< Jeremiah 17 >
1 The sin of Judah, is written With a stylus of iron, With the point of a diamond: It is engraved Upon the tablet of their heart, And upon the horns of your altars;
“Ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a fi kálámù irin kọ, èyí tí a fi ṣóńṣó òkúta adamante gbẹ́ ẹ, sórí wàláà oókan àyà wọn, àti sórí ìwo pẹpẹ yín.
2 So long as their sons remember their altars, and their Sacred Stems, By the green tree, —Upon the high hills,
Kódà àwọn ọmọ wọn rántí pẹpẹ àti ère Aṣerah lẹ́bàá igi tí ó tẹ́ rẹrẹ àti àwọn òkè gíga.
3 O my mountain in the field Thy substance all thy treasures, for a prey, will I give: Thy high places for sin, within all thy bounds.
Àwọn òkè nínú ilẹ̀ àti àwọn ọrọ̀ rẹ̀ àti ọlá rẹ̀ ni èmi yóò fi sílẹ̀ bí ìjẹ pẹ̀lú àwọn ibi gíga, nítorí ẹ̀ṣẹ̀ tí ó pọ̀ káàkiri orílẹ̀-èdè yín.
4 So shalt thou even of thyself, suffer to rest the inheritance which I gave thee, Seeing that I will cause thee to serve thine enemies, in the land which thou knowest not; For, a fire, have ye kindled in mine anger, Unto times age-abiding, shall it burn.
Láti ipasẹ̀ àìṣedéédéé yín ni ẹ̀yin yóò ti sọ ogún tí mo fún un yín nù. Èmi yóò fi yín fún ọ̀tá yín bí ẹrú ní ilẹ̀ tí ẹ̀yin kò mọ̀, nítorí ẹ̀yin ti mú inú bí mi, èyí tí yóò sì wà títí ayé.”
5 Thus, saith Yahweh Accursed is the man—Who trusteth in a son of earth, And hath made flesh his arm, —And whose heart from Yahweh, turneth aside:
Báyìí ni Olúwa wí: “Ègbé ni fún àwọn tí ó fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú ènìyàn, tí ó fi agbára rẹ̀ sínú ẹran-ara, àti tí ọkàn rẹ̀ kò sí lọ́dọ̀ Olúwa.
6 Therefore shall he become as a shrub in the waste plain, Neither shall he perceive when good cometh, But shall inhabit Parched places in a wilderness, A land of salt that cannot be dwelt in.
Yóò dàbí igbó tí ó wà ní ilẹ̀ aláìlọ́ràá, kò ní rí ìre, nígbà tí ó bá dé, yóò máa gbé ní ibi ìyàngbẹ ilẹ̀ aginjù, ní ilẹ̀ iyọ̀ tí ẹnikẹ́ni kò gbé.
7 Blessed is the man Who trusteth in Yahweh, To whom Yahweh is his ground of confidence;
“Ṣùgbọ́n ìbùkún ni fún ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, tí ó sì fi Olúwa ṣe ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ̀.
8 For he shall become like a tree planted by waters, And, by a stream, shall he send out his roots, Neither shall he perceive when heat cometh, But, his leaf shall continue green: Even in a year of dearth, shall he not be anxious, Neither shall he cease from bearing fruit.
Yóò dàbí igi tí a gbìn sí ipadò tí ó ta gbòǹgbò rẹ̀ ká etí odò kò sí ìbẹ̀rù fún un nígbà ooru, gbogbo ìgbà ni èwe rẹ̀ máa ń tutù kò sí ìjayà fún un ní ọdún ọ̀dá bẹ́ẹ̀ ni kò ní dẹ́kun láti máa so èso.”
9 Deceitful is the heart above all things And, dangerously wayward, —Who can know it?
Ọkàn ènìyàn kún fún ẹ̀tàn ju ohun gbogbo lọ, ó kọjá ohun tí a lè wòsàn. Ta ni èyí lè yé?
10 I—Yahweh, Searching the heart, Testing the affections; And giving to every man According to his way, According to the fruit of his doings.
“Èmi Olúwa ń wo ọkàn àti èrò inú ọmọ ènìyàn, láti san èrè iṣẹ́ rẹ̀ fún un gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀, àti gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀.”
11 As a partridge gathereth eggs she did not lay, [So] is he that maketh riches but not with justice, —In the midst of his days, shall he leave them, And in his latter end, prove to have been base.
Bí àparò tó pa ẹyin tí kò yé ni ọmọ ènìyàn tí ó kó ọrọ̀ jọ ni ọ̀nà àìṣòdodo. Yóò di ẹni ìkọ̀sílẹ̀ ní agbede-méjì ayé rẹ̀, àti ní òpin rẹ̀ yóò wá di aṣiwèrè.
12 A throne of glory, exalted from the beginning, hath been the place of our sanctuary.
Ìtẹ́ ògo; ibi gíga láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ní ibi ilé mímọ́ wa.
13 Thou hope of Israel Yahweh, All who forsake thee, shall turn pale, —Yea, all who depart from me, in the ground, shall be written, For they have forsaken a fountain of living water, even Yahweh.
Olúwa ìwọ ni ìrètí Israẹli; gbogbo àwọn tí ó kọ̀ ọ́ sílẹ̀ ni ojú ó tì. Àwọn tí ó padà sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ rẹ ni a ó kọ orúkọ wọn sínú ekuru, nítorí wọ́n ti kọ Olúwa, orísun omi ìyè sílẹ̀.
14 Heal thou me O Yahweh, that I may be healed, Save me that I may be saved, —For, my praise, thou art!
Wò mí sàn Olúwa, èmi yóò di ẹni ìwòsàn, gbà mí là, èmi yóò di ẹni ìgbàlà, nítorí ìwọ ni ìyìn mi.
15 Lo! they, are saying unto me, —Where is the word of Yahweh? Pray thee let it come to pass!
Wọ́n sọ fún mi wí pé: “Níbo ni ọ̀rọ̀ Olúwa wà? Jẹ́ kí ó di ìmúṣẹ báyìí.” Ni Olúwa wí.
16 But as for me, I have neither forced myself away from tending the flock after thee, Nor yet for the woeful day, have I longed—thou, knowest, —That which came out of my lips, before thy face, was uttered.
Èmi kò sá kúrò láti máa jẹ́ olùṣọ àgùntàn rẹ, ìwọ mọ̀ wí pé èmi kò kẹ̀rẹ̀ ní ọjọ́ ìpọ́njú. Ohun tí ó jáde ní ètè mi jẹ́ èyí tí ó hàn sí ọ.
17 Do not thou become to me a terror, —My refuge, art thou, in the day of calamity.
Má ṣe di ìbẹ̀rù fún mi, ìwọ ni ààbò mi ní ọjọ́ ìpọ́njú.
18 Let my persecutors, turn pale, but let not me, turn pale, Let, them, be terrified, but let not, me, be terrified, —Bring thou upon them a day of calamity, And with a double fracture, destroy them.
Jẹ́ kí ojú ti àwọn ẹni tí ń lépa mi, ṣùgbọ́n pa mí mọ́ kúrò nínú ìtìjú, jẹ́ kí wọn kí ó dààmú. Mú ọjọ́ ibi wá sórí wọn, fi ìparun ìlọ́po méjì pa wọ́n run.
19 Thus, said Yahweh unto me—Go and stand in the gate of the sons of the people, through which the kings of Judah enter in, and through which they come out, —also in all the gates of Jerusalem.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún mi: “Lọ dúró ní ẹnu-ọ̀nà àwọn ènìyàn níbi tí àwọn ọba Juda ń gbà wọlé tí wọ́n ń gbà jáde àti ní gbogbo ẹnu-bodè Jerusalẹmu.
20 Then shalt thou say unto them—Hear ye the word of Yahweh Ye kings of Judah and all Judah, And all ye inhabitants of Jerusalem, —who enter in through these gates:
Sọ fún wọ́n pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba Juda àti gbogbo ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé ní Jerusalẹmu tí ń wọlé láti ẹnu ibodè yìí.
21 Thus, saith Yahweh, Take heed unto your souls, —And do not bear any burden on the sabbath day, Nor bring it in through the gates of Jerusalem, —
Báyìí ni Olúwa wí, “Ẹ kíyèsi láti máa ru ẹrù lọ́jọ́ ìsinmi tàbí kí ẹ gbé wọlé láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.
22 Neither shall ye take forth any burden out of your houses on the sabbath day, Nor any manner of work, shall ye do, —But ye shall hallow the sabbath day, As I commanded your fathers.
Má ṣe gbé ẹrù jáde kúrò nínú ilé yín, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ má ṣe ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ ìsinmi ṣùgbọ́n kí ẹ pa ọjọ́ ìsinmi mọ́ fún àwọn baba ńlá yín.”
23 Howbeit they hearkened not, neither inclined their ear, —but stiffened their neck, that they might not hearken, neither receive correction.
Síbẹ̀ wọn kò gbọ́ tàbí tẹ́tí sílẹ̀, wọ́n jẹ́ ọlọ́rùn líle; wọn kì í fẹ́ gbọ́ tàbí gba ìbáwí.
24 And it shall come to pass, —If ye will, indeed hearken, unto me Declareth Yahweh, To bring in no burden through the gates of this city, on the sabbath day, —But to hallow the sabbath day, by not doing thereon any manner of work,
Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kíyèsi láti gbọ́ tèmi ní Olúwa wí, tí ẹ kò sì gbe ẹrù gba ẹnu-bodè ìlú ní ọjọ́ ìsinmi, ṣùgbọ́n tí ẹ ya ọjọ́ ìsinmi, sí mímọ́, nípa pé ẹ kò ṣe iṣẹ́kíṣẹ́ ní ọjọ́ náà.
25 Then shall enter in through the gates of this city, Kings and princes Sitting on the throne of David, Riding in chariots and on horses They, and their princes, The men of Judah and the inhabitants of Jerusalem, And this city shall remain unto times age-abiding.
Nígbà náà ni ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba ẹnu ibodè wọlé pẹ̀lú àwọn ìjòyè rẹ̀. Àwọn àti ìjòyè wọn yóò gun ẹṣin àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wá, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu yóò tẹ̀lé wọn; ìlú yìí yóò sì di ibi gbígbé títí láéláé.
26 And they shall come in—Out of the cities of Judah and Out of the places round about Jerusalem, and Out of the land of Benjamin, and Out of the lowlands, and out of the hill country, and Out of the South, Bringing in ascending-offering, and peace-offering, and meal-offering, and frankincense, —Even they who bring in a thank-offering into the house of Yahweh,
Àwọn ènìyàn yóò wá láti ìlú Juda àti ní agbègbè Jerusalẹmu, láti ilẹ̀ Benjamini, láti pẹ̀tẹ́lẹ̀, àti láti òkè, àti láti gúúsù wá, wọn yóò wá pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, àti ọrẹ ẹran, àti tùràrí, àti àwọn tó mú ìyìn wá sí ilé Olúwa.
27 But, if ye will not hearken unto me—To hallow the sabbath day, And to bear no burden and bring in through the gates of Jerusalem, on the sabbath day, Then will I kindle a fire within her gates, And it shall devour the palaces of Jerusalem, And shall not be quenched.
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá pa òfin mi mọ́ láti ya ọjọ́ ìsinmi sí mímọ́, kí ẹ má sì ṣe ru ẹrùkẹ́rù bí ẹ̀yin yóò ṣe máa gba ẹnu ibodè Jerusalẹmu wọlé ní ọjọ́ ìsinmi, nígbà náà ni èmi yóò da iná tí kò ní ṣe é parun ní ẹnu-bodè Jerusalẹmu tí yóò sì jó odi agbára rẹ̀.’”