< Job 28 >

1 Though there is, for silver, a vein, and a place for the gold they refine;
Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ, àti ibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.
2 Iron, out of the ore, is taken, and, stone, poureth out copper;
Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin, bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.
3 An end, hath one set to the darkness, and, into every extremity, is, he, making search, for the stone of darkness and death-shade;
Ènìyàn ni ó fi òpin si òkùnkùn, ó sì ṣe àwárí ìṣúra láti inú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.
4 He hath sunken a shaft, away from the inhabitants; Places forsaken by the foot, they hang down, away from men, sway to and fro;
Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jì sí àwọn tí ń gbé òkè, àwọn tí ẹsẹ̀ ènìyàn gbàgbé wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀, wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.
5 As for the earth, out of it, cometh forth bread, and, under it, is upturned, as it were fire;
Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá, àti ohun tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni ó yí padà bi iná;
6 The place of sapphires, are the stones thereof, and it hath, nuggets of gold: —
òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta safire, o sì ní erùpẹ̀ wúrà.
7 A path, the vulture hath not discerned, nor hath the eye of the hawk scanned it;
Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀, àti ojú gúnnugún kò rí i rí.
8 Ravenous beasts have not made a track thereof, neither hath the lion marched thereon:
Àwọn ẹranko agbéraga kò rìn ibẹ̀ rí, bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.
9 Upon the flint, hath he thrust forth his hand, He hath turned up mountains by the roots;
Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta, ó yí òkè ńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.
10 Among the rocks, hath he cut open streams, and, every precious thing, hath his eye seen:
Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta, ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.
11 From trickling, he restraineth, rivers, and, some hidden thing, is he bringing out to light.
Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún àkúnya, ó sì mú ohun tí ó pamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.
12 Yet where can, Wisdom, be found? And where is the place of understanding?
Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wá ọgbọ́n rí, níbo sì ni òye ń gbe?
13 Mortal knoweth not the way thereof, neither can it be found in the land of the living;
Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
14 The resounding deep, hath said, It is not in me! And, the sea, hath said, It is not with me!
Ọ̀gbun wí pé, “Kò sí nínú mi”; omi òkun sì wí pé, “Kò si nínú mi.”
15 Pure gold cannot be given in its stead, neither can silver he weighed as the value thereof;
A kò le è fi wúrà rà á, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi òsùwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.
16 It cannot be put into the scales against the gold of Ophir, with costly onyx, or sapphire;
A kò le è fi wúrà Ofiri, tàbí òkúta óníkìsì iyebíye, tàbí òkúta safire díye lé e.
17 Neither gold nor crystal can compare with it, nor can, the exchange thereof, be a vessel of pure gold,
Wúrà àti òkúta kristali kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èlò wúrà ṣe pàṣípàrọ̀ rẹ̀.
18 Coral or crystal, cannot be mentioned, Yea, a possession, is wisdom, above red coral;
A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta jasperi; iye ọgbọ́n sì ju iyùn lọ.
19 The topaz of Ethiopia cannot compare with it, Against purest gold, can it not be weighed.
Òkúta topasi ti Kuṣi kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.
20 Whence then cometh, wisdom? And where is the place of understanding?
Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá? Tàbí níbo ni òye ń gbé?
21 Seeing it hath been hid from the eyes of every living thing, and, from the bird of the heavens, hath it been concealed?
A rí i pé, ó fi ara sinko kúrò ní ojú àwọn alààyè gbogbo, ó sì fi ara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
22 Destruction and death, have said, With our ears, have we heard the report thereof!
Ibi ìparun àti ikú wí pé, àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.
23 GOD, understandeth the way thereof, and, he, discerneth the place thereof;
Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nà rẹ̀, òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé.
24 For, he, unto the ends of the earth, directeth his look, under all the heavens, he seeth;
Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé, ó sì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,
25 Making, for the wind, a weight, and, the waters, he proved by measure,
láti dà òsùwọ̀n fún afẹ́fẹ́, ó sì fi òsùwọ̀n wọ́n omi.
26 When he made, for the rain, a decree, and a way for the lightning of thunders,
Nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò, tí ó sì la ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
27 Then, saw he it, and declared it, He settled it, yea also he searched it out;
nígbà náà ni ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde; ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.
28 And said to the son of earth, Lo! the reverence of the Lord, that, is wisdom, and, to avoid evil, is understanding.
Àti fún ènìyàn ni ó wí pé, “Kíyèsi i, ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n, àti láti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.”

< Job 28 >