< Psalms 119 >
1 [ALEPH.] How happy the men of blameless life, who walk in the law of Yahweh.
Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀, ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa.
2 How happy they who observe his testimonies, with a whole heart, they seek him.
Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́ tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
3 Yea, they have not wrought perversity, In his ways, have they walked.
Wọn kò ṣe ohun tí kò dára; wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
4 Thou, hast commanded thy precepts, that they should be diligently kept.
Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀ kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
5 Oh would that my ways might be settled! that I might keep thy statutes.
Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
6 Then, shall I not be ashamed, when I have respect unto all thy commandments.
Nígbà náà, ojú kò ní tì mí nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
7 I will thank thee with uprightness of heart, when I have learned thy righteous regulations.
Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
8 Thy statutes, will I keep, Do not thou forsake me utterly.
Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.
9 [BETH.] Wherewithal can a young man keep pure his way? By taking heed, according to thy word.
Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
10 With all my heart, have I sought thee, Suffer me not to be led astray from thy commandments.
Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
11 In my heart, have I treasured what thou hast said, to the end I may not sin against thee.
Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.
12 Blessed art thou, O Yahweh—Teach me thy statutes.
Ìyìn ni fún Olúwa; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
13 With my lips, have I recounted All the regulations of thy mouth.
Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
14 In the way of thy testimonies, have I rejoiced, Like as over all riches.
Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ, bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
15 In thy precepts, will I meditate, that I may discern thy paths.
Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.
16 In thy statutes, will I find my dear delight, I will not forget thy word.
Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ; èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.
17 [GIMEL.] Bestow thy bounties upon thy servant—let me live, That I may observe thy word.
Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè; èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
18 Unveil thou mine eyes, that I may discern Wondrous things out of thy law.
La ojú mi kí èmi lè ríran rí ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
19 A sojourner, am, I, in the earth, Do not hide from me, thy commandments.
Àlejò ní èmi jẹ́ láyé, má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
20 My soul is crushed with longing for thy just decisions at all times.
Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
21 Thou hast rebuked the proud as accursed, who stray from thy commandments.
Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
22 Roll from off me, reproach and contempt, For, thy testimonies, have I observed.
Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi, nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
23 Even rulers have taken their seat, against me, have talked, Thy servant, will still meditate in thy statutes.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
24 Yea, thy testimonies, are my dear delight, My counsellors.
Òfin rẹ ni dídùn inú mi; àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.
25 [DALETH.] My soul, cleaveth to the dust, Give me life, according to thy word.
Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀; ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
26 My ways, I recounted, and thou didst answer me, Teach me thy statutes.
Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
27 The way of thy precepts, cause thou me to understand, and I will indeed meditate in thy wonders.
Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ: nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
28 My soul weepeth itself away, for grief, Confirm thou me, according to thy word.
Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́; fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
29 The way of falsehood, take thou from me, and, with thy law, O favour me.
Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
30 The way of faithfulness, have I chosen, Thy regulations, have I deemed right.
Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́ èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
31 I have kept close to thy testimonies, O Yahweh! do not put me to shame.
Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
32 The way of thy commandments, will I run, for thou wilt enlarge my heart.
Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ, nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
33 [HE.] Point out to me, O Yahweh, the way of thy statutes, that I may observe it unto the end.
Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ; nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
34 Give me understanding, that I may observe thy law, that I may keep it with a whole heart.
Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́ èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
35 Guide me in the path of thy commandments, for, therein, do I find pleasure.
Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí, nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
36 Incline my heart unto thy testimonies, and not unto unjust gain.
Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
37 Turn away mine eyes, from beholding vanity, In thy way, give me life.
Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán: pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
38 Establish, unto thy servant, thy word, which pertaineth to the reverence of thee.
Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí òfin rẹ dára.
39 Cause to pass away my reproach, that I have feared, for, thy regulations, are good.
Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
40 Lo! I have longed for thy precepts, In thy righteousness, give me life.
Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ! Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.
41 [WAW.] And let thy lovingkindness reach me, O Yahweh, thy salvation, according to thy word.
Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa, ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
42 So shall I have something to answer him that reproacheth me, That I have trusted in thy word.
Nígbà náà ni èmi yóò dá ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn, nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
43 And do not snatch away from my mouth the word of truth in any wise, because, for thy regulation, have I waited.
Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.
44 That I may keep thy law continually, to times age-abiding and beyond.
Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo láé àti láéláé.
45 That I may walk to and fro in a large place, because, thy precepts, have I sought.
Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira, nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
46 That I may speak of thy testimonies before kings, and not be ashamed.
Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba ojú kì yóò sì tì mí,
47 That I may find dear delight in thy commandments, which I have loved.
nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
48 That I may lift up my hands unto thy commandments, which I have loved, and may meditate in thy statutes.
Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn, èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.
49 [ZAYIN.] Remember the word unto thy servant, upon which thou hast caused me to hope.
Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
50 This, is my comfort in mine affliction, that, thy word, hath given me life.
Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí: ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
51 Insolent men, have derided me exceedingly, From thy law, have I not swerved.
Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró, ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
52 I have remembered thy regulations, [which have come down] from age-past times, O Yahweh, and have consoled myself.
Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa, èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
53 A raging heat, hath seized me, by reason of the lawless, who forsake thy law.
Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú, tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
54 Songs, have thy statutes become to me, in my house of sojourn.
Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi níbikíbi tí èmi ń gbé.
55 I have remembered, in the night, thy Name, O Yahweh, and have kept thy law.
Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
56 This, have I had, because, thy precepts, have I observed.
nítorí tí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.
57 [HETH.] My portion, is Yahweh, I have promised that I would keep thy words.
Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa: èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
58 I have sought the smile of thy face with all my heart, Show me favour, according to thy word.
Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
59 I have thought upon my ways, and have turned my feet unto thy testimonies.
Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
60 I have hastened, and not delayed, to keep thy commandments.
Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
61 The meshes of the lawless, have surrounded me, Thy law, have I not forgotten.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
62 At midnight, I arise to give thanks unto thee, For thy righteous regulations.
Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ nítorí òfin òdodo rẹ.
63 Companion, am I, to all who revere thee, and to them who keep thy precepts.
Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
64 Of thy lovingkindness, O Yahweh, the earth, is full, Thy statutes, teach thou me.
Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, Olúwa, kọ́ mi ní òfin rẹ.
65 [TETH.] Well, hast thou dealt with thy servant, O Yahweh, according to thy word.
Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.
66 Good judgment and knowledge, teach thou me, For, in thy commandments, have I trusted.
Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere, nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
67 Before I was afflicted, I myself was going astray, but, now, thy word, have I kept.
Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà, ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
68 Good, thou art, and doing good, Teach me thy statutes.
Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
69 Insolent men have plastered falsehood over me, I, with a whole heart, will observe thy precepts.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí, èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
70 Gross, like fat, is their heart, I, in thy law, have found dear delight.
Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú, ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
71 It is, well for me, that I was afflicted, That I might learn thy statutes.
Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
72 Better to me, is the law of thy mouth, than thousands of gold and silver.
Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.
73 [YODH.] Thine own hands, have made me, and formed me. Give me understanding, that I may learn thy commandments.
Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí; fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
74 They who revere thee, shall see me and rejoice, that, for thy word, I waited.
Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi, nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
75 I know, O Yahweh, that righteous are thy regulations, and, in faithfulness, didst thou afflict me.
Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni, àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
76 Let thy lovingkindness, I beseech thee, serve to comfort me, according to thy word to thy servant.
Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi, gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
77 Let thy compassions reach me, that I may live, for, thy law, is my dear delight.
Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè, nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
78 Let insolent men, be ashamed, because, by means of falsehood, they have dealt with me perversely, I, will meditate in thy precepts.
Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga nítorí wọn pa mí lára láìnídìí ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
79 Let them who revere thee, turn unto me, even they who know thy testimonies.
Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi, àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
80 Let my heart be thorough in thy statutes, that I may not be ashamed.
Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ, kí ojú kí ó má ṣe tì mí.
81 [KAPH.] My soul, hath languished for thy salvation, For thy word, have I hoped.
Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ, ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
82 Mine eyes have failed for thy word, saying, When wilt thou comfort me?
Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ; èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
83 Though I have been like a wine-skin in the smoke, thy statutes, have I not forgotten.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín, èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
84 How few are the days of thy servant! When wilt thou execute sentence on my persecutors?
Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó? Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
85 Insolent men digged for me pits, men who are not according to thy law.
Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi, tí ó lòdì sí òfin rẹ.
86 All thy commandments, are faithful, With falsehood, have they persecuted me, O help me!
Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé; ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
87 A little more, and they had consumed me in the earth, but, I, forsake not thy precepts.
Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé, ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
88 According to thy lovingkindness, give thou me life, so will I keep the testimonies of thy mouth.
Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ, èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.
89 [LAMED.] Age-abidingly, O Yahweh, hath thy word been set up in the heavens.
Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni; ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.
90 To generation after generation, is thy faithfulness, Thou hast established the earth, and it standeth.
Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran; ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
91 By thy regulations, do they stand to-day, for, all, are thy servants.
Òfin rẹ dúró di òní nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
92 Had not thy law been my dear delight, then, had I perished in mine affliction.
Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi, èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
93 Unto times age-abiding, will I not forget thy precepts, For, by them, hast thou given me life.
Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé, nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.
94 Thine, am I, —oh save me! For, thy precepts, have I sought.
Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
95 For me, have the lawless waited, to destroy me, Thy testimonies, will I diligently consider.
Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run, ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
96 To all perfection, have I seen an end, Broad is thy commandment, exceedingly.
Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin; ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.
97 [MEM.] Oh how I love thy law! All the day, is it my (meditation)
Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó! Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
98 Beyond mine enemies, will thy commandment make me wise, for, age-abidingly, shall it be mine.
Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ, nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
99 Beyond all my teachers, have I shown discretion, for, thy testimonies, are my (meditation)
Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ, nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
100 Beyond the elders, will I show understanding, for, thy precepts, have I observed.
Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ, nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
101 From every way of wickedness, have I withheld my feet, that I might keep thy word.
Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
102 From thy regulations, have I not turned aside, for, thou, hast directed me.
Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.
103 How smooth to my palate is thy speech, More than honey, to my mouth.
Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó, ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
104 Out of thy precepts, will I get understanding, For this cause, do I hate every false way.
Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ; nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.
105 [NUN.] A lamp to my feet, is thy word, and a light to my path.
Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.
106 I sware, and have fulfilled, To keep thy righteous regulations.
Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
107 I have been afflicted exceedingly, —O Yahweh, give me life according to thy word.
A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
108 The freewill offerings of my mouth, accept, I pray thee, O Yahweh, And, thy regulations, teach thou me.
Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi, kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
109 My life, is in my hand continually, Yet, thy law, have I not forgotten.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
110 The lawless have set a snare for me, Yet, from thy precepts, have I not strayed.
Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
111 As an inheritance have I taken thy testimonies unto times age-abiding, for, the joy of my heart, they are.
Òfin rẹ ni ogún mi láéláé; àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
112 I have inclined my heart to perform thy statutes, Age-abidingly, to the end.
Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́ láé dé òpin.
113 [SAMECH.] Half-hearted ones, do I hate, but, thy law, do I love.
Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì, ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
114 My hiding-place and my buckler, thou art, For thy word, have I waited.
Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
115 Depart from me, ye evil-doers, —that I may observe the commandments of my God.
Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú, kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
116 Uphold me according to thy word, that I may live, and do not shame me out of my hope!
Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, kí èmi kí ó lè yè Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
117 Sustain me, that I may be saved, and may find dear delight in thy statutes continually.
Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu; nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
118 Thou hast made light of all who stray from thy statutes, for their fraud is, falsehood.
Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
119 Dross, have I accounted all the lawless of the earth, therefore do I love thy testimonies.
Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́; nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
120 My flesh, bristled up from dread of thee, and, of thy regulations, stand I in fear.
Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀: èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.
121 [AYIN.] I have done justice and righteousness, —Do not leave me to mine oppressors.
Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́: má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
122 Be thou surety for thy servant for good, Let not insolent men oppress me.
Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú: má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
123 Mine eyes, have become dim for thy salvation, and for thy righteous word.
Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ, fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
124 Deal with thy servant according to thy lovingkindness, and, thy statutes, teach thou me.
Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
125 Thy servant, I am—give me understanding, so shall I get to know thy testimonies.
Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye kí èmi lè ní òye òfin rẹ
126 It is time that Yahweh should work, They have frustrated thy law!
Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa; nítorí òfin rẹ ti fọ́.
127 For this cause, do I love thy commandments, More than gold, yea than fine gold!
Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
128 For this cause, all thy precepts concerning all things, I deem right, Every way of falsehood, I hate.
nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀, èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.
129 [PE.] Wonderful are thy testimonies, For this cause, hath my soul observed them.
Òfin rẹ̀ ìyanu ni: nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
130 The opening of thy words, sheddeth light, Giving understanding to the simple.
Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá; ó fi òye fún àwọn òpè.
131 My mouth, have I opened wide, and panted, because, for thy commandments, have I longed.
Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ, nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
132 Turn thyself unto me, and show me favour, —As is befitting, to the lovers of thy Name.
Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi, bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
133 My steps, direct thou by thy word, and let no iniquity, have dominion over me.
Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ, má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
134 Set me free from the oppression of man, so will I keep thy precepts.
Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn, kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
135 Thy face, light thou up on thy servant, and teach me thy statutes.
Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
136 Streams of water, have run down mine eyes, because men have not kept thy law.
Omijé sàn jáde ní ojú mi, nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
137 [ZADHE.] Righteous art thou, O Yahweh, —and, equitable, are thy regulations.
Olódodo ni ìwọ Olúwa ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.
138 Thou hast righteously commanded thy testimonies, yea in great faithfulness.
Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo: wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
139 My zeal, hath put an end to me, for mine adversaries have forgotten thy words.
Ìtara mi ti pa mí run, nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
140 Refined is thy word, to the uttermost, and, thy servant loveth it.
Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
141 Small, am I, and despised, Thy precepts, have I not forgotten.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
142 Thy righteousness, is righteous to times age-abiding, and, thy law, is truth.
Òdodo rẹ wà títí láé òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
143 Straitness and distress, have befallen me, Thy commandments, are my dear delights.
Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi, ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.
144 Righteous are thy testimonies, unto times age-abiding, Give me understanding, that I may live.
Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé; fún mi ní òye kí èmi lè yè.
145 [KOPH.] I have cried out with all my heart, answer me, O Yahweh; Thy statutes, will I observe.
Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: dá mi lóhùn Olúwa, èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
146 I have cried out unto thee, oh save me, That I may keep thy testimonies.
Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
147 I forestalled the twilight, and cried for help, For thy word, I waited.
Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
148 Mine eyes forestalled the night-watches, To meditate in thy word.
Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru, nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
149 My voice, O hear, according to thy lovingkindness, O Yahweh! according to thy wont, give me life.
Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ: pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
150 They have drawn near, who pursue villainy, From thy law, have they gone far away.
Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí, ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
151 Near art thou, O Yahweh, and, all thy commandments, are truth.
Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa, àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
152 Long, have I known, from thy testimonies, That, to times age-abiding, thou didst establish them.
Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.
153 [RESH.] Behold mine affliction, and rescue me, For, thy law, have I not forgotten.
Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí, nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
154 Plead my cause, and redeem me, By thy word, give me life
Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
155 Far from the lawless, is salvation, For, thy statutes, have they not sought.
Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
156 Thy compassions, are great, O Yahweh, According to thy regulations, give me life.
Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
157 Many, are my persecutors and mine adversaries, From thy testimonies, have I not swerved.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi, ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
158 I have seen traitors, and felt loathing, Because, thy word, they kept not.
Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́ nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
159 See thou that, thy precepts, I have loved, O Yahweh, according to thy lovingkindness, give me life.
Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ; pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
160 The sum of thy word, is truth, and, age-abiding, is every one of thy righteous regulations.
Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ; gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
161 [SHIN.] Rulers, have persecuted me, without cause, But, of thy word, hath my heart stood in awe.
Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí, ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
162 Joyful am I over thy word, Like the finder of spoil in abundance.
Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
163 Falsehood, I hate and abhor, Thy law, do I love.
Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
164 Seven times in the day, have I praised thee, For thy righteous regulations.
Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́ nítorí òfin òdodo rẹ.
165 Blessing in abundance, have the lovers of thy law, and nothing to make them stumble.
Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ, kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
166 I have looked for thy salvation, O Yahweh, and, thy commandments, have I done.
Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa, èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
167 My soul hath kept thy testimonies, yea I have loved them greatly.
Èmi gba òfin rẹ gbọ́, nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.
168 I have kept thy precepts, and thy testimonies, For, all my ways, are before thee.
Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ, nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
169 [TAU] Let my shouting come near before thee, O Yahweh, According to thy word, give me understanding.
Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa; fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
170 Let my supplication come in before thee, According to thy word, deliver me.
Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
171 My lips, shall pour out, praise, When thou shalt teach me thy statutes.
Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde, nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
172 My tongue, shall respond, with thy word, For, all thy commandments, are righteous.
Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ, nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
173 Be thy hand ready to help me, For, thy statutes, have I chosen.
Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
174 I have longed for thy salvation, O Yahweh, and, thy law, is my dear delight.
Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa, àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
175 Let my soul live, that it may praise thee, So shall thy regulation help me.
Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́, kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
176 I have strayed like a wandering sheep, O seek thy servant, For, thy commandments, have I not forgotten.
Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù. Wá ìránṣẹ́ rẹ, nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.