< Ezekiel 23 >

1 And the word of Yahweh came unto me saying,
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Son of man, Two women, daughters of one mother, there were;
“Ọmọ ènìyàn, obìnrin méjì wà, ọmọ ìyá kan náà.
3 And they became unchaste in Egypt, In their youth, became they unchaste, There, were handled their breasts, And there, were pressed their virgin bosoms.
Wọn ń ṣe panṣágà ní Ejibiti, wọn ń ṣe panṣágà láti ìgbà èwe wọn. Ní ilẹ̀ yẹn ni wọn ti fi ọwọ́ pa ọyàn wọn, níbẹ̀ ni wọn sì fọwọ́ pa igbá àyà èwe wọn.
4 And their names were Oholah the elder And Oholibah—her sister, And they became mine and bare sons and daughters, - And as for their names, Samaria was Oholah, And Jerusalem, was Oholibah.
Èyí ẹ̀gbọ́n ń jẹ́ Ohola, àbúrò rẹ̀ sì ń jẹ́ Oholiba. Tèmi ni wọ́n, wọ́n sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin. Ohola ni Samaria, Oholiba sì ni Jerusalẹmu.
5 Then became Oholah unchaste after she had become mine- And lusted after her lovers, For Assyrians, so warlike,
“Ohola ń ṣe panṣágà nígbà tí ó sì jẹ́ tèmi; Ó sì ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, àwọn jagunjagun ará Asiria.
6 Clothed in blue Governors and deputies, Attractive young men all of them, -Horsemen riding on horses.
Aṣọ aláró ni a fi wọ̀ wọ́n, àwọn gómìnà àti àwọn balógun, gbogbo wọn jẹ́ ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà àwọn tí ń gun ẹṣin.
7 So she bestowed her unchastities upon them, The choicest men of Assyria all of them, - And, with whomsoever she lusted after-with all their manufactured gods, she defiled herself.
O fi ara rẹ̀ fún gbajúmọ̀ ọkùnrin Asiria gẹ́gẹ́ bí panṣágà obìnrin, o fi òrìṣà gbogbo àwọn tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́,
8 And, her unchaste doings from the time she was in Egypt, had she not forsaken, For with her, had they lain in her youth, Yea they had pressed her virgin bosoms, - and had poured out their unchastity upon her.
kò fi ìwà panṣágà tí ó ti bẹ̀rẹ̀, ni Ejibiti sílẹ̀, ní ìgbà èwe rẹ̀ àwọn ọkùnrin n bá a sùn, wọn fi ọwọ́ pa àyà èwe rẹ̀ lára wọn sì ń ṣe ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
9 therefore, did I deliver her into the hand of her lovers, - into the hand of the sons of Assyria, after whom she lusted:
“Nítorí náà mo fi i sílẹ̀ fún àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, ará Asiria, tí ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí i.
10 They disclosed her shame, Her sons and her daughters: , took they away, And herself—with the sword, they slew, — Thus became she a by-word among women, when judgments, they had executed upon her.
Wọ́n bọ́ ọ sí ìhòhò, wọ́n sì gba àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ̀ wọn sì pa wọn pẹ̀lú idà. Ó di ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ láàrín àwọn obìnrin wọ́n sì fi ìyà jẹ ẹ́.
11 And though her sister Oholibah saw, Yet became she more corrupt in her lust than the other, - And her unchaste doings exceeded the unchaste doings of her sister.
“Àbúrò rẹ̀ Oholiba rí èyí, síbẹ̀ nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ̀, Ó ba ara rẹ jẹ́ ju ẹ̀gbọ́n rẹ̀ lọ.
12 After the sons of Assyria: , she lusted Governors and deputies so warlike. Clothed in splendid array, Horsemen, riding on horses, Attractive young men, all of them.
Òun náà ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí ará Asiria àwọn gómìnà àti àwọn balógun, jagunjagun nínú aṣọ ogun, àwọn tí ń gun ẹṣin, gbogbo àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà.
13 So I saw that she defiled herself, — One way, had they both.
Mo rí i pé òun náà ba ara rẹ̀ jẹ́; àwọn méjèèjì rìn ojú ọ̀nà kan náà.
14 Yet did she add, unto her unchaste doings, when she saw men portrayed upon the wall, likenesses of Chaldeans, Portrayed with vermilion:
“Ṣùgbọ́n ó tẹ̀síwájú nínú ṣíṣe panṣágà. O ri àwòrán àwọn ọkùnrin lára ògiri, àwòrán àwọn ara Kaldea àwòrán pupa,
15 Girded with waistcloths upon their loins With overhanging high turbans upon their heads, In appearance, knights all of them, -The likeness of the sons of Babylon of Chaldea, the land of their birth.
pẹ̀lú ìgbànú ni ìdí wọn àti àwọn ìgbàrí ni orí wọn; gbogbo wọn dàbí olórí kẹ̀kẹ́ ogun Babeli ọmọ ìlú Kaldea.
16 Then lusted she after them, as soon as her eyes beheld them, — And she sent messengers unto them to Chaldea.
Ní kété tí ó rí wọn, ó ní ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ sí wọn, ó sì rán oníṣẹ́ sí wọn ni Kaldea.
17 Then came in unto her the sons of Babylon into the bed of endearments, and defiled her with their unchaste doings, - And she defiled herself with them, And then was her soul torn from them.
Àwọn ará Babeli wá sọ́dọ̀ rẹ̀, lórí ibùsùn ìfẹ́, nínú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ wọn, wọ́n bà á jẹ́. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n bà á jẹ́ tán, ó yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn ní ìtìjú.
18 Thus disclosed she her unchaste desires, And disclosed her shame, - So my soul was torn from her, Just as my soul had been torn from her sister.
Nígbà tí ó tẹ̀síwájú nínú iṣẹ́ panṣágà rẹ̀ ní gbangba wọ́n sì tú u sí ìhòhò, mo yí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ ní ìtìjú, gẹ́gẹ́ bí mo ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
19 Yea she multiplied her unchaste desires, -calling to mind the days of her youth, when she was unchaste in the land of Egypt; -
Síbẹ̀síbẹ̀ ó ń pọ̀ sí i nínú ìdàpọ̀ rẹ̀ bí ó ti ń rántí ìgbà èwe rẹ̀ tí ó jẹ́ panṣágà ní Ejibiti.
20 So she lusted after their courtiers, - Whose flesh was the flesh of asses, and Whose issue was the issue of horses.
Nítorí ó fẹ́ olùfẹ́ àwọn olùfẹ́ wọn ní àfẹ́jù, tí àwọn tí nǹkan ọkùnrin wọn dàbí ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ẹni tí ìtújáde ara wọn dàbí ti àwọn ẹṣin.
21 Yea thou didst look about for the lewdness of thy youth, - When were pressed by the Egyptians. thy bosoms, When they handled thy youthful breasts.
Báyìí ni ìwọ pe ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ìgbà èwe rẹ wá sí ìrántí, ní ti rírin orí ọmú rẹ láti ọwọ́ àwọn ará Ejibiti, fún ọmú ìgbà èwe rẹ.
22 Therefore, O Oholibah, Thus saith My Lord Yahweh, Behold me! rousing up thy lovers against thee, Even them from whom thy soul hath been torn, - And I will bring them against thee from every side:
“Nítorí náà, Oholiba, báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò gbé olólùfẹ́ rẹ dìde sí ọ, àwọn tí o kẹ́yìn si ní ìtìjú, èmi yóò sì mú wọn dojúkọ ọ́ ní gbogbo ọ̀nà
23 The sons of Babylon and all Chaldeans Pekod and Shoa and Koa, All the sons of Assyria with them, — Attractive young men Governors and deputies, all of them. Knights and men of renown, Riders on horses all of them;
àwọn ará Babeli àti gbogbo ara Kaldea àwọn ọkùnrin Pekodi àti Ṣoa àti Koa àti gbogbo ará Asiria pẹ̀lú wọn, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin arẹwà, gbogbo àwọn gómìnà àti balógun, olórí oníkẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn onípò gíga, gbogbo àwọn tí ń gun ẹṣin.
24 And they shall come upon thee— With battle-axe, chariot and wheel And with a gathered host of peoples: Shield and buckler and helmet, will they array against thee on every side, - And I will put before them judgment, And they shall judge thee with their judgments;
Wọn yóò wa dojúkọ ọ pẹ̀lú ohun ìjà, kẹ̀kẹ́ ogun pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ ẹrù àti pẹ̀lú ìwọ́jọpọ̀ ènìyàn; wọn yóò mú ìdúró wọn lòdì sí ọ ní gbogbo ọ̀nà pẹ̀lú asà ńlá àti kékeré pẹ̀lú àṣíborí. Èmi yóò yí ọ padà sí wọn fun ìjìyà, wọn yóò sì fi ìyà jẹ ọ gẹ́gẹ́ bí wọn tí tó.
25 When I set forth my jealousy against thee, Then will they deal with thee in indignation: Thy nose and thine ears, will they remove, And that which is left of thee, by the sword, shall fall, — They, will take away thy sons and thy daughters, And that which is left of thee, shall be devoured by the fire;
Èmi yóò sì dojú ìbínú owú mi kọ ọ́, wọn yóò sì fìyà jẹ ọ́ ní ìrunú. Wọ́n yóò gé àwọn imú àti àwọn etí yín kúrò, àwọn tí ó kù nínú yín yóò ti ipá idà ṣubú. Wọn yóò mú àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọkùnrin yín lọ, àwọn tí o kù nínú yín ni iná yóò jórun.
26 And they shall strip off thy raiment, - And take away thine adorning jewels!
Wọn yóò sì kó àwọn aṣọ àti àwọn ohun ọ̀ṣọ́ iyebíye yín.
27 Thus will I cause thy lewdness to cease, from thee Even thine unchastity brought from the land of Egypt, - So that thou shalt not lift up thine eyes unto them, And Egypt, shalt thou not call to mind any more.
Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti iṣẹ́ panṣágà tí ẹ bẹ̀rẹ̀ ni Ejibiti. Ẹ̀yin kò ní wo àwọn nǹkan wọ̀nyí pẹ̀lú ìpòùngbẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ kò ní rántí Ejibiti mọ.
28 For thus saith My Lord, Yahweh, Behold me! delivering thee up, into the hand of them whom thou hatest, Into the hand of them from whom thy soul hath been torn;
“Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò fi ọ lé ọwọ́ àwọn tí ó kórìíra, lọ́wọ́ àwọn ẹni tí ọkàn rẹ ti ṣí kúrò.
29 And they shall deal with thee in hatred And take away all thy labour, And leave thee utterly naked, - And thine unchaste shame, shall be disclosed, with thy lewdness and unchastities,
Wọn yóò fìyà jẹ ọ́ pẹ̀lú ìkórìíra, wọn yóò sì kó gbogbo ohun tí o ṣiṣẹ́ fún lọ. Wọn yóò fi ọ́ sílẹ̀ ní ìhòhò goloto, ìtìjú iṣẹ́ panṣágà rẹ ni yóò farahàn. Ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ̀ àti panṣágà rẹ.
30 These things shall be done to thee, In that thou hast gone unchastely after the nations, Because thou hast defiled thyself with their manufactured gods.
Èmi yóò ṣe gbogbo nǹkan wọ̀nyí sí ọ, nítorí ìwọ ti bá àwọn kèfèrí ṣe àgbèrè lọ, o sì fi àwọn òrìṣà wọn ba ara rẹ̀ jẹ́.
31 In the way of thy sister, hast thou walked, Therefore will I put her cup into thy hand.
Ìwọ ti rin ọ̀nà ti ẹ̀gbọ́n rẹ rìn, Èmi yóò sì fi ago rẹ̀ lé ọ lọ́wọ́.
32 Thus, saith My Lord Yahweh, The cup of thy sister, shalt thou drink, The cup deep and large, Thou shalt become a laughingstock and a derision, much doth it contain!
“Èyí yìí ní ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: “Ìwọ yóò mu nínú ago ẹ̀gbọ́n rẹ, ago tí ó tóbi tí ó sì jinnú: yóò mú ìfiṣẹ̀sín àti ìfiṣe ẹlẹ́yà wá, nítorí tí ago náà gba nǹkan púpọ̀.
33 With drunkenness and grief, shalt thou be filled, - The cup of astonishment and desolation, The cup of thy sister Samaria;
Ìwọ yóò mu àmupara àti ìbànújẹ́, ago ìparun àti ìsọdahoro ago ẹ̀gbọ́n rẹ Samaria.
34 Yea thou shalt drink it and drain it out And the sherds thereof, shalt thou gnaw And thy breasts, shalt thou tear out, - For, I, have spoken, Declareth My Lord. Yahweh.
Ìwọ yóò mú un ni àmugbẹ; ìwọ yóò sì fọ sí wẹ́wẹ́ ìwọ yóò sì fa ọmú rẹ̀ ya. Èmi ti sọ̀rọ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
35 Therefore, Thus, saith My Lord. Yahweh, Because thou hast forgotten me, and has cast me behind thy back, Thou also thyself, bear thou thy lewdness and thine unchaste doings.
“Nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n bí ìwọ ti gbàgbé mi, tí ìwọ sì ti fi mi sí ẹ̀yìn rẹ, ìwọ gbọdọ̀ gba àbájáde ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ àti panṣágà rẹ.”
36 And Yahweh said unto me, Son of man Wilt thou judge Oholah and Oholibah? Then declare thou unto them their abominations.
Olúwa sọ fún mi pé: “Ọmọ ènìyàn, ń jẹ́ ìwọ yóò ṣe ìdájọ́ Ohola àti Oholiba? Nítorí náà dojúkọ wọn nípa ìkórìíra tí wọn ń ṣe,
37 For they have committed adultery. And blood, is one their hands, Yea with their manufactured gods, have they committed adultery. And even their own children whom they bare unto me, have they set apart for them to be devoured.
nítorí wọn ti dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn. Wọn dá ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà pẹ̀lú àwọn òrìṣà wọn; kódà wọ́n fi àwọn ọmọ wọn tí wọn bí fún ni ṣe ìrúbọ, gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ fún wọn.
38 Yet more, this, have they done to me, They have defiled my sanctuary, on the same day, And my sabbaths, have they profaned.
Bákan náà ni wọ́n ti ṣe èyí náà sí mi. Ní àkókò kan náà wọn ba ibi mímọ́ mi jẹ́, wọ́n sì lo ọjọ́ ìsinmi mi ní àìmọ́.
39 Yea when they had slaughtered their children to their manufactured gods, then entered they into my sanctuary, on the same day, to profane it, - And lo! thus have they done in the midst of mine own house.
Ní ọjọ́ náà gan an wọ́n fi àwọn ọmọ wọn rú ẹbọ sí àwọn òrìṣà, wọn wọ ibi mímọ́ mi lọ wọn sì lò ó ní ìlòkulò. Ìyẹn ní wọn ṣe ní ilé mi.
40 Yea verily, that ye must needs send for men, ready to come in from afar, in that, a messenger, was sent unto them and lo! they came, For whom thou didst bathe thyself Paint thine eyes And deck thyself with ornaments.
“Wọn tilẹ̀ rán oníṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí wọ́n wá láti ọ̀nà jíjìn, nígbà tí wọ́n dé, ìwọ wẹ ara rẹ fún wọn, ìwọ kún ojú rẹ, ìwọ sì fi ọ̀ṣọ́ iyebíye sára.
41 Then satest thou upon a glorious couch With a table prepared before it, — And mine incense and mine oil, didst thou set thereon.
Ìwọ jókòó lórí ibùsùn ti o lẹ́wà, pẹ̀lú tábìlì tí a tẹ́ ní iwájú rẹ lórí, èyí tí o gbé tùràrí àti òróró tí ó jẹ́ tèmi kà.
42 The noise of careless throng also, was with her, And besides men out of the mass of mankind, there were brought in drunkards, out of the desert; And they put bracelets upon the hands of both women, And crowns of adorning upon their heads.
“Ariwo ìjọ ènìyàn tí kò bìkítà wà ní àyíká rẹ̀; a mú àwọn ara Sabeani láti aginjù pẹ̀lú àwọn ọkùnrin láti ara àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn aláìníláárí, wọ́n sì mú àwọn ẹ̀gbà ọrùn ọwọ́ sí àwọn ọwọ́ obìnrin náà àti ẹ̀gbọ́n rẹ̀, adé dáradára sì wà ní orí wọn.
43 Then said I of her that was worn out with adulteries, Will they now join in her unchaste doings even hers?
Lẹ́yìn náà mo sọ̀rọ̀ nípa èyí tí ó lo ara rẹ̀ sá nípa panṣágà ṣíṣe, ‘Nísinsin yìí jẹ kí wọn lo o bí panṣágà, nítorí gbogbo ohun tí ó jẹ́ nìyẹn.’
44 Yet came they in unto her, as men go in unto a woman that is a harlot, — So, came they in unto Oholah, and unto Oholibah—the lewd women!
Wọn ba sùn bí ọkùnrin ti bá panṣágà sùn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe sùn pẹ̀lú obìnrin onífẹ̀kúfẹ̀ẹ́, Ohola àti Oholiba.
45 But righteous men, they, shall judge them, With the judgment of adulteresses, and With the judgment of women that shed blood, — Because adulteresses, they are And blood, is on their hands.
Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin olódodo yóò pàṣẹ pé kí wọ́n fi ìyà jẹ àwọn obìnrin tí ó dá ẹ̀ṣẹ̀ àgbèrè tí ó sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀ nítorí pé panṣágà ni wọ́n ẹ̀jẹ̀ sì wà ní ọwọ́ wọn.
46 For thus, saith My Lord. Yahweh, - There shall be brought up against them a gathered host, Then shall they be delivered up. for a terror and for a prey,
“Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Mú àgbájọ àwọn ènìyànkénìyàn wá sọ́dọ̀ wọn ki ó sì fi wọn lé ọwọ́ ìpayà àti ìkógun.
47 Yea a gathered host shall stone them with stones, and dispatch them with their swords, Their sons and their daughters, shall they slay, And their houses—in the fire, shall they consume.
Àwọn ènìyànkénìyàn náà yóò sọ wọ́n ni òkúta, yóò sì gé wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà wọn; wọn ó sì pa àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn, wọ́n ó sì jó àwọn ilé wọn kanlẹ̀.”
48 So will I make an end of lewdness out of the land, - And all women shall be disciplined, and shall not do according to your lewdness.
“Èmi yóò sì fi òpin sí ìwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ni ilẹ̀ náà, kí gbogbo àwọn obìnrin le gba ìkìlọ̀ kí wọn kí ó ma sì ṣe fi ara wé ọ.
49 Yea the judges Shall set your lewdness upon you, And your sins with manufactured gods, shall ye bear; So shall ye know that, I, am The Lord Yahweh.
Ìwọ yóò sì jìyà fún ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ rẹ, ìwọ yóò sì gba àbájáde àwọn ẹ̀ṣẹ̀ panṣágà tí o dá. Nígbà náà ìwọ yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa Olódùmarè.”

< Ezekiel 23 >