< Numbers 29 >
1 And in the seventh month, on the first of the month, a holy convocation, shall there be unto you, no laborious work, shall ye do, —a day of loud acclamation, shall it be unto you.
“‘Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù keje, kí ẹ ní àpéjọ mímọ́, ẹ kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Ọjọ́ ìfùnpè ni ó jẹ́ fún yín.
2 Therefore shall ye offer, as an ascending-sacrifice for a satisfying odour unto Yahweh, one choice bullock one ram, —seven he-lambs a year old without defect;
Gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn sí Olúwa, ẹ pèsè ẹgbọrọ akọ màlúù kan, àgbò kan àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan aláìlábùkù, kí ẹ fi ẹbọ sísun.
3 and as their meal-offering, fine meal, overflowed with oil, —three-tenths to a bullock two-tenths to a ram;
Pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ wọn, ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi òróró pò, ìdámẹ́ta nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n fún akọ màlúù kan, àti ìdá méjì nínú mẹ́wàá, òsùwọ̀n fún àgbò kan,
4 and one-tenth to each lamb, —of the seven lambs;
àti ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n fún ọ̀dọ́-àgùntàn kan, àti fún ọ̀dọ́-àgùntàn méje.
5 and one young he-goat as a sin-bearer, —for putting a propitiatory-covering over you:
Àti òbúkọ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣètùtù fún yín.
6 in addition to the monthly ascending-sacrifice with the meal-offering thereof and the continual ascending sacrifice, with the meal-offering thereof and the drink-offering thereof according to their regulation, —for a satisfying odour, an altar-flame, unto Yahweh.
Pẹ̀lú ẹbọ sísun oṣù àti ẹbọ ohun jíjẹ rẹ̀ àti ẹbọ sísun ìgbà gbogbo àti ẹbọ mímu wọn gẹ́gẹ́ bí ìlànà wọn. Fún òórùn dídùn, ẹbọ tí a fi iná ṣe sí Olúwa.
7 And on the tenth of this seventh month, a holy convocation, shall there be unto you, —when ye shall humble your souls, —no work, shall ye do;
“‘Ní ọjọ́ kẹwàá nínú oṣù keje, kí ẹ ṣe àpéjọ mímọ́. Kí ẹ̀yin kí ó sẹ́ ara yín, ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan.
8 but ye shall bring near, as an ascending-sacrifice unto Yahweh a satisfying odour, one choice bullock one ram, —seven he-lambs a year old, without defect, shall they be for you;
Kí ẹ̀yin kí ó rú ẹbọ sísun olóòórùn dídùn sí Olúwa, ẹgbọrọ akọ màlúù kan, àgbò kan, àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn méje ọlọ́dún kan, kí wọn kí ó sì jẹ́ aláìlábùkù fún yín.
9 and, as their meal-offering, fine meal overflowed with oil, —three-tenths to a bullock, two-tenths to the one ram;
Pẹ̀lú akọ màlúù, pèsè ọrẹ ìdámẹ́wàá mẹ́ta, òsùwọ̀n ìyẹ̀fun tí a fi òróró pò àti ìdámẹ́wàá méjì òsùwọ̀n fún àgbò kan,
10 a tenth severally to each lamb, —of the seven lambs;
àti fún ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan, ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n.
11 one young he-goat as a sin-bearer, —in addition to, the propitiatory sin-bearer, and the continual ascending-sacrifice, with its meal-offering and their drink-offerings.
Pẹ̀lú akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, pẹ̀lú ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ fún ètùtù àti ẹbọ sísun gbogbo ìgbà àti ẹbọ jíjẹ rẹ̀ àti ẹbọ mímu wọn.
12 And on the fifteenth day of the seventh month, a holy convocation shall there be unto you, no laborious work, shall ye do, but ye shall celebrate a festival unto Yahweh, seven days.
“‘Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù keje, kí ẹ̀yin kí ó ní àpéjọ mímọ́, ẹ̀yin kò sì gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan. Kí ẹ̀yin kí ó sì ṣe àjọyọ̀ fún Olúwa fún ọjọ́ méje.
13 Then shall ye bring near as an ascending-sacrifice—an altar-flame of a satisfying odour unto Yahweh, —thirteen choice bullocks two rams, —fourteen he-lambs a year old without defect, shall they be;
Kí ẹ sì rú ẹbọ sísun kan, ẹbọ tí a fi iná ṣe, tí ó ní òórùn dídùn sí Olúwa, ẹbọ tí ẹgbọrọ akọ màlúù mẹ́tàlá, àgbò méjì àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́rìnlá tí ó jẹ́ ọdún kan, tí gbogbo rẹ̀ sì jẹ́ aláìlábùkù.
14 and, as their meal-offering, fine-meal overflowed with oil, three-tenths to each bullock of the thirteen bullocks, two-tenths to each ram, of the two rams;
Àti ẹbọ ohun jíjẹ wọn, ìyẹ̀fun tí a fi òróró pò, ìdámẹ́wàá mẹ́ta òsùwọ̀n fún akọ màlúù kan, bẹ́ẹ̀ ni fún akọ màlúù mẹ́tẹ̀ẹ̀tàlá, ìdámẹ́wàá méjì òsùwọ̀n fún àgbò kan, bẹ́ẹ̀ ni fún àgbò méjèèjì,
15 and a tenth severally, to each lamb, —of the fourteen lambs;
àti fún ọ̀kọ̀ọ̀kan ọ̀dọ́-àgùntàn kan. Bẹ́ẹ̀ ni fún ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́rẹ̀ẹ̀rìnlá.
16 also one young he-goat, as a sin-bearer, —in addition to the continual ascending-sacrifice, the meal-offering thereof and the drink-offering thereof.
Àti akọ ewúrẹ́ kan gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, pẹ̀lú ẹbọ sísun gbogbo ìgbà ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu rẹ̀.
17 And on the second day, twelve choice bullocks two rams, —fourteen he-lambs a year old without defect;
“‘Àti ní ọjọ́ kejì ni kí ẹ̀yin kí ó fi ẹgbọrọ akọ màlúù méjìlá, àgbò méjì àti ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́rìnlá ọlọ́dún kan aláìlábùkù rú ẹbọ.
18 with their meal-offerings and their drink-offerings—to the bullocks, to the rams, and to the lambs, by their number according to the regulation;
Pẹ̀lú fún akọ màlúù, fún àgbò, àti fún ọ̀dọ́-àgùntàn kí ẹ pe ẹbọ ohun jíjẹ, àti ẹbọ ohun mímu, kí ó jẹ́ bí iye wọn, gẹ́gẹ́ bí ìlànà.
19 also one young he-goat as a sin-bearer, —in addition to the continual ascending-sacrifice, with its meal-offering, and their drink-offerings.
Àti òbúkọ fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun gbogbo ìgbà pẹ̀lú ẹbọ jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu.
20 And on the third day, eleven bullocks two rams, —and fourteen he-lambs a year old without defect;
“‘Ní ọjọ́ kẹta, pèsè akọ màlúù mọ́kànlá, àgbò méjì, akọ àgùntàn mẹ́rìnlá ti ọdún kan tí kò ní àbùkù.
21 with their meal-offering and their drink-offerings, to the bullocks, to the rams, and to the lambs, by their number, according to the regulation;
Pẹ̀lú akọ màlúù, àgbò, àti akọ àgùntàn, pèsè ọrẹ ohun jíjẹ àti ohun mímu gẹ́gẹ́ bí iye wọn.
22 also one young he-goat as a sin-bearer, in addition to the continual ascending-sacrifice, with the meal-offering thereof and the drink-offering thereof.
Pẹ̀lú akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àti ẹbọ sísun ìgbà gbogbo pẹ̀lú ẹbọ jíjẹ àti ẹbọ mímu.
23 And on the fourth day, ten bullocks, two rams, —fourteen he-lambs a year old without defect;
“‘Ní ọjọ́ kẹrin, pèsè akọ màlúù mẹ́wàá, àgbò méjì, àti ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́rìnlá ti ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan tí kò ní àbùkù.
24 their meal-offering, and their drink-offerings, to the bullocks, to the rams, and to the lambs, by their number, according to the regulation;
Àti akọ màlúù, àgbò àti àgùntàn, pèsè ẹbọ jíjẹ àti ẹbọ mímu gẹ́gẹ́ bí iye wọn, gẹ́gẹ́ bí ìlànà.
25 also one he-goat as a sin-bearer, —in addition to the continual ascending-sacrifice, the meal-offering thereof and the drink-offering thereof.
Àti akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun gbogbo ìgbà, pẹ̀lú ẹbọ jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu.
26 And on the fifth day, nine bullocks two rams, —fourteen he-lambs, a year old without defect;
“‘Àti ní ọjọ́ karùn-ún, pèsè akọ màlúù mẹ́sàn-án, àgbò méjì àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́rìnlá ti ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan, tí gbogbo rẹ̀ kò ní àbùkù.
27 with their meal-offering and their drink-offerings, —to the bullocks to the rams, and to the lambs, by their number, according to the regulation:
Pẹ̀lú akọ màlúù, àgbò àti ọ̀dọ́-àgùntàn, pèsè ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu gẹ́gẹ́ bí iye wọn sí ìlànà.
28 also one young he-goat as a sin-bearer, —in addition to the continual ascending-sacrifice, with the meal-offering thereof and the drink-offering thereof.
Àti akọ ewúrẹ́ kan gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun ìgbà gbogbo pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu.
29 And on the sixth day, eight bullocks, two rams, fourteen he-lambs a year old without defect;
“‘Ní ọjọ́ kẹfà, pèsè akọ màlúù mẹ́jọ, àgbò ọlọ́dún kan tí gbogbo rẹ̀ kò ní àbùkù.
30 with their meal-offering and their drink-offerings to the bullocks, to the rams, and to the lambs, by their number, according to the regulation;
Pẹ̀lú akọ màlúù, àgbò, àti ọ̀dọ́-àgùntàn, pèsè ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu gẹ́gẹ́ bí iye wọn.
31 also one young he-goat as a sin-bearer, —in addition to the continual ascending-sacrifice, the meal-offering thereof and the drink-offerings thereof,
Pẹ̀lú akọ ewúrẹ́ kan gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, pẹ̀lú ẹbọ sísun gbogbo ìgbà pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu.
32 And on the seventh day, seven bullocks, two rams, fourteen he-lambs a year old, with-out defect:
“‘Àti ní ọjọ́ keje, pèsè akọ màlúù méje, àgbò méjì, àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́rìnlá ti ọlọ́dún kan, tí gbogbo rẹ̀ kò sì ní àbùkù.
33 with their meal-offering and their drink-offering, to the bullock, to the rams, and to the lambs by their number, according to their regulation;
Pẹ̀lú akọ màlúù, àgbò, àti ọ̀dọ́-àgùntàn, pèsè ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu fún wọn gẹ́gẹ́ bí iye wọn.
34 also one young he-goat as a sin-bearer, in addition to the continual ascending-sacrifice, the meal-offering thereof and the drink-offering thereof
Pẹ̀lú akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, pẹ̀lú ẹbọ sísun gbogbo ìgbà, pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu.
35 [And] on the eighth day, a closing feast shall there be unto you, no laborious work, shall ye do;
“‘Àti ní ọjọ́ kẹjọ kí ẹ̀yin kó ní àpéjọ, kí ẹ má sì ṣe iṣẹ́ kankan.
36 but ye shall bring near—as an ascending-sacrifice, an altar-flame of a satisfying odour, unto Yahweh—one bullock, one ram, —seven he-lambs a year old, without defect:
Kí ẹ̀yin ṣe ìgbékalẹ̀ ẹbọ tí a fi iná ṣe tí ó ní òórùn dídùn sí Olúwa, ẹbọ sísun ti akọ màlúù kan, àgbò ọlọ́dún kan àti ọ̀dọ́-àgùntàn ọlọ́dún kan méje, gbogbo rẹ̀ tí kò ní àbùkù.
37 [with] their meal-offering and their drink-offerings—to the bullock to the ram, and to the lambs—by their number, according to the regulation;
Pẹ̀lú akọ màlúù, àgbò, àti ọ̀dọ́-àgùntàn, pèsè fún wọn ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu gẹ́gẹ́ bí iye wọn.
38 also one young he-goat as a sin-bearer, —in addition to the continual ascending-sacrifice, with the meal-offering thereof, and the drink-offering thereof.
Àti akọ ewúrẹ́ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun gbogbo ìgbà àti ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu.
39 These, shall ye offer unto Yahweh in your appointed seasons, —besides your vow-offerings and your freewill offerings—as your ascending-sacrifices, and as your meal-offerings, and as your drink-offerings and as your peace-offerings.
“‘Pẹ̀lú ẹ̀jẹ́ yín, àti ẹbọ àtinúwá yín, kí ẹ̀yin kí o pèsè fún Olúwa ní àjọ̀dún tí a yàn yín, ẹbọ sísun, ẹbọ ohun jíjẹ, ẹbọ ohun mímu àti ẹbọ ìkẹ́gbẹ́ yín.’”
40 So Moses told the sons of Israel, —According to all that Yahweh commanded Moses.
Mose sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli gbogbo ohun tí Olúwa ti pàṣẹ fún un.