< Hosea 10 >
1 A luxuriant vine, is Israel, fruit, beseemeth him, —According to the abundance of his fruit, hath he brought abundance to the altars, according to the goodliness of his land, hath he made goodly statues.
Israẹli jẹ́ igi àjàrà tó gbilẹ̀ ó ń so èso fún ara rẹ̀. Bí èso rẹ̀ ṣe ń pọ̀ bẹ́ẹ̀ ni ó ń kọ́ pẹpẹ sí i bí ilẹ̀ rẹ̀ ṣe ń ṣe rere o bu ọlá fún òkúta ìyàsọ́tọ̀ ère rẹ̀.
2 Hypocritical is their heart, Now, shall they be held guilty, —He, will break down their altars, he will destroy their statutes.
Ọkàn wọn kún fún ìtànjẹ báyìí wọ́n gbọdọ̀ ru ẹ̀bi wọn. Olúwa yóò wó pẹpẹ wọn palẹ̀ yóò sì pa gbogbo òkúta ìyàsọ́tọ̀ wọn run.
3 For, now, will they say, We have no king, —for we revere not Yahweh, and what could, a king, do for us?
Nígbà náà ni wọn yóò wí pé, “A kò ní ọba nítorí tí a kò bọ̀wọ̀ fún Olúwa ṣùgbọ́n bí a tilẹ̀ ní ọba, kí ni yóò ṣe fún wa?”
4 They have spoken words, swearing falsely, in solemnizing a covenant, —therefore shall judgment, spring up like a poisonous plant, on the ridges of the field.
Wọ́n ṣe ìlérí púpọ̀, wọ́n ṣe ìbúra èké, wọ́n da májẹ̀mú; báyìí ni ìdájọ́ hù sókè bí igi ìwọ̀ ni aporo oko, bi i koríko májèlé láàrín oko tí a ro.
5 About the calves of Beth-aven, will the inhabitant of Samaria be concerned, —for the people thereof, have mourned over it, and, the ascetics thereof, who, over it, used to exult, [shall mourn] for the glory thereof, because it hath departed therefrom.
Àwọn ènìyàn tí ń gbé Samaria bẹ̀rù nítorí ère abo màlúù tó wà ní Beti-Afeni. Àwọn ènìyàn rẹ̀ yóò ṣọ̀fọ̀ le e lórí bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà rẹ̀. Gbogbo àwọn tó láyọ̀ sì dídán rẹ̀, nítorí tí a ti mú lọ sí ìgbèkùn.
6 Itself also, to Assyria, shall be borne along, as a present to a hostile king, —shame, shall Ephraim receive, that Israel, may be ashamed, of his own counsel.
A ó gbé lọ sí Asiria gẹ́gẹ́ bí ẹ̀bùn fún ọba ńlá a ó dójútì Efraimu; ojú yóò ti Israẹli nítorí ìgbìmọ̀ rẹ̀.
7 Silenced is Samaria: her king, is as a chip on the face of the waters,
Bí igi tó léfòó lórí omi ni Samaria àti àwọn ọba rẹ yóò sàn lọ.
8 So shall the high places of Aven, be destroyed, the sin of Israel, Thorn and prickle, shall come up on their altars, —Therefore shall they say to the mountains, Cover us, and to the hills, Fall on us.
Àwọn ibi gíga tí ẹ tí ń hùwà búburú ni a o parun, èyí ni ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli. Ẹ̀gún ọ̀gàn àti ẹ̀gún òṣùṣú yóò hù jáde, yóò sì bo àwọn pẹpẹ wọn. Wọn yóò sọ fún àwọn òkè gíga pé, “Bò wá mọ́lẹ̀!” àti fún àwọn òkè kéékèèké pé, “Ṣubú lù wá!”
9 Beyond the days of Gibeah, hast thou sinned, O Israel: there, came they to a stand, the battle against the sons of perversity, touched them not in Gibeah.
“Láti ìgbà Gibeah, ni ó ti ṣẹ̀, ìwọ Israẹli, ìwọ sì tún wà níbẹ̀. Ǹjẹ́ ogun kò lé ẹ̀yin aṣebi ni Gibeah bá bí?
10 When I please, then will I chastise them, —and there shall be gathered together against them—peoples, they being harnessed to their two Iniquities;
Nígbà tó bá tẹ́ mi lọ́rùn, èmi yóò fi ìyà jẹ wọ́n; Orílẹ̀-èdè yóò kó ra wọn jọ, wọ́n ó sì dojúkọ wọn, láti fi wọn sínú ìdè nítorí ìlọ́po ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
11 But, Ephraim, shall be a heifer broken in, loving to tread out corn, when, I, have passed over upon her fair neck, —I will drive Ephraim, Judah, shall plow, Jacob, shall harrow to him.
Efraimu jẹ́ ọmọ abo màlúù tí a tí kọ́, to si fẹ́ràn láti máa pa ọkà; lórí ọrun rẹ̀ tó lẹ́wà ni èmi ó dí ẹrù wúwo lé. Èmi yóò mú kí a gun Efraimu bí ẹṣin Juda yóò tú ilẹ̀, Jakọbu yóò sì fọ́ ògúlùtu rẹ̀.
12 Sow to yourselves in righteousness, reap ye at the bidding of lovingkindness, furrow to yourselves the newly-ploughed soil, —then will be the time to seek Yahweh, until he come, that he may rain down righteousness for you.
Ẹ gbin òdòdó fún ara yín, kí ẹ sì ká èso ìfẹ́ àìlópin. Ẹ tu ilẹ̀ yín tí a kò ro, nítorí pé ó ti tó àsìkò láti wá Olúwa, títí tí yóò fi dé, tí yóò sì rọ òjò òdodo lé yín lórí.
13 Ye have plowed lawlessness, perversity, have ye reaped, ye have eaten the fruit of deception, —because thou didst trust in thy chariots, in the multitude of thy mighty men.
Ṣùgbọ́n ẹ tí gbin búburú ẹ si ka ibi, ẹ ti jẹ èso èké nítorí ẹ tí gbẹ́kẹ̀lé agbára yín àti àwọn ọ̀pọ̀ jagunjagun yín,
14 Therefore shall there arise a tumult among thy peoples, and, all thy fortresses, shall be plundered, as Shalman plundered Beth-arbel, in the day of battle, —the mother, upon her children, dashed to the ground.
ariwo ogun yóò bo àwọn ènìyàn yín kí gbogbo odi agbára yín ba le parun. Gẹ́gẹ́ bí Ṣalmani ṣe pa Beti-Arbeli run lọ́jọ́ ogun, nígbà tí a gbé àwọn ìyá ṣánlẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ wọn.
15 Even so, hath Bethel, done to you, because of your exceeding wickedness, —in the dawn, shall the king of Israel be, utterly silenced.
Báyìí ni a o sì ṣe sí ọ, ìwọ Beteli, nítorí pé ìwà búburú yín ti pọ̀jù. Ní àfẹ̀mọ́júmọ́ ọjọ́ náà, a o pa ọba Israẹli run pátápátá.