard over the door of my lips.
Fi ẹ̀ṣọ́ ṣọ́ ẹnu mi, Olúwa: kí o sì máa pa ìlẹ̀kùn ètè mi mọ́.
4 Let not my heart incline to a matter of wrong, that I should busy myself with practices in lawlessness, with men working iniquity, and let me not eat of their dainties.
Má ṣe jẹ́ kí ọkàn mi fà sí ohun tí ń ṣe ibi, láti máa bá àwọn tí ń ṣiṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ búburú má sì ṣe jẹ́ kí èmi jẹ àdídùn wọn.
5 Let a righteous man smite me—a lovingkindness, that he should correct me, an oil for the head [which] let not my head refuse! For, yet, even my prayer, shall be in their calamities.
Jẹ́ kí olódodo lù mí, ìṣeun ni ó jẹ́: jẹ́ kí ó bá mi wí, ó jẹ́ òróró ní orí mi. Tí kì yóò fọ́ mi ní orí. Síbẹ̀ àdúrà mi wá láìsí ìṣe àwọn olùṣe búburú.
6 Their judges, have been hurled down by a crag, Now have men heard my sayings, for they have become sweet.
A ó ju àwọn alákòóso sílẹ̀ láti bẹ̀bẹ̀ òkúta, àwọn ẹni búburú yóò kọ pé àwọn ọ̀rọ̀ mi dùn.
7 As when one plougheth and furroweth the earth, Scattered about, are our bones at the mouth of hades! (Sheol h7585)
Wọn yóò wí pé, “Bí ẹni tí ó la aporo sórí ilẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni egungun wa tànkálẹ̀ ní ẹnu isà òkú.” (Sheol h7585)
8 Surely, unto thee, O Yahweh, My Lord, are mine eyes, In thee, have I sought refuge, Do not pour out my life.
Ṣùgbọ́n ojú mi ń bẹ lára rẹ, Olúwa Olódùmarè; nínú rẹ̀ ni èmi ti rí ààbò, má ṣe fà mi fún ikú.
9 Keep me out of the clutches of the trap they have set for me, and the snares of the workers of iniquity.
Pa mí mọ́ kúrò nínú okùn tí wọn ti dẹ sílẹ̀ fún mi, kúrò nínú ìkẹ́kùn àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
10 They who are lawless, shall fall into the nooses thereof, while, I, at the same time, pass on.
Jẹ́ kí àwọn ẹni búburú ṣubú sínú àwọ̀n ara wọn, nígbà tí èmi bá kọjá lọ láìléwu.

< Psalms 141 >