< Ezra 2 >
1 Now, these, are the sons of the province, who came up from among the captives of the exile, whom Nebuchadnezzar the king of Babylon exiled to Babylon, —who came back unto Jerusalem and Judah, every one unto his own city;
Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
2 who came in with Zerubbabel, Jeshua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordecai, Bilshan, Mispar, Bigvai Rehum, Baanah, —the number of the men of the people of Israel: —
Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
3 The sons of Parosh, two thousand one hundred and seventy-two;
Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
4 The sons of Shephatiah, three hundred and seventy-two;
Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
5 The sons of Arah, seven hundred and seventy-five;
Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
6 The sons of Pahath-moab, belonging to the sons of Jeshua, Joab, two thousand eight hundred and twelve;
Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
7 The sons of Elam, a thousand two hundred and fifty-four;
Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
8 The sons of Zattu, nine hundred and forty-five;
Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
9 The sons of Zaccai, seven hundred and sixty;
Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
10 The sons of Bani, six hundred and forty-two;
Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
11 The sons of Bebai, six hundred and twenty-three;
Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
12 The sons of Azgad, a thousand two hundred and twenty-two;
Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
13 The sons of Adonikam, six hundred and sixty-six;
Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
14 The sons of Bigvai, two thousand and fifty-six;
Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
15 The sons of Adin, four hundred and fifty-four;
Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
16 The sons of Ater pertaining to Hezekiah, ninety-eight;
Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
17 The sons of Bezai, three hundred and twenty-three;
Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
18 The sons of Jorah, a hundred and twelve;
Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
19 The sons of Hashum, two hundred and twenty-three:
Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
20 The sons of Gibbar, ninety-five;
Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
21 The sons of Bethlehem, a hundred and twenty-three;
Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
22 The men of Netophah, fifty-six;
Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
23 The men of Anathoth, a hundred and twenty-eight;
Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
24 The sons of Azmaveth, forty-two;
Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
25 The sons of Kiriath-arim, Chephirah and Beeroth, seven hundred and forty-three;
Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
26 The sons of Ramah and Geba, six hundred and twenty-one;
Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
27 The men of Michmas, a hundred and twenty-two:
Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
28 The men of Bethel and Ai, two hundred and twenty-three;
Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
29 The sons of Nebo, fifty-two;
Nebo jẹ́ méjìléláàádọ́ta
30 The sons of Magbish, a hundred and fifty-six;
Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
31 The sons of the other Elam, a thousand two hundred and fifty-four;
Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
32 The sons of Harim, three hundred and twenty;
Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
33 The sons of Lod, Hadid and Ono, seven hundred and twenty-five;
Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
34 The sons of Jericho, three hundred and forty-five;
Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
35 The sons of Senaah, three thousand and six hundred and thirty!
Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
36 The priests, The sons of Jedaiah of the house of Jeshua, nine hundred and seventy-three;
Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
37 The sons of Immer, a thousand and fifty-two;
Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
38 The sons of Pashhur, a thousand two hundred and forty-seven;
Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
39 The sons of Harim, a thousand and seventeen,
Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
40 The Levites, The sons of Jeshua, and Kadmiel of the sons of Hodaviah, seventy-four.
Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
41 The singers, The sons of Asaph, a hundred and twenty-eight.
Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
42 The sons of the door-keepers, The sons of Shallum, the sons of Ater, the sons of Talmon, the sons of Akkub, the sons of Hatita, the sons of Shobai, —in all, a hundred and thirty-nine.
Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
43 The Nethinim, The sons of Ziha, the sons of Hasupha, the sons of Tabbaoth;
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
44 the sons of Keros, the sons of Siaha, the sons of Padon;
Kerosi, Siaha, Padoni,
45 the sons of Lebanah, the sons of Hagabah, the sons of Akkub;
Lebana, Hagaba, Akkubu,
46 the sons of Hagab, the sons of Shamlai, the sons of Hanan;
Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
47 the sons of Giddel, the sons of Gahar, the sons of Reaiah;
Giddeli, Gahari, Reaiah,
48 the sons of Rezin, the sons of Nekoda, the sons of Gazzam;
Resini, Nekoda, Gassamu,
49 the sons of Uzza, the sons of Paseah, the sons of Besai;
Ussa, Pasea, Besai,
50 the sons of Asnah, the sons of Meunim, the sons of Nephisim;
Asna, Mehuni, Nefisimu,
51 the sons of Bakbuk, the sons of Hakupha, the sons of Harhur;
Bakbu, Hakufa, Harhuri.
52 the sons of Bazluth, the sons of Mehida, the sons of Harsha;
Basluti, Mehida, Harṣa,
53 the sons of Barkos, the sons of Sisera, the sons of Temah;
Barkosi, Sisera, Tema,
54 the sons of Neziah, the sons of Hatipha.
Nesia àti Hatifa.
55 The Sons of the Servants of Solomon. The sons of Sotai, the sons of Hasso-phereth, the sons of Peruda;
Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
56 the sons of Jaalah, the sons of Darkon, the sons of Giddel;
Jaala, Darkoni, Giddeli,
57 the sons of Shephatiah, the sons of Hattil, the sons of Pochereth-hazzebaim, the sons of Ami.
Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
58 All the Nethinim, and the Sons of the Servants of Solomon, were three hundred and ninety-two.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
59 And, these, were they who came up from Tel-melah, Tel-harsha, Cherub, Addan, Immer; but they could not tell their ancestral house, nor their seed, whether, of Israel, they were:
Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
60 the sons of Delaiah, the sons of Tobiah, the sons of Nekoda, —six hundred and fifty-two.
Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
61 And, of the sons of the priests, the sons of Habaiah, the sons of Hakkoz, —the sons of Barzillai, who took of the daughters of Barzillai the Gileadite to wife, and was called after their name.
Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
62 These, sought their writing wherein they were registered, but they were not found, —so they were desecrated out of the priesthood;
Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
63 and the governor told them, that they must not eat of the most holy things, —until there should stand up a priest, with Lights and Perfections.
Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
64 All the gathered host together, was forty-two thousand three hundred and sixty;
Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
65 besides, their men-servants and their maid-servants who were these, seven thousand three hundred and thirty-seven, —and there pertained to them, singing men and singing women, two hundred:
Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
66 their horses, were seven hundred and thirty-six, —their mules, two hundred and forty-five;
Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
67 their camels, four hundred and thirty-five, —asses, six thousand seven hundred and twenty.
ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
68 And, a portion of the ancestral chiefs, when they came to the house of Yahweh which was in Jerusalem, offered voluntarily for the house of God, to set it up on its basis.
Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
69 According to their ability, gave they unto the treasury of the work, of gold, sixty-one thousand drams, and, of silver, five thousand manehs, —and, tunics for priests, one hundred.
Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
70 So the priests and the Levites, and some of the people, and the singers and the doorkeepers and the Nethinim, took up their abode, in their cities, —and, all Israel, in their cities.
Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.