< Jonah 3 >
1 Then came the word of Yahweh unto Jonah, the second time, saying:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jona wá nígbà kejì wí pé:
2 Arise, get thee unto Nineveh, the great city, —and cry against it the cry that I am bidding thee.
“Dìde lọ sí Ninefe, ìlú ńlá a nì, kí o sì kéde sí i, ìkéde tí mo sọ fún ọ.”
3 So Jonah arose, and went his way unto Nineveh, according to the word of Yahweh, —Nineveh, being a city great before God, of three days’ journey.
Jona sì dìde ó lọ sí Ninefe gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa. Ninefe jẹ́ ìlú títóbi gidigidi, ó tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta.
4 So Jonah began to enter into the city, one day’s journey, —and he cried out and said—Yet forty days, and, Nineveh, is to be overthrown!
Jona sì bẹ̀rẹ̀ sí wọ ìlú náà lọ ní ìrìn ọjọ́ kan, ó sì ń kéde, ó sì wí pé, “Níwọ́n ogójì ọjọ́ sí i, a ó bi Ninefe wó.”
5 And the people of Nineveh believed in God, —and proclaimed a fast, and clothed themselves in sackcloth, from the greatest of them, even unto the least of them.
Àwọn ènìyàn Ninefe sì gba Ọlọ́run gbọ́. Wọ́n sì kéde àwẹ̀, gbogbo wọ́n sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, bẹ̀rẹ̀ láti orí ọmọdé títí dé orí àgbà wọn.
6 And the word reached unto the king of Nineveh, so he arose from his throne, and laid aside his robe from off him, —and covered him with sackcloth, and sat on ashes.
Ọ̀rọ̀ náà sì dé ọ̀dọ̀ ọba Ninefe, ó sì dìde kúrò lórí ìtẹ́ rẹ̀, ó sì bọ́ aṣọ ìgúnwà rẹ̀ kúrò lára rẹ̀, ó sì da aṣọ ọ̀fọ̀ bora, ó sì jókòó nínú eérú.
7 And he caused an outcry to be made—and said—throughout Nineveh, By decree of the king and of his great men, Be it known: —Man and beast, herd and flock, Let them taste, nothing, let them not feed, and, water, let them not drink:
Nígbà náà ní ó kéde rẹ̀ ni Ninefe pé, “Kí a la Ninefe já nípa àṣẹ ọba, àti àwọn àgbàgbà rẹ̀ pé: “Má ṣe jẹ́ kí ènìyàn, tàbí ẹranko, ọ̀wọ́ ẹran tàbí agbo ẹran, tọ́ ohunkóhun wò, má jẹ́ kí wọn jẹ tàbí mu omi.
8 Let both man and beast, cover themselves with sackcloth, and let them cry unto God, mightily, —Yea let them turn, every man from his wicked way, and from the violence which is in their hands:
Ṣùgbọ́n jẹ́ kí ènìyàn àti ẹranko da aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara, kí wọn sì kígbe kíkan sí Ọlọ́run, sì jẹ́ kí wọn yípadà, olúkúlùkù kúrò ní ọ̀nà ibi rẹ̀ àti kúrò ní ìwà ìpa tí ó wà lọ́wọ́ wọn.
9 Who knoweth whether God himself—may turn and grieve, —and turn away from the glow of his anger, that we perish not?
Ta ni ó lè mọ̀ bí Ọlọ́run yóò yípadà kí ó sì ronúpìwàdà, kí ó sì yípadà kúrò ní ìbínú gbígbóná rẹ̀, kí àwa má ṣègbé?”
10 And God saw their doings, that they turned from their wicked way, —and God was grieved over the calamity which he had spoken of executing upon them, and executed it not.
Ọlọ́run sì rí ìṣe wọn pé wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀nà ibi wọn, Ọlọ́run sì ronúpìwàdà ibi tí òun ti wí pé òun yóò ṣe sí wọn, òun kò sì ṣe e mọ́.