< Exodus 15 >

1 Then, sang Moses, and the sons of Israel, this song unto Yahweh, and they spake, saying, —I will sing to Yahweh, for he is exalted, exalted, —The horse and his rider, hath he cast into the sea.
Nígbà náà ni Mose àti àwọn ọmọ Israẹli kọ orin yìí sí Olúwa, Èmi yóò kọrin sí Olúwa, nítorí òun pọ̀ ní ògo. Ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún ni ó ti sọ sínú Òkun.
2 My might and melody, is Yah, And he became mine, by salvation, —This, is my GOD, and I will glorify him, The God of my father and I will set him on high.
Olúwa ni agbára àti orin mi; òun ti di Olùgbàlà mi, òun ni Ọlọ́run mi, èmi ó yìn ín, Ọlọ́run baba mi, èmi ó gbé e ga.
3 Yahweh is a warlike one, —Yahweh, is his name.
Ológun ni Olúwa, Olúwa ni orúkọ rẹ,
4 The chariots of Pharaoh and his train, hath he cast into the sea, —Yea, the choice of his warriors, were sunk in the Sedgy Sea.
kẹ̀kẹ́ ogun Farao àti ogun rẹ̀ ni ó mú wọ inú Òkun. Àwọn ọmọ-ogun Farao tó jáfáfá jùlọ ni ó rì sínú Òkun Pupa.
5 Roaring deeps, covered them, —They went down in the raging depths like a stone.
Ibú omi bò wọ́n mọ́lẹ̀; wọ́n sì rì sí ìsàlẹ̀ omi òkun bí òkúta.
6 Thy right hand, O Yahweh is splendid in power, —Thy right hand, O Yahweh dasheth in pieces a foe;
“Ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Olúwa, pọ̀ ní agbára. Ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Olúwa, fọ́ àwọn ọ̀tá túútúú.
7 And in the greatness of thine exaltation, dost thou tear down thine opposers, —Thou dost send forth thy wrath, it consumeth them as straw;
“Nínú agbára ńlá rẹ ti ó tóbi ìwọ bi àwọn ti ó dìde sí ọ ṣubú. Ìwọ rán ìbínú gbígbóná rẹ; tí ó run wọ́n bí àgémọ́lẹ̀ ìdí koríko.
8 And with the blast of thy nostrils, heaped up are the waters, Upreared like a mound, are the flowing waves, —Roaring deeps are congealed in the heart of the sea.
Pẹ̀lú èémí imú rẹ ni omi fi ń wọ́jọ pọ̀. Ìṣàn omi dìde dúró bí odi; ibú omi sì dìpọ̀ láàrín Òkun.
9 Said the foe—I will pursue—overtake divide spoil, —Take her fill of them—shall my soul, I will bare my sword, root them out—shall my hand.
Ọ̀tá ń gbéraga, ó ń wí pé, ‘Èmi ó lépa wọn, èmi ó bá wọn. èmi ó pín ìkógun; èmi ó tẹ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ mi lọ́run lára wọn. Èmi yóò fa idà mi yọ, ọwọ́ mi yóò pa wọ́n run.’
10 Thou didst blow with thy wind they were covered by the sea, —They rolled like lead, into the waters so wide.
Ìwọ fẹ́ èémí rẹ, òkun ru bò wọ́n mọ́lẹ̀. Wọ́n rì bí òjé ni àárín omi ńlá.
11 Who is, like unto thee, among the mighty O Yahweh? Who is, like unto thee, Majestic in holiness, —To be revered in praises, Doing a marvellous thing?
Ta ni nínú àwọn òrìṣà tó dàbí rẹ, Olúwa? Ta ló dàbí rẹ: ní títóbi, ní mímọ́ Ẹlẹ́rù ni yìn, tí ń ṣe ohun ìyanu?
12 Thou didst stretch forth thy right hand, earth swallowed them up.
“Ìwọ na apá ọ̀tún rẹ, ilẹ̀ si gbé wọn mì.
13 Thou hast led forth in thy lovingkindness, the people which thou hast redeemed, —Thou hast guided them in thy might into the home of thy holiness.
Nínú ìfẹ́ rẹ ti kì í sákí Ìwọ ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn náà tí Ìwọ ti rà padà. Nínú agbára rẹ Ìwọ yóò tọ́ wọn, lọ sí ibi ìjókòó rẹ mímọ́.
14 Peoples have heard they tremble, —A pang, hath seized the dwellers of Philistia:
Orílẹ̀-èdè yóò gbọ́ wọn yóò wárìrì. Ìkáàánú yóò mi àwọn ènìyàn Filistia.
15 Then, were amazed the chiefs of Edom, The mighty ones of Moab, there seizeth them, a trembling, —Melted away, have all the dwellers of Canaan:
Ìbẹ̀rù yóò mú àwọn ìjòyè Edomu, àwọn olórí Moabu yóò wárìrì. Àwọn ènìyàn Kenaani yóò sì yọ́ dànù.
16 There falleth upon them a terror and dread, With the greatness of thine arm, are they struck dumb as a stone, —Till thy people pass over O Yahweh, Till the people pass over, which thou hast made thine own: —
Ìbẹ̀rù bojo yóò ṣubú lù wọ́n, nítorí nína títóbi apá rẹ̀ wọn yóò dúró jẹ́ẹ́ láì mira bí i òkúta, títí àwọn ènìyàn rẹ yóò fi rékọjá, Olúwa, títí tí àwọn ènìyàn tí o ti rà yóò fi rékọjá.
17 Thou bringest them in and plantest them, In the mountain of thine inheritance, Thy dwelling-place to abide in which thou hast made, O Yahweh, —A hallowed place O My Lord which thy hands have established.
Ìwọ yóò mú wọn wá láti gbìn wọ́n ni orí òkè ti ìwọ jogún, ní ibi ti ìwọ ṣe fún ara rẹ, Olúwa. Láti máa gbé ibi mímọ́ ti ìwọ fi ọwọ́ rẹ gbé kalẹ̀, Olúwa.
18 Yahweh, shall reign unto times age-abiding and beyond.
“Olúwa yóò jẹ ọba láé àti láéláé.”
19 For the horses of Pharaoh, with his chariots and his horsemen, entered into the sea, Then did Yahweh bring back upon them the waters of the sea, —But the sons of Israel, had gone their way on the dry ground through the midst of the sea.
Nígbà ti ẹṣin Farao, kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀ wọ inú Òkun, Olúwa mú kí omi òkun padà bò wọ́n mọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli rìn lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ la òkun kọjá.
20 Then took Miriam the prophetess, sister of Aaron the timbrel in her hand, —and all the women came forth after her with timbrels and dances,
Miriamu wòlíì obìnrin, arábìnrin Aaroni, mú ohun èlò orin ni ọwọ́ rẹ̀, gbogbo àwọn obìnrin sì jáde tẹ̀lé e pẹ̀lú ìlù òun ijó.
21 And Miriam responded to the men, Sing to Yahweh for he is exalted—exalted, The horse and his rider, hath he cast into the sea.
Miriamu kọrin sí wọn báyìí pé, “Ẹ kọrin sí Olúwa, nítorí òun ni ológo jùlọ. Ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún, ni òun bi ṣubú sínú Òkun.”
22 And Moses caused Israel to break up from the Red Sea, and they went out into the desert of Shur, —and journeyed three days in the desert and found no water;
Nígbà náà ni Mose ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn Israẹli jáde láti Òkun Pupa lọ sínú ijù Ṣuri. Wọ́n lọ ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sínú ijù náà, wọn kò sì rí omi.
23 and, when they came in towards Marah they could not drink the waters of Marah, for they were bitter, —for this cause, was the name thereof called Marah.
Nígbà tí wọ́n dé Mara, wọn kò lè mu omi Mara nítorí omi náà korò. (Nítorí náà ni a ṣe pe ibẹ̀ ni Mara: ibi ìkorò.)
24 So the people murmured against Moses—saying, What are we to drink?
Àwọn ènìyàn ń kùn sí Mose wí pé, “Kí ni àwa yóò mu?”
25 And he made outcry unto Yahweh, and Yahweh pointed out a tree, and he cast it into the waters, and the waters became sweet, —There, he appointed him a statute and regulation And, there, he put him to the proof.
Mose sì ké pe Olúwa, Olúwa sì fi igi kan hàn án, ó sì sọ igi náà sínú omi, omi náà sì dùn. Níbẹ̀ ni Olúwa ti gbé ìlànà àti òfin kalẹ̀ fún wọn, níbẹ̀ ni ó sì ti dán wọn wò.
26 And he said: If thou, wilt indeed hearken, to the voice of Yahweh thy God, And the thing that is right in his eyes, thou wilt do, And so give ear to his commandments, And keep all his statutes, None of the sicknesses which I laid on the Egyptians, will I lay upon thee, For, I, am Yahweh, thy physician.
Ó wí pé, “Bí ìwọ bá fetísílẹ̀ dáradára sí òfin Olúwa Ọlọ́run, ti ìwọ sì ṣe ohun tí ó tọ́ ni ojú rẹ̀, ti ìwọ sì tẹ̀lé ohun tí ó pàṣẹ, ti ìwọ si pa ìlànà rẹ̀ mọ́. Èmi kì yóò jẹ́ kí èyíkéyìí nínú àwọn ààrùn wọ̀n-ọn-nì ti mo mú wá sórí àwọn ará Ejibiti wá sí ara rẹ, nítorí Èmi ni Olúwa ti ó mú ọ láradá.”
27 Then came they in to Elim, and there, were twelve fountains of water and seventy palm-trees, —so they encamped there, by the waters.
Nígbà ti wọ́n dé Elimu, níbi ti kànga omi méjìlá àti àádọ́rin ọ̀pẹ gbé wà, wọ́n pàgọ́ síbẹ̀ ni etí omi.

< Exodus 15 >