< Hosea 12 >
1 Ephraim, feedeth on wind, and pursueth the east wind, all the day, falsehood and force, doth he magnify, —and, a covenant with Assyria, would they solemnize, and, oil into Egypt, must be borne along.
Efraimu ń jẹ afẹ́fẹ́; o ń lépa afẹ́fẹ́ ìwọ̀-oòrùn ní gbogbo ọjọ́. O sì ń gbèrú nínú irọ́ o dá májẹ̀mú pẹ̀lú Asiria o sì fi òróró olifi ránṣẹ́ sí Ejibiti.
2 But, a controversy, hath Yahweh with Judah, —so that he may bring punishment on Jacob, according to his ways, According to his doings, repay him.
Olúwa ní ẹjọ́ kan tí yóò bá Juda rò, yóò fì ìyà jẹ Jakọbu gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀ yóò sì sán fún un gẹ́gẹ́ bí i ìṣe rẹ̀.
3 In the womb, took he his brother by the heel; and, in his manly vigour, strove he with God:
Láti inú oyún ni ó ti di arákùnrin rẹ̀ mú ni gìgísẹ̀, àti nípa ipá rẹ̀ ó ni agbára pẹ̀lú Ọlọ́run
4 Yea he strove against a Messenger, and prevailed, he wept, and made supplication unto him, —At Bethel, he found him, and, there, he spake with us;
Ó bá angẹli ja ìjàkadì, ó sì borí rẹ̀, o sọkún, ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere rẹ̀. Ó bá Olúwa ní Beteli, Ó sì bá a sọ̀rọ̀ níbẹ̀,
5 And, Yahweh, is God of host, —Yahweh, is his memorial.
àní Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun; Olúwa ni orúkọ ìrántí rẹ̀.
6 Thou, therefore, by thy God, shalt return, —lovingkindness and justice, do thou keep, so wait thou for thy God, continually.
Ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀; di ìfẹ́ àti ìdájọ́ òdodo mú kí ẹ sì dúró de Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
7 A trafficker! in his hand, are balances of deceit, to oppress, he loveth.
Oníṣòwò ń lo òsùwọ̀n èké o fẹ́ràn láti rẹ́ ni jẹ.
8 So then Ephraim said, Surely I have gotten me riches, I have found wealth for myself, —in all my toils, they cannot find in me perversity which is sin.
Efraimu gbéraga, “Èmi ní ìní fún ara mi, mo sì ti di ọlọ́rọ̀, pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ mi yìí, wọn kò le ká àìṣedéédéé tàbí ẹ̀ṣẹ̀ kankan mọ́ mi lọ́wọ́.”
9 But, I, Yahweh, have been thy God, from the land of Egypt, —I will yet make thee dwell in tents, as in the days of appointed meeting.
“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ; ẹni tí ó mu ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti; èmi yóò tún mú yín gbé nínú àgọ́ bí i ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn wọ̀n-ọn-nì.
10 And I will lay my word upon the prophets, yea, I myself, have magnified, vision, —and, by the hand of the prophets, will I use similitudes.
Mo sọ fún àwọn wòlíì, mo fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìran hàn wọ́n mo sì pa òwe láti ẹnu wòlíì wọn.”
11 If, Gilead, is in sorrow, surely false, have they been, In Gilgal, have they sacrificed, bullocks, —their very altars, shall become as heaps upon the furrows of the field.
Gileadi ha burú bí? Àwọn ènìyàn rẹ̀ jẹ́ asán. Ǹjẹ́ wọ́n ń fi akọ màlúù rú ẹbọ ní Gilgali? Gbogbo pẹpẹ wọ́n sì dàbí ebè nínú aporo oko.
12 When Jacob fled to the country of Syria, then Israel served for a wife, and, for a wife, he watched over a flock.
Jakọbu sálọ si orílẹ̀-èdè Aramu; Israẹli sìn kí o tó fẹ́ ìyàwó ó ṣe ìtọ́jú ẹran láti fi san owó ìyàwó.
13 And, by a prophet, Yahweh, brought up, Israel out of Egypt, —and, by a prophet, was he watched over.
Olúwa lo wòlíì kan láti mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, nípasẹ̀ wòlíì kan ó ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
14 Ephraim hath provoked, very bitterly, —his own blood, therefore, upon him, will he leave, and, his reproach, shall his Lord, bring back to him.
Ṣùgbọ́n Efraimu ti mú un bínú gidigidi; Olúwa rẹ̀ yóò sì fi ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sí orí rẹ̀ òun yóò sì san án padà fún un nítorí ìwà ẹ̀gàn an rẹ̀.