< Leviticus 24 >
1 And Yahweh spake unto Moses, saying:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Command the sons of Israel, That they bring unto thee—pure oil olive, beaten, for giving light, —to cause the lamp to burn up continually.
“Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli láti mú òróró tí ó mọ́ tí a fún láti ara olifi wá láti fi tan iná, kí fìtílà lè máa jò láì kú.
3 Outside the veil of the testimony, in the tent of meeting, shall Aaron order it, from evening until morning, before Yahweh continually, —a statute age-abiding, to your generations.
Lẹ́yìn aṣọ ìkélé ti ibi àpótí ẹ̀rí tí ó wà ní inú àgọ́ ìpàdé, ni kí Aaroni ti tan iná náà níwájú Olúwa, láti ìrọ̀lẹ́ di àárọ̀ lójoojúmọ́. Èyí yóò jẹ́ ìlànà ayérayé fún àwọn ìran tí ń bọ̀.
4 Upon the pure lampstand, shall he order the lamps, —before Yahweh, continually.
Àwọn Àtùpà tí wọ́n wà lórí ojúlówó ọ̀pá fìtílà tí a fi wúrà ṣe níwájú Olúwa ni kí ó máa jó lójoojúmọ́.
5 And thou shalt take fine meal, and bake it, in twelve cakes, —of two-tenths, shall each cake be.
“Mú ìyẹ̀fun dáradára, kí o sì ṣe ìṣù àkàrà méjìlá, kí o lo ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n efa (èyí jẹ́ lita mẹ́rin ààbọ̀) fún ìṣù kọ̀ọ̀kan.
6 And thou shalt set them in two rows, six in a row, —upon the pure table, before Yahweh.
Tò wọ́n sí ọ̀nà ìlà méjì, mẹ́fà mẹ́fà ní ìlà kọ̀ọ̀kan lórí tábìlì tí a fi ojúlówó wúrà bọ̀. Èyí tí ó wà níwájú Olúwa.
7 And thou shalt put upon each row pure frankincense, —so shall it belong unto the bread as a memorial, an altar-flame unto Yahweh.
Ẹ fi ojúlówó tùràrí sí ọnà kọ̀ọ̀kan, gẹ́gẹ́ bí ìpín ìrántí láti dípò àkàrà, àti láti jẹ ẹbọ sísun sí Olúwa.
8 Sabbath day by sabbath day, shall he order it before Yahweh continually, —from the sons of Israel as an age-abiding covenant:
Àkàrà yìí ni kí ẹ gbé wá síwájú Olúwa nígbàkígbà, lọ́ṣọ̀ọ̀ṣẹ̀, nítorí tí àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí májẹ̀mú ayérayé.
9 so shall it be for Aaron and for his sons, and they shall eat it in a holy place, —for most holy, shall it be unto him from among the altar-flames of Yahweh, a statute age-abiding.
Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ló ni í. Wọ́n gbọdọ̀ jẹ ẹ́ ní ibi mímọ́ torí pé ó jẹ́ ipa tí ó mọ́ jùlọ ti ìpín wọn ojoojúmọ́ nínú ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa.”
10 And forth went the son of a woman of Israel—he being the son of a man of Egypt—in the midst of the sons of Israel;
Ọmọkùnrin kan wà tí ìyá rẹ̀ jẹ́ ọmọ Israẹli baba rẹ̀ sì jẹ́ ará Ejibiti. Ó jáde lọ láàrín àwọn ọmọ Israẹli, ìjà sì ṣẹlẹ̀ nínú àgọ́ láàrín òun àti ọmọ Israẹli kan.
11 and the son of the woman of Israel, and a man of Israel, reviled one another in the camp. And the son of the Israelitish woman uttered contemptuously the Name, and reviled. So they brought him in unto Moses, —now, the name of his mother, was Shelomith, daughter of Dibri, of the tribe of Dan;
Ọmọkùnrin arábìnrin Israẹli náà sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa pẹ̀lú èpè, wọ́n sì mú un tọ Mose wá. (Orúkọ ìyá rẹ̀ ní Ṣelomiti, ọmọbìnrin Debiri, ti ẹ̀yà Dani.)
12 and they put him in ward, —that a clear answer might be given to them at the mouth of Yahweh.
Wọ́n fi í sínú túbú kí Olúwa to sọ ohun tí wọn yóò ṣe fún wọn.
13 Then spake Yahweh unto Moses, saying:
Olúwa sì sọ fún Mose pé,
14 Bring forth him that reviled unto the outside of the camp, then shall all that heard [him] lean their hands upon his head, —and all the assembly shall stone him.
“Mú asọ̀rọ̀-òdì náà jáde wá sẹ́yìn àgọ́, kí gbogbo àwọn tí ó gbọ́ pé ó ṣépè gbé ọwọ́ wọn lórí ọkùnrin náà láti fihàn pé ó jẹ̀bi. Lẹ́yìn náà ni kí gbogbo àpéjọpọ̀, sọ ọ́ ní òkúta pa.
15 And, unto the sons of Israel, shalt thou speak saying, —What man soever curseth his God shall bear his sin.
Sọ fún àwọn ará Israẹli pé, ‘Bí ẹnikẹ́ni bá ṣépè lé Ọlọ́run rẹ̀, yóò jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀.
16 And, he that contemptuously uttereth the name of Yahweh, shall be, surely put to death, all the assembly shall, surely stone, him, —as the sojourner so the home-born, when he contemptuously uttereth the Name, he shall be put to death.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa ni kí ẹ pa, kí gbogbo àpéjọpọ̀ sọ ọ́ ní òkúta pa, yálà àlejò ni tàbí ọmọ bíbí Israẹli, bí ó bá ti sọ̀rọ̀-òdì sí orúkọ Olúwa, pípa ni kí ẹ pa á.
17 And, when, any man, by smiting taketh the life of any human being, he shall be surely put to death,
“‘Ẹni tí ó bá gba ẹ̀mí ènìyàn pípa ni kí ẹ pa á.
18 And he that by smiting taketh away the life of a beast, shall make it good, —life for life.
Ẹni tí ó bá gba ẹ̀mí ẹran ọ̀sìn ẹlòmíràn, kí ó dá a padà—ẹ̀mí dípò ẹ̀mí.
19 And, when, any man, inflicteth a blemish upon his neighbour, as he hath done, so, shall it be done to him:
Bí ẹnìkan bá pa ẹnìkejì rẹ̀ lára, ohunkóhun tí ó ṣe ni kí ẹ ṣe sí i.
20 fracture for fracture, eye for eye, tooth for tooth, as he inflicteth a blemish upon a human being, so, shall one be inflicted upon him.
Ẹ̀yà fún ẹ̀yà, ojú fún ojú, eyín fún eyín; bí òun ti ṣe àbùkù sí ara ènìyàn, bẹ́ẹ̀ ni kí a ṣe sí i.
21 And he that killeth a beast, shall make it good, -and he that killeth a human being, shall be put to death.
Ẹni tí ó bá sì lu ẹran pa, kí ó sán an padà; ẹni tí ó bá sì lu ènìyàn pa, a ó pa á.
22 One rule, shall ye have, as the sojourner, so the home-born, shall be, —For, I—Yahweh, am your God.
Òfin kan náà ló wà fún àlejò àti fún ọmọ Israẹli. Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
23 So then Moses spake unto the sons of Israel, and they took forth the reviler, unto the outside of the camp, and stoned him with stones. Thus, the sons of Israel did, as Yahweh commanded Moses.
Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì mú asọ̀rọ̀-òdì náà lọ sí ẹ̀yìn àgọ́, wọ́n sì sọ ọ́ ní òkúta pa. Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mose.