< John 5 >
1 After these things, was a feast of the Jews, and Jesus went up unto Jerusalem.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, àjọ àwọn Júù kan kò; Jesu sì gòkè lọ sí Jerusalẹmu.
2 Now there is in Jerusalem, at the Sheep-gate, a pool, which is called in Hebrew Bethzatha, —having, five porches.
Adágún omi kan sì wà ní Jerusalẹmu, létí bodè àgùntàn, tí a ń pè ní Betisaida ní èdè Heberu, tí ó ní ẹnu-ọ̀nà márùn-ún.
3 In these, was lying a throng of them who were sick, —blind, lame, withered.
Ní ẹ̀gbẹ́ odò yìí ni ọ̀pọ̀ àwọn abirùn ènìyàn máa ń gbé dùbúlẹ̀ sí, àwọn afọ́jú, arọ àti aláàrùn ẹ̀gbà.
5 And there was a certain man there, who, for thirty-eight years, had continued in his sickness.
Ọkùnrin kan wà níbẹ̀, ẹni tí ó tí wà ní àìlera fún ọdún méjìdínlógójì.
6 Jesus, seeing, this one, lying, and taking note that now, a long time, had he continued, saith unto him—Desirest thou to be made, well?
Bí Jesu ti rí i ní ìdùbúlẹ̀, tí ó sì mọ̀ pé ó pẹ́ tí ó ti wà bẹ́ẹ̀, ó wí fún un pé, “Ìwọ fẹ́ kí a mú ọ láradá bí?”
7 The sick man answered him—Sir! I have, no man, that, as soon as the water hath been troubled, might thrust me into the pool; but, while, I, am coming, another, before me, goeth down.
Abirùn náà dá a lóhùn wí pé, “Arákùnrin, èmi kò ní ẹni tí ìbá gbé mi sínú adágún, nígbà tí a bá ń rú omi náà, bí èmi bá ti ń bọ̀ wá, ẹlòmíràn a sọ̀kalẹ̀ sínú rẹ̀ síwájú mi.”
8 Jesus saith unto him—Rise! take up thy couch, and be walking.
Jesu wí fún un pé, “Dìde, gbé àkéte rẹ, kí o sì máa rìn.”
9 And, straightway, the man was made well and took up his couch, and began to walk. Now it was Sabbath, on that day.
Lọ́gán, a sì mú ọkùnrin náà láradá, ó sì gbé àkéte rẹ̀, ó sì ń rìn. Ọjọ́ náà sì jẹ́ ọjọ́ ìsinmi.
10 The Jews, therefore, were saying, unto him who had been cured—It is, Sabbath; and it is not allowable for thee to take up thy couch: —
Nítorí náà àwọn Júù wí fún ọkùnrin náà tí a mú láradá pé, “Ọjọ́ ìsinmi ni òní; kò tọ́ fún ọ láti gbé àkéte rẹ.”
11 who, however, answered them—He that made me well, he, unto me, said—Take up thy couch, and be walking.
Ó sì dá wọn lóhùn wí pé, “Ẹni tí ó mú mi láradá, ni ó wí fún mi pé, ‘Gbé àkéte rẹ, kí o sì máa rìn.’”
12 They questioned him—Who is the man that said unto thee, Take up [thy couch], and be walking?
Nígbà náà ni wọ́n bi í lérè wí pé, “Ọkùnrin wo ni ẹni tí ó wí fún ọ pé gbé àkéte rẹ, kí o sì máa rìn?”
13 But, the healed one, knew not, who, it was; for, Jesus, had turned aside, a multitude, being in the place.
Ẹni tí a mú láradá náà kò sì mọ̀ ẹni tí ó jẹ́ nítorí Jesu ti kúrò níbẹ̀, àwọn ènìyàn púpọ̀ wà níbẹ̀.
14 After these things, Jesus findeth him, in the temple, and said unto him—See! thou hast become, well: —No more, be committing sin, lest, some worse thing, do thee befall.
Lẹ́yìn náà, Jesu rí i nínú tẹmpili ó sì wí fún un pé, “Wò ó, a mú ọ láradá: má ṣe dẹ́ṣẹ̀ mọ́, kí ohun tí ó burú ju èyí lọ má ba à bá ọ!”
15 The man went away, and told the Jews, that it was, Jesus, who had made him well.
Ọkùnrin náà lọ, ó sì sọ fún àwọn Júù pé, Jesu ni ẹni tí ó mú òun láradá.
16 And, on this account, were the Jews persecuting Jesus, because, these things, he had been doing, on Sabbath.
Nítorí èyí ni àwọn Júù ṣe inúnibíni sí Jesu, wọ́n sì ń wá ọ̀nà láti pa á, nítorí tí o ń ṣe nǹkan wọ̀nyí ní ọjọ́ ìsinmi.
17 But, he, answered them—My Father, until even now, is working; and, I, am working.
Ṣùgbọ́n Jesu dá wọn lóhùn pé, “Baba mi ń ṣiṣẹ́ títí di ìsinsin yìí, èmi náà sì ń ṣiṣẹ́.”
18 On this account, therefore, the rather, were the Jews seeking to slay him, —because, not only was he breaking the Sabbath, but was calling God, his own Father, making, himself, equal, with, God.
Nítorí èyí ni àwọn Júù túbọ̀ ń wá ọ̀nà láti pa á, kì í ṣe nítorí pé ó ba ọjọ́ ìsinmi jẹ́ nìkan ni, ṣùgbọ́n ó wí pẹ̀lú pé, Baba òun ni Ọlọ́run jẹ́, ó ń mú ara rẹ̀ bá Ọlọ́run dọ́gba.
19 Jesus, therefore, answered, and went on to say unto them—Verily, verily, I say unto you: The Son cannot be doing, of himself, a single thing, —save anything he may see, the Father, doing; for, whatsoever, he, may be doing, these things, the Son also, in like manner, doeth.
Nígbà náà ni Jesu dáhùn, ó sì wí fún wọn pé, “Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ọmọ kò lè ṣe ohunkóhun fún ara rẹ̀, bí kò ṣe ohun tí ó bá rí pé Baba ń ṣe, nítorí ohunkóhun tí baba bá ń ṣe, ìwọ̀nyí ni ọmọ náà sì ń ṣe pẹ̀lú.
20 For, the Father, dearly loveth the Son, and, all things, pointeth out to him, which, himself, is doing; and, greater works than these, will he point out to him, that, ye, may marvel.
Nítorí Baba fẹ́ràn ọmọ, ó sì ti fi ohun gbogbo tí ó ń ṣe hàn án, òun yóò sì fi iṣẹ́ tí ó tóbi jù wọ̀nyí lọ hàn án, kí ẹnu lè yà yín.
21 For, just as the Father waketh up the dead, and quickeneth them, in like manner, the Son also, whom he pleaseth, doth quicken.
Nítorí pé, gẹ́gẹ́ bí Baba ti ń jí òkú dìde, tí ó sì ń sọ wọ́n di alààyè: bẹ́ẹ̀ ni ọmọ ń sọ àwọn tí ó fẹ́ di alààyè pẹ̀lú.
22 For neither doth, the Father, judge anyone, —but, all the judging, hath given unto the Son:
Nítorí pé Baba kì í ṣe ìdájọ́ ẹnikẹ́ni, ṣùgbọ́n ó ti fi gbogbo ìdájọ́ lé ọmọ lọ́wọ́,
23 That, all, may honour the Son, just as they honour the Father: he that doth not honour the Son, doth not, in fact, honour the Father who sent him.
kí gbogbo ènìyàn lè máa fi ọlá fún ọmọ gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ń fi ọlá fún Baba. Ẹnikẹ́ni tí kò bá fi ọlá fún ọmọ, kò fi ọlá fún Baba tí ó ran an.
24 Verily, verily, I say unto you: He that heareth, my word, and believeth in him that sent me, hath life age-abiding, and, into judgment, cometh not, but hath passed over, out of death into life. (aiōnios )
“Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ẹnikẹ́ni tí ó bá gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, tí ó bá sì gba ẹni tí ó rán mi gbọ́, ó ní ìyè tí kò nípẹ̀kun, òun kì yóò sì wá sí ìdájọ́; ṣùgbọ́n ó ti ré ikú kọjá bọ́ sí ìyè. (aiōnios )
25 Verily, verily, I say unto you: There cometh an hour, and now is, when, the dead, shall hearken unto the voice of the Son of God, and, they who have hearkened, shall live.
Lóòótọ́, lóòótọ́ ni mo wí fún yín, wákàtí náà ń bọ̀, ó sì dé tán nísinsin yìí, nígbà tí àwọn òkú yóò gbọ́ ohùn Ọmọ Ọlọ́run, àwọn tí ó bá gbọ́ yóò sì yè.
26 For, just as, the Father, hath life, in himself, in like manner, unto the Son also, hath he given, life, to have, in himself;
Nítorí pé gẹ́gẹ́ bí Baba ti ní ìyè nínú ara rẹ̀; gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni ó sì fi fún ọmọ láti ní ìyè nínú ara rẹ̀;
27 And, authority, hath he given him, to be executing, judgment, —because, Son of Man, is he!
Ó sì fún un ní àṣẹ láti máa ṣe ìdájọ́ pẹ̀lú, nítorí tí òun jẹ́ Ọmọ Ènìyàn.
28 Do not be marvelling at this: because there come an hour, in which, all they in the tombs, shall hearken unto his voice,
“Kí èyí má ṣe yà yín lẹ́nu; nítorí pé wákàtí ń bọ̀, nínú èyí tí gbogbo àwọn tí ó wà ní ibojì yóò gbọ́ ohun rẹ̀.
29 and shall come forth, —they who, the good things, have done, unto a resurrection, of life; but, they who the corrupt things, have practised, unto a resurrection, of judgment.
Wọn ó sì jáde wá; àwọn tí ó ṣe rere, sí àjíǹde ìyè; àwọn tí ó sì ṣe búburú sí àjíǹde ìdájọ́.
30 I, cannot be doing, of myself, a single thing, —Just as I hear, I judge; and, my judging, is, just, —because I seek not my own will, but the will of him that sent me.
Èmi kò le ṣe ohun kan fún ara mi, bí mo ti ń gbọ́ ni, mo ń dájọ́, òdodo sì ni ìdájọ́ mi; nítorí èmi kò wá ìfẹ́ ti èmi fúnra mi, bí kò ṣe ìfẹ́ ti ẹni tí ó rán mi.
31 If, I, bear witness, concerning myself, my witness, is not, true.
“Bí èmi bá ń jẹ́rìí ara mi, ẹ̀rí mi kì í ṣe òtítọ́.
32 Another, it is, who beareth witness concerning me, —and I know that, true, is the witness which he witnesseth concerning me.
Ẹlòmíràn ni ẹni tí ń jẹ́rìí mi; èmi sì mọ̀ pé, òtítọ́ ni ẹ̀rí mi tí ó jẹ́.
33 Ye, have sent forth unto John, —and he hath borne witness to the truth: —
“Ẹ̀yin ti ránṣẹ́ lọ sọ́dọ̀ Johanu, òun sì ti jẹ́rìí sí òtítọ́.
34 I, however, not from man, my witness, receive; but, these things, I say, that, ye, may be saved: —
Ṣùgbọ́n èmi kò gba ẹ̀rí lọ́dọ̀ ènìyàn, nǹkan wọ̀nyí ni èmi ń sọ, kí ẹ̀yin lè là.
35 He, was the burning and shining lamp, and, ye, were willing to exult, for an hour, in his light.
Òun ni fìtílà tí ó ń jó, tí ó sì ń tànmọ́lẹ̀, ẹ̀yin sì fẹ́ fún sá à kan láti máa yọ̀ nínú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀.
36 But, I, have, as my witness, something greater than John’s; for, the works which the Father hath given me, that I should complete them, —the works themselves which I am doing, bear witness concerning me, that, the Father, hath sent me.
“Ṣùgbọ́n èmi ní ẹ̀rí tí ó pọ̀jù ti Johanu lọ. Nítorí iṣẹ́ tí Baba ti fi fún mi láti ṣe parí, iṣẹ́ náà pàápàá tí èmi ń ṣe náà ń jẹ́rìí mi pé, Baba ni ó rán mi.
37 And so, the Father who sent me, he, hath borne witness concerning me; Neither, a sound of him, at any time, have ye heard, nor, a form of him, have ye seen;
Àti Baba tìkára rẹ̀ tí ó rán mi ti jẹ́rìí mi. Ẹ̀yin kò gbọ́ ohùn rẹ̀ nígbà kan rí, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò rí ìrísí rẹ̀.
38 And, his word, ye have not, within you abiding—because, as touching him whom, he, sent, in him, ye, believe not.
Ẹ kò sì ní ọ̀rọ̀ rẹ̀ láti máa gbé inú yín, nítorí ẹni tí ó rán, òun ni ẹ̀yin kò gbàgbọ́.
39 Ye search the Scriptures, because, ye, think, by them, to have, life age-abiding; and, those [Scriptures], are they which bear witness concerning me: (aiōnios )
Ẹ̀yin ń wá ìwé mímọ́ nítorí ẹ̀yin rò pé nínú wọn ni ẹ̀yin ní ìyè tí kò nípẹ̀kun. Wọ̀nyí sì ni àwọn tí ó ń jẹ́rìí mi. (aiōnios )
40 And yet ye choose not to come unto me, that, life, ye may have.
Ẹ̀yin kò sì fẹ́ láti wá sọ́dọ̀ mi, kí ẹ̀yin ba à lè ní ìyè.
41 Glory from men, am I not receiving; —
“Èmi kò gba ògo lọ́dọ̀ ènìyàn.
42 But I have taken knowledge of you, that, the love of God, ye have not, in yourselves: —
Ṣùgbọ́n èmi mọ̀ pé, ẹ̀yin fúnra yín kò ní ìfẹ́ Ọlọ́run nínú yín.
43 I, have come, in the name of my Father, —and ye are not receiving me: If, another, shall come in his own name, him, ye will receive!
Èmi wá ní orúkọ Baba mi, ẹ̀yin kò sì gbà mí; bí ẹlòmíràn bá wá ní orúkọ ara rẹ̀, òun ni ẹ̀yin yóò gbà.
44 How can, ye, believe, —Glory from one another, receiving; and, the glory which is from the only God, are not seeking?
Ẹ̀yin ó ti ṣe lè gbàgbọ́, ẹ̀yin tí ń gba ògo lọ́dọ̀ ara yín tí kò wá ògo tí ó ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run nìkan wá?
45 Do not think that, I, will accuse you unto the Father: There, is, who accuseth you, even, Moses, —on whom, ye, have set your hope.
“Ẹ má ṣe rò pé, èmi ó fi yín sùn lọ́dọ̀ Baba, ẹni tí ń fi yín sùn wà, àní Mose, ẹni tí ẹ̀yin gbẹ́kẹ̀lé.
46 For, if ye had been believing, in Moses, ye would, in that case, have been believing, in me: for, concerning me, he wrote.
Nítorí pé ẹ̀yin ìbá gba Mose gbọ́, ẹ̀yin ìbá gbà mí gbọ́, nítorí ó kọ ìwé nípa tèmi.
47 But, if, in his writings, ye are not believing, how, in my sayings, will ye believe?
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá gba ìwé rẹ̀ gbọ́, ẹ̀yin ó ti ṣe gbà ọ̀rọ̀ mi gbọ́?”