< Judges 3 >

1 Now, these, are the nations which Yahweh left, that he might, by them, put Israel to the proof, —all who had not known any of the wars of Canaan;
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn orílẹ̀-èdè tí Olúwa fi sílẹ̀ láti dán àwọn ìran tuntun ní Israẹli wò, àwọn ìran tí kò ì tí ì ní ìrírí ogun àwọn ará Kenaani.
2 that the generations of the sons of Israel might certainly get to know, by being taught to make war, —such, at least, as aforetime knew nothing thereof: —
(Ó ṣe èyí láti fi kọ́ àwọn ìran Israẹli tí kò rí ogun rí níbí a ti ṣe ń jagun).
3 five lords of the Philistines, and all the Canaanites, and the Zidonians, and the Hivites dwelling in Mount Lebanon, —from Mount Baal-hermon as far as the entering in of Hamath.
Àwọn ìjòyè ìlú Filistini márààrún, gbogbo àwọn ará Kenaani, àwọn ará Sidoni, àti àwọn ará Hifi tí ń gbé ní àwọn òkè Lebanoni bẹ̀rẹ̀ láti òkè Baali-Hermoni títí dé Lebo-Hamati.
4 So then [these] were [left], that, by them, he might put Israel to the proof, —to know whether they would hearken unto the commandments of Yahweh which he commanded their fathers by the hand of Moses.
A fi àwọn ènìyàn náà sílẹ̀ láti dán àwọn Israẹli wò bóyá wọn yóò gbọ́rọ̀ sí àwọn òfin Olúwa, èyí tí ó ti fi fún àwọn baba wọn láti ipasẹ̀ Mose.
5 And thus, the sons of Israel, dwelt in the midst of the Canaanites, —the Hittites, and the Amorites, and the Perizzites, and the Hivites, and the Jebusites;
Àwọn ọmọ Israẹli gbé láàrín àwọn ará Kenaani, àwọn ará Hiti àwọn ará Amori, àwọn ará Peresi, àwọn ará Hifi àti àwọn ará Jebusi.
6 and took their daughters to be their wives, their own daughters moreover, gave they unto their sons, and they served their gods.
Dípò kí wọ́n run àwọn ènìyàn wọ̀nyí, Israẹli ń fẹ́ àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n sì ń fi àwọn ọmọbìnrin Israẹli fún àwọn ará ilẹ̀ náà ní aya, wọ́n sì ń sin àwọn òrìṣà wọn.
7 Thus did the sons of Israel the thing that was wicked in the sight of Yahweh, and forgat Yahweh their God, —and served the Baals and the Asherahs.
Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe èyí tí ó burú níwájú Olúwa, wọ́n gbàgbé Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì ń sin Baali àti Aṣerah.
8 Then kindled the anger of Yahweh upon Israel, and he sold them into the hand of Chushan-rishathaim, king of Mesopotamia, —and the sons of Israel served Chushan-rishathaim, eight years.
Ìbínú Olúwa sì ru sí Israẹli tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ kí Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu-Naharaimu bá wọn jà kí ó sì ṣẹ́gun wọn, Israẹli sì ṣe ẹrú rẹ̀ fún ọdún mẹ́jọ.
9 And the sons of Israel made outcry unto Yahweh, so Yahweh raised up a saviour unto the sons of Israel, who saved them, —even Othniel son of Kenaz, Caleb’s younger brother.
Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli kígbe sí Olúwa, Òun gbé olùgbàlà kan dìde fún wọn, ẹni náà ni Otnieli ọmọ Kenasi àbúrò Kalebu tí ó jẹ́ ọkùnrin, ẹni tí ó gbà wọ́n sílẹ̀.
10 And the Spirit of Yahweh came upon him, and he judged Israel, and went out to war, and Yahweh delivered into his hand, Chushan-rishathaim, king of Syria, —and his hand prevailed over Chushan-rishathaim.
Ẹ̀mí Olúwa bà lé e, òun sì ṣe ìdájọ́ Israẹli, ó sì síwájú wọn lọ sí ogun. Olúwa sì fi Kuṣani-Riṣataimu ọba Aramu lé Otnieli lọ́wọ́, ẹni tí ọwọ́ rẹ̀ sì borí Kuṣani-Riṣataimu.
11 And the land had rest forty years, —and Othniel son of Kenaz, died.
Ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ogójì ọdún títí tí Otnieli ọmọ Kenasi sì kú.
12 And the sons of Israel again did the thing that was wicked, in the sight of Yahweh, —and Yahweh emboldened Eglon, king of Moab, against Israel, because they did the thing that was wicked in the sight of Yahweh;
Àwọn ọmọ Israẹli sì tún padà sí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn, wọ́n sì ṣe èyí tí ó burú ní iwájú Olúwa, fún ìdí iṣẹ́ búburú yìí, Olúwa fún Egloni, ọba àwọn Moabu ní agbára ní orí Israẹli.
13 and he gathered unto him, the sons of Ammon, and Amalek, —and came and smote Israel, and took possession of the city of palm-trees.
Pẹ̀lú ìfi ọwọ́ ṣowọ́pọ̀ ogun àwọn Ammoni àti àwọn ọmọ-ogun Amaleki ní Egloni gbógun ti àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì gba ìlú Ọ̀pẹ tí i se Jeriko.
14 So the sons of Israel served Eglon king of Moab, eighteen years.
Àwọn ọmọ Israẹli sì sin Egloni ọba Moabu fún ọdún méjìdínlógún.
15 And the sons of Israel made outcry unto Yahweh, and Yahweh raised up unto them a saviour, Ehud son of Gera, a Benjamite, a man left-handed, —and the sons of Israel sent, by his hand, a present, unto Eglon king of Moab.
Ṣùgbọ́n nígbà tí Israẹli tún ké pe Olúwa, Olúwa rán olùgbàlà kan sí wọn, Ehudu ẹni tí ń lo ọwọ́ òsì, ọmọ Gera ti ẹ̀yà Benjamini. Àwọn ọmọ Israẹli fi ẹ̀bùn rán sí Egloni ọba Moabu.
16 So Ehud made himself a sword which had two edges, a cubit in length, —and girded it under his raiment, upon his right thigh.
Ehudu sì rọ idà kan olójú méjì, ìgbọ̀nwọ́ kan ní gígùn; òun sì sán an ní abẹ́ aṣọ rẹ̀ ní itan rẹ̀ ọ̀tún.
17 So he offered the present unto Eglon, king of Moab, —now, Eglon, was an exceedingly fat man.
Ó sì mú ọrẹ náà wá fún Egloni ọba Moabu, Egloni ẹni tí ó sanra púpọ̀.
18 And so it was, when he had made an end of offering the present, that he sent away the people who had been bearing the present;
Lẹ́yìn tí Ehudu ti fi ẹ̀bùn náà fún ọba tan, ó rán àwọn tí ó kó ẹrú náà wá lọ sí ọ̀nà wọn.
19 but, he himself, turned back from the images that were by Gilgal, and said, A secret word, have I, unto thee, O king! And he said—Silence! Thereupon went out from his presence all who had been standing near him.
Ṣùgbọ́n nígbà tí òun fúnra rẹ̀ dé ibi ère fínfín tí ó wà létí Gilgali, ó padà sí Egloni, ó sì wí pé, “Ọba, mo ní ọ̀rọ̀ àṣírí láti bá ọ sọ.” Ọba sì wí pé, “Ẹ dákẹ́!” Gbogbo àwọn tí ń ṣọ sì jáde síta kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
20 And, Ehud, came in unto him, he, having been sitting in a summer parlour, which he had for himself, alone, and Ehud said, A divine word, have I, unto thee. So he arose from off his seat.
Ehudu lọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀ níbi tí ó ti jókòó ní iyàrá ìtura rẹ̀, Ehudu sì wí fún un pé, “Mo ní ọ̀rọ̀ kan fún ọ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.” Bí ọba sì ti dìde ní orí ìtẹ́ rẹ̀,
21 And Ehud put forth his left hand, and took the sword from off his right thigh, —and thrust it into his body;
Ehudu fi ọwọ́ òsì rẹ̀ yọ idà láti ibi itan ọ̀tún rẹ̀ ó sì fi gún ọba nínú ikùn rẹ̀.
22 and, the handle also, went in after the blade, and the flesh closed upon the blade, for he withdrew not the sword out of his body, —and he came out into the ante-chamber.
Àti idà àti èèkù rẹ̀ sì wọlé ó sì yọ ní ẹ̀yìn rẹ̀. Ehudu kò yọ idà náà, ọ̀rá sì bo idà náà.
23 And, when Ehud came out into the porch, he closed the doors of the parlour upon him, and bolted them.
Ehudu ti àwọn ìlẹ̀kùn ní àtì-sínú òun sì bá yàrá òkè jáde, ó sì sálọ.
24 When, he, had come out, his servants, went in, and looked, and lo! the doors of the parlour were bolted, —so they said, Surely he covereth his feet, in the summer chamber.
Lẹ́yìn tí ó ti lọ àwọn ìránṣẹ́ ọba dé, ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí ìlẹ̀kùn yàrá òkè ní títì, wọ́n rò pé, “Bóyá ó wà ní ilé ìyàgbẹ́ ní yàrá nínú ilé.”
25 But, though they tarried a long time, yet lo! he opened not the doors of the parlour, —so they took the key, and opened [them], when lo! their lord, fallen to the ground dead.
Nígbà tí wọ́n dúró dé ibi pé ó jẹ́ ìyanu fún wọn, wọ́n mú kọ́kọ́rọ́, wọ́n sì ṣí ìlẹ̀kùn. Níbẹ̀ ni wọ́n ti rí Olúwa wọn tí ó ti ṣubú, ó sì ti kú.
26 But, Ehud, escaped while they delayed, —yea, he, passed the images, and escaped into Seirah.
Nígbà tí wọ́n dúró tí wọn sì ń retí, Ehudu ti sálọ. Ó ti gba ibi tí wọ́n ti ń gbẹ́ òkúta lére, ó sì sálọ sí Seira.
27 And so it was, when he came, that he blew with a horn, throughout the hill country of Ephraim, —and the sons of Israel came down with him, out of the hill country, he, being before them.
Nígbà tí ó dé ibẹ̀, ó fọn ìpè ní orí òkè Efraimu, àwọn ọmọ Israẹli sì ba sọ̀kalẹ̀ lọ láti òkè náà wá, òun sì wà níwájú wọn.
28 And he said unto them—Come down after me, for Yahweh hath delivered your enemies, the Moabites, into your hand. So they came down after him, and captured the fords of the Jordan, towards Moab, and suffered not a man to pass over.
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ máa tẹ̀lé mi, nítorí Olúwa ti fi Moabu ọ̀tá yín lé yín lọ́wọ́.” Wọ́n sì tẹ̀lé e, wọ́n sì gba ìwọdò Jordani tí ó lọ sí ilẹ̀ Moabu, wọn ò jẹ́ kí ẹnikẹ́ni kọjá.
29 And they smote of Moab, at that time, about ten thousand men, every one a mighty man, and every one a man of valour, —and, there escaped not a man.
Ní báyìí, wọ́n ti pa tó ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọkùnrin ará Moabu tí wọ́n jẹ́ alágbára àti onígboyà ènìyàn, kò sí ènìyàn tí ó sálà.
30 And Moab was subdued on that day, under the hand of Israel. And the land had rest eighty years, and Ehud judged them until his death.
Ní ọjọ́ náà ni Israẹli ṣẹ́gun àwọn ará Moabu, ilẹ̀ náà sì wà ní àlàáfíà fún ọgọ́rin ọdún.
31 And, after him, was Shamgar, son of Anath, who smote of the Philistines, six hundred men, with an ox-goad, —and, he also, saved Israel.
Lẹ́yìn Ehudu, ni Ṣamgari ọmọ Anati ẹni tí ó pa ẹgbẹ̀ta Filistini pẹ̀lú ọ̀pá tí a fi ń da akọ màlúù, òun pẹ̀lú sì gba Israẹli kúrò nínú ìpọ́njú.

< Judges 3 >