< Jeremiah 18 >

1 The word that came unto Jeremiah from Yahweh, saying:
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wá wí pe:
2 Arise and go down to the house of the potter, —and, there, will I cause thee to hear my words.
“Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ilé amọ̀kòkò, níbẹ̀ ni èmi yóò ti bá ọ sọ̀rọ̀.”
3 So I went down, to the house of the potter, —and there he was! making a piece of work on the wheels,
Nígbà náà ni mo lọ sí ilé amọ̀kòkò mo sì rí i tí ó ń ṣiṣẹ́ kan lórí kẹ̀kẹ́.
4 Then was marred, the vessel that he was making, while yet it was clay in the hand of the potter, —so he turned and made of it another vessel, as seemed right in the eyes of the potter to make it.
Ṣùgbọ́n ìkòkò tí ó ń mọ láti ara amọ̀ bàjẹ́ ní ọwọ́ rẹ̀, nítorí náà ni amọ̀kòkò fi ṣe ìkòkò mìíràn, ó mọ ọ́n bí èyí tí ó dára jù ní ojú rẹ̀.
5 Then came the word of Yahweh unto me, saying:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá pé:
6 Like this potter, can I not deal with you O house of Israel? Demandeth Yahweh: Lo! as clay in the hand of the potter, So, are, ye, in my hand O house of Israel.
“Ẹyin ilé Israẹli, èmi kò ha lè ṣe fún un yín gẹ́gẹ́ bí amọ̀kòkò yìí ti ṣe?” ni Olúwa wí. “Gẹ́gẹ́ bí amọ̀ ní ọwọ́ amọ̀kòkò bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin rí ní ọwọ́ mi, ẹ̀yin ilé Israẹli.
7 The moment I speak, concerning a nation or concerning a kingdom, —to pull up and to break down, and to destroy;
Bí ó bá jẹ́ ìgbà kan, tí èmi kéde kí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan di fífà tu láti dojúdé àti láti parun,
8 and that nation return from its wickedness against whom I have spoken, then will I repent concerning the calamity which I had devised to bring upon it.
tí orílẹ̀-èdè ti mo kìlọ̀ fún bá yípadà kúrò nínú ìwà búburú wọn, nígbà náà ni Èmi yóò yí ọkàn mi padà nínú àjálù tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.
9 And, the moment I speak, concerning a nation or concerning a kingdom, —to build and to plant;
Ní ìgbà mìíràn tí èmi bá tún kéde láti tẹ̀dó tàbí gbin orílẹ̀-èdè kan tàbí ìjọba kan.
10 and it commit wickedness in mine eyes, in not hearkening unto my voice, then will I repent concerning the good wherewith I had said I would do it good.
Bí ó bá sì ṣe búburú níwájú mi, tí kò sì gba ohùn mi gbọ́, nígbà náà ni èmi yóò yí ọkàn mi padà ní ti rere, èyí tí mo wí pé, èmi ó ṣe fún wọn.
11 Now, therefore, I pray thee, speak unto the men of Judah and concerning the inhabitants of Jerusalem saying, Thus, saith Yahweh, —Lo! I am fashioning against you calamity, and devising against you, a device, —Return I pray you every man from his wicked way, And amend your ways and your doings.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí, sọ fún àwọn ènìyàn Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa wí: Wò ó! Èmi ń gbèrò ibi sí yin, èmi sì ń ṣe ìpinnu kan lórí yín. Nítorí náà ẹ yípadà kúrò lọ́nà búburú yín kí olúkúlùkù yín sì tún ọ̀nà àti ìṣe rẹ̀ ṣe.’
12 And, since they will say, Hopeless! For after our own devices, will we walk, And, every one, the stubbornness of his own wicked heart, will we do!
Ṣùgbọ́n wọn yóò sọ wí pé, ‘Kò ṣe nǹkan kan, àwa yóò tẹ̀síwájú nínú èrò wa, ẹnìkọ̀ọ̀kan wa, yóò hùwà agídí ọkàn búburú rẹ̀.’”
13 Therefore, Thus saith Yahweh, Ask I pray you among the nations, —Who hath heard such things as these? A very horrible thing, hath, the virgin, Israel done!
Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: “Ẹ béèrè nínú orílẹ̀-èdè, ẹni tí ó bá ti gbọ́ irú nǹkan wọ̀nyí ri? Ohun tí ó burú gidi ni wúńdíá Israẹli ti ṣe.
14 Shall the snow of Lebanon, fail from the rock of the field? Or shall waters from afar, deep, overflowing, be dried up?
Ǹjẹ́ omi ojo dídì Lebanoni yóò ha dá láti máa sàn láti ibi àpáta? Tàbí odò tí ó jìnnà, tí ó tútù, tí ó ń sàn, yóò ha gbẹ bí?
15 Yet my people have forgotten me, Unto vanity, have they been burning incense; And it hath caused them to stumble In their ways The roads of age-past times, To walk in by-paths—A way not cast up.
Nítorí àwọn ènìyàn mi gbàgbé mi, wọ́n sun tùràrí fún òrìṣà asán, tí ó mú wọn kọsẹ̀ ní ọ̀nà wọn, àti ọ̀nà wọn àtijọ́. Wọ́n mú wọn rìn ní ọ̀nà àtijọ́, àti ní ojú ọ̀nà ti a kò ṣe.
16 To make their land a desolation The hissings of age-abiding times, —Every one that passeth by her, shall be astonished and wag his head.
Ilẹ̀ wọn yóò wà lásán yóò sì di nǹkan ẹ̀gàn títí láé, gbogbo àwọn tí ó ń kọjá yóò bẹ̀rù, wọn yóò sì mi orí wọn.
17 Like an east wind, will I scatter them before the enemy, —The back and not the face, will I let them see in the day of their distress.
Gẹ́gẹ́ bí afẹ́fẹ́ láti ìlà-oòrùn, Èmi yóò tú wọn ká lójú àwọn ọ̀tá wọn. Èmi yóò sì kọ ẹ̀yìn sí wọn, n kì yóò kọjú sí wọn ní ọjọ́ àjálù wọn.”
18 Then said they, —Come ye and let us devise against Jeremiah devices, For the law shall not perish from the priest, Nor, counsel, from the wise, Nor, the word from the prophet: Come and let as smite him with the tongue, And let us not give ear to any of his words!
Wọ́n sọ wí pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ ṣọ̀tẹ̀ sí Jeremiah, nítorí òfin ìkọ́ni láti ẹnu àwọn àlùfáà kì yóò jásí asán, tàbí ìmọ̀ràn fún àwọn ọlọ́gbọ́n tàbí ọ̀rọ̀ láti ẹnu àwọn wòlíì. Nítorí náà wá, ẹ jẹ́ kí a kọlù ú pẹ̀lú ahọ́n wa, kí a má sì ṣe tẹ́tí sí ohunkóhun tí ó bá sọ.”
19 Give thou ear O Yahweh unto me, —And hearken unto the voice of mine accusers.
Dẹtí sí ọ̀rọ̀ mi Olúwa, gbọ́ ohun tí àwọn tí ó fi mí sùn ń sọ.
20 Shall, evil, be recompensed for good? For they have digged a pit for my life, —Remember how I stood before thee To speak in their behalf what was good! To turn back thine indignation from them.
Ṣe kí a fi rere san búburú? Síbẹ̀ wọ́n ti gbẹ́ kòtò fún mi. Rántí pé mo dúró níwájú rẹ, mo sì sọ̀rọ̀ nítorí wọn, láti yí ìbínú rẹ kúrò lọ́dọ̀ wọn.
21 Therefore, give thou up their sons to the famine And deliver them into the hands of the sword, And let their, wives, become, childless and widows, And let, their men, be slain by death, Their young men be smitten by the sword in battle.
Nítorí náà, jẹ́ kí ìyàn mú ọmọ wọn jọ̀wọ́ wọn fún ọwọ́ idà jẹ́ kí ìyàwó wọn kí ó di aláìlọ́mọ àti opó jẹ́ kí a pa àwọn ọkùnrin wọn kí a sì fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn lójú ogun.
22 Let there be heard a cry out of their houses, When thou shalt bring in upon them a troop, suddenly, —Because they digged a pit to capture me, And snares, did they hide for my feet.
Jẹ́ kí a gbọ́ ohùn ẹkún láti ilé wọn nígbà tí ó bá mu àwọn jagunjagun kọlù wọ́n lójijì nítorí wọ́n ti gbẹ́ kòtò láti mú mi. Wọ́n ti dẹ okùn fún ẹsẹ̀ mi.
23 But, thou, O Yahweh, knowest all their counsels against me to put me to death, Put thou no propitiatory-covering over their iniquity, And their sin from before thee, do not thou blot out, —But let them be overthrown before thee, In the time of thine anger, deal thou effectively with them.
Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa mọ gbogbo ète wọn láti pa mí, má ṣe dárí ẹ̀bi wọn jì wọ́n bẹ́ẹ̀ ni má ṣe pa ẹ̀ṣẹ̀ wọn rẹ́ kúrò lójú rẹ. Jẹ́ kí wọn kí ó ṣubú níwájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ kí ó sì ṣe sí wọn nígbà ìbínú rẹ.

< Jeremiah 18 >