< Deuteronomy 28 >

1 And it shall be, if thou wilt, hearken, unto the voice of Yahweh thy God, to observe to do all his commandments which I am commanding thee to-day, then will Yahweh thy God set thee on high, above all the nations of the earth;
Bí ìwọ bá gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ ní kíkún kí o sì kíyèsára láti tẹ̀lé gbogbo ohun tí ó pàṣẹ tí mo fi fún ọ lónìí, Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbé ọ lékè ju gbogbo orílẹ̀-èdè ayé lọ.
2 and all these blessings shall come in upon thee, and reach thee, —because thou dost hearken unto the voice of Yahweh thy God: —
Gbogbo ìbùkún yìí yóò wá sórí rẹ yóò sì máa bá ọ lọ bí o bá gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
3 Blessed shalt, thou be in the city, —and blessed shalt thou be in the field:
Ìbùkún ni fún ọ ni ìlú, ìbùkún ni fún ọ ní oko.
4 Blessed shall be the fruit of thy body, and the fruit of thy ground and the fruit of thy cattle, —the young of thy kine, and the ewes of thy flock:
Ìbùkún ni fún ọmọ inú rẹ, àti èso ilẹ̀ rẹ, àti irú ohun ọ̀sìn rẹ àti ìbísí i màlúù rẹ àti ọmọ àgùntàn rẹ.
5 Blessed, shall be thy basket and thy kneading-trough:
Ìbùkún ni fún agbọ̀n rẹ àti fún ọpọ́n ipò ìyẹ̀fun rẹ.
6 Blessed, shalt thou be when thou comest in, —and, blessed, shalt thou be when thou goest out:
Ìbùkún ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá wọlé, ìbùkún ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá jáde.
7 Yahweh will deliver thine enemies who rise up against thee, to be routed before thee, —one way, shall they come out against thee, and seven ways, shall they flee before thee:
Olúwa yóò gbà fún ọ pé gbogbo ọ̀tá tí ó dìde sí ọ yóò bì ṣubú níwájú rẹ. Wọn yóò tọ̀ ọ́ wá ní ọ̀nà kan ṣùgbọ́n wọn yóò sá fún ọ ní ọ̀nà méje.
8 Yahweh will command to be with thee the blessing, in thy storehouses and in all whereunto thou settest thy hand, —and will bless thee in the land which Yahweh thy God is giving unto thee:
Olúwa yóò rán ìbùkún sí ọ àti sí ohun gbogbo tí o bá dáwọ́ rẹ lé. Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò bùkún un fún ọ nínú ilẹ̀ tí ó ń fi fún ọ.
9 Yahweh will confirm thee unto himself for a holy people, as he sware unto thee, —because thou dost keep the commandments of Yahweh thy God, and dost walk in his ways.
Olúwa yóò fi ọ́ múlẹ̀ bí ènìyàn mímọ́, bí ó ti ṣe ìlérí fún ọ lórí ìbúra, bí o bá pa àṣẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ mọ́ tí o sì ń rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
10 And all the peoples of the earth shall see that, the name of Yahweh, hath been called upon thee, —and shall be afraid of thee.
Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn tí ó wà ní ayé yóò rí i pé a pè ọ́ ní orúkọ Olúwa, wọn yóò sì bẹ̀rù rẹ.
11 And Yahweh will cause thee to abound in that which is good, in the fruit of thy body, and in the fruit of thy cattle and in the fruit of thy soil, —upon the soil which Yahweh sware unto thy fathers, to give unto thee:
Olúwa yóò fi àlàáfíà fún ọ ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́, fún ọmọ inú rẹ, irú ohun ọ̀sìn rẹ àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ ní ilẹ̀ tí ó ti búra fún àwọn baba ńlá rẹ láti fún ọ.
12 Yahweh will open unto thee his rich storehouse—the heavens, to give the rain of thy land in its season, and to bless every work of thy hand, so shalt thou lend unto many nations, but thou, shalt not borrow:
Olúwa yóò ṣí ọ̀run sílẹ̀, ìṣúra rere rẹ̀ fún ọ, láti rọ òjò sórí ilẹ̀ rẹ ní àsìkò rẹ àti láti bùkún gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ ọ̀ rẹ. Ìwọ yóò yá ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè ṣùgbọ́n ìwọ kò ní í yá lọ́wọ́ ẹnìkankan.
13 And Yahweh, will give thee, to be the head, and not the tail, and thou shalt be only above, and shalt not be beneath, —because thou dost hearken unto the commandments of Yahweh thy God, which I am commanding thee, to-day, to observe and to do;
Olúwa yóò fi ọ́ ṣe orí, ìwọ kì yóò sì jẹ́ ìrù. Bí o bá fi etí sílẹ̀ sí àṣẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ tí mo fi fún ọ kí o sì máa rọra tẹ̀lé wọn, ìwọ yóò máa wà lókè, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò wà ní ìsàlẹ̀ láé.
14 and dost not turn side from any of the words which I am commanding you to-day, to the right hand or to the left, —to go after other gods, to serve them,
Má ṣe yà sọ́tùn tàbí sósì kúrò, nínú èyíkéyìí àwọn àṣẹ tí mo fi fún ọ ní òní yìí, kí o má ṣe tẹ̀lé àwọn ọlọ́run mìíràn láti máa sìn wọ́n.
15 But it shall be, if thou do not hearken unto the voice of Yahweh thy God, to observe to do all his commandments and his statutes which I am commanding thee to-day, then shall come in upon thee all these curses and shall reach thee: —
Ṣùgbọ́n bí o kò bá gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ kí o sì rọra máa tẹ̀lé gbogbo àṣẹ àti òfin rẹ̀ tí mò ń fún ọ lónìí, gbogbo ègún yìí yóò wá sórí rẹ yóò sì máa bá ọ lọ.
16 Cursed, shalt thou be in the city, —and cursed, shalt thou be in the field:
Ègún ni fún ọ ní ìlú, ègún ni fún ọ ní oko.
17 Cursed, shall be thy basket, and thy kneading-trough:
Ègún ni fún agbọ̀n rẹ àti ọpọ́n ìpo-fúláwà rẹ.
18 Cursed, shall be the fruit of thy body, and the fruit of thy ground—the young of thy kine and the ewes of thy flock:
Ègún ni fún ọmọ inú rẹ, àti èso ilẹ̀ rẹ, ìbísí màlúù rẹ àti ọmọ àgùntàn rẹ.
19 Cursed, shalt thou be, when thou comest in, —and, cursed, shalt thou be, when thou goest out:
Ègún ni fún ọ nígbà tí o bá wọlé ègún sì ni fún ọ nígbà tí ìwọ bá jáde.
20 Yahweh will send upon thee cursing, confusion and rebuke, in all whereunto thou settest thy hand that thou mayest do it, —until thou be destroyed and until thou perish quickly, because of the wickedness of thy doings, whereby thou hast forsaken me.
Olúwa yóò rán ègún sórí rẹ, rúdurùdu àti ìfibú nínú gbogbo ohun tí o bá dáwọ́ rẹ lé, títí ìwọ yóò fi parun àti wá sí ìparun lójijì nítorí búburú tí o ti ṣe ní kíkọ̀ mi sílẹ̀.
21 Yahweh will cause to cleave unto thee—the pestilence, —until he hath consumed thee from off the soil which thou art entering to possess.
Olúwa yóò fi àjàkálẹ̀-ààrùn bá ọ jà títí tí yóò fi pa ọ́ run kúrò ní ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
22 Yahweh, will smite thee, with consumption and with fever, and with inflammation and with violent heat and with the sword, and with blight and with mildew, —and they shall pursue thee, until thou perish.
Olúwa yóò kọlù ọ́ pẹ̀lú ààrùn ìgbẹ́, pẹ̀lú ibà àti àìsàn wíwú, pẹ̀lú ìjóni ńlá àti idà, pẹ̀lú ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù tí yóò yọ ọ́ lẹ́nu títí ìwọ yóò fi parun.
23 And thy heavens which are over thy head shall become bronze, —and the earth which is under thee iron.
Ojú ọ̀run tí ó wà lórí rẹ yóò jẹ́ idẹ, ilẹ̀ tí ń bẹ níṣàlẹ̀ rẹ yóò sì jẹ́ irin.
24 Yahweh will cause the rain of thy land to be powder and dust, —out of the heavens, shall it come down upon thee, until thou be destroyed.
Olúwa yóò yí òjò ilẹ̀ rẹ sí eruku àti ẹ̀tù; láti ọ̀run ni yóò ti máa sọ̀kalẹ̀ sí ọ, títí tí ìwọ yóò fi run.
25 Yahweh will give thee up to be routed before thine enemies, one way, shalt thou go out against them, and, seven ways, shalt thou flee before them, —and thou shalt become a terror unto all the kingdoms of the earth.
Olúwa yóò fi ọ́ gégùn ún láti ṣubú níwájú àwọn ọ̀tá rẹ. Ìwọ yóò tọ̀ wọ́n wá ní ọ̀nà kan ṣùgbọ́n ìwọ yóò sá fún wọn ní ọ̀nà méje, ìwọ yóò sì padà di ohun ìbẹ̀rù fún gbogbo ìjọba lórí ayé.
26 And thy dead body shall become food for every bird of the heavens, and for the beast of the earth, —with none to fright them away.
Òkú rẹ yóò jẹ́ oúnjẹ fún gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún ẹranko ayé, àti pé kò ní sí ẹnikẹ́ni tí yóò lé wọn kúrò.
27 Yahweh, will smite thee, with the burning sores of Egypt and with the hemorrhoids, and with scab, and with itch, —of which thou canst not be healed.
Olúwa yóò bá ọ jà pẹ̀lú oówo, Ejibiti àti pẹ̀lú kókó, ojú egbò kíkẹ̀ àti ìhúnra.
28 Yahweh, will smite thee, with madness and with blindness, —and with terror of heart;
Olúwa yóò bá ọ jà pẹ̀lú ìsínwín, ojú fífọ́ àti rúdurùdu àyà.
29 and thou shalt he groping about in noonday brightness, as the blind man gropeth in thick darkness, and thou shalt not make thy ways prosper, —but shalt be only oppressed and spoiled all the days with none to save.
Ní ọ̀sán gangan ìwọ yóò fi ọwọ́ tálẹ̀ kiri bí ọkùnrin afọ́jú nínú òkùnkùn ìwọ kì yóò ṣe àṣeyọrí nínú ohun gbogbo tí o bá ń ṣe, ojoojúmọ́ ni wọn yóò máa ni ọ́ lára àti jà ọ́ ní olè, tí kò sì ní í sí ẹnìkan láti gbà ọ́.
30 A wife, shalt thou betroth, and, another man shall lie with her. A house, shalt thou build, and shalt not dwell therein, —A vineyard, shalt thou plant, and shalt not throw it open;
Ìwọ yóò gba ògo láti fẹ́ obìnrin kan ṣùgbọ́n ẹlòmíràn yóò gbà á yóò sì tẹ́ ẹ́ ní ògo. Ìwọ yóò kọ́ ilé, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò gbé ibẹ̀. Ìwọ yóò gbin ọgbà àjàrà, ṣùgbọ́n ìwọ kò tilẹ̀ ní gbádùn èso rẹ.
31 Thine ox slaughtered before thine eyes, and thou shalt not eat thereof, Thine ass stolen from before thee, and shall not be restored to thee, —Thy flock given to thine enemies, and thou shalt have none to save.
Màlúù rẹ yóò di pípa níwájú rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò jẹ nǹkan kan nínú rẹ̀. Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ yóò sì di mímú pẹ̀lú agbára kúrò lọ́dọ̀ rẹ, a kì yóò sì da padà. Àgùntàn rẹ yóò di mímú fún àwọn ọ̀tá rẹ, ẹnìkankan kò sì ní gbà á.
32 Thy sons and thy daughters given to another people, thine eyes looking on, and failing for them all the day, thine own hand being powerless.
Àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin rẹ yóò di mímú fún àwọn orílẹ̀-èdè mìíràn, ìwọ yóò sì fi ojú rẹ ṣọ́nà dúró dè wọ́n láti ọjọ́ dé ọjọ́, ìwọ yóò sì jẹ́ aláìlágbára láti gbé ọwọ́.
33 The fruit of thy soil, and all thy toilsome produce, shall a people whom thou knowest not, eat up, —and thou shalt be only oppressed and crushed, all the days;
Èso ilẹ̀ rẹ àti gbogbo iṣẹ́ làálàá rẹ ni orílẹ̀-èdè mìíràn tí ìwọ kò mọ̀ yóò sì jẹ, ìwọ yóò jẹ́ kìkì ẹni ìnilára àti ẹni ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
34 so that thou shalt be mad, —for the sight of thine eyes which thou shalt see.
Ìran tí ojú rẹ yóò rí, yóò sọ ọ́ di òmùgọ̀.
35 Yahweh, will smite thee, with a grievous boil, upon the knees and upon the legs, of which thou canst not be healed, —from the sole of thy foot even unto the crown of thy head.
Olúwa yóò lu eékún àti ẹsẹ̀ rẹ pẹ̀lú oówo dídùn tí kò le san tán láti àtẹ̀lé méjèèjì rẹ lọ sí òkè orí rẹ.
36 Yahweh will bring thee and thy king whom thou wilt set up over thee, unto a nation which thou hast not known, thou nor thy fathers, —and thou shalt serve there other gods of wood and of stone.
Olúwa yóò lé ọ àti ọba tí ó yàn lórí rẹ lọ sí orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò mọ̀ tàbí ti àwọn baba rẹ kò mọ̀. Ibẹ̀ ni ìwọ̀ yóò sì sin ọlọ́run mìíràn, ọlọ́run igi àti òkúta.
37 Thus shalt thou become a horror, a byword, and a mockery, among all the peoples whither Yahweh thy God will drive thee.
Ìwọ yóò di ẹni ìyanu, àti ẹni òwe, àti ẹni ìfisọ̀rọ̀ sọ nínú gbogbo orílẹ̀-èdè tí Olúwa yóò darí rẹ sí.
38 Much seed, shalt thou take out into the field, —and little, shalt thou gather in, for the locust shall consume it.
Ìwọ yóò gbin irúgbìn púpọ̀ ṣùgbọ́n ìwọ yóò kórè kékeré, nítorí eṣú yóò jẹ ẹ́ run.
39 Vineyards, shalt thou plant, and dress, —but wine, shalt thou not drink, neither shalt thou gather the grapes, for the worm shall eat them.
Ìwọ yóò gbin ọgbà àjàrà púpọ̀ ìwọ yóò sì ro wọ́n ṣùgbọ́n kò ní mú wáìnì náà tàbí kó àwọn èso jọ, nítorí kòkòrò yóò jẹ wọ́n run.
40 Olive trees, shalt thou have in all thy bounds, —but with oil, shalt thou not anoint thyself, for thine olives, shall drop off.
Ìwọ yóò ní igi olifi jákèjádò ilẹ̀ rẹ ṣùgbọ́n ìwọ kò ní lo òróró náà, nítorí olifi náà yóò rẹ̀ dànù.
41 Sons and daughters, shalt thou beget, and they shall not be thine, for they shall go into captivity.
Ìwọ yóò ní àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin ṣùgbọ́n ìwọ kò nípa wọ́n mọ́, nítorí wọn yóò lọ sí ìgbèkùn.
42 All thy trees, and the fruit of thy ground, shall the grasshopper, devour.
Ọ̀wọ́ eṣú yóò gba gbogbo àwọn igi rẹ àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ.
43 The sojourner who is in thy midst, shall mount up above thee higher and higher, —whereas, thou, shalt come down lower and lower:
Àjèjì tí ń gbé láàrín rẹ yóò gbé sókè gíga jù ọ́ lọ, ṣùgbọ́n ìwọ yóò máa di ìrẹ̀sílẹ̀.
44 he, shall lend to thee, but, thou, shalt not lend to him, —he, shall become head, and, thou, shalt become tail.
Yóò yà ọ́, ṣùgbọ́n o kì yóò yà á, òun ni yóò jẹ́ orí, ìwọ yóò jẹ́ ìrù.
45 Moreover, all these curses, shall come in upon thee, and pursue thee and overtake thee, until thou be destroyed, —because thou didst not hearken unto the voice of Yahweh thy God, to keep his commandments and his statutes which he hath commanded thee;
Gbogbo ègún yìí yóò wá sórí rẹ, wọn yóò lé ọ wọn yóò sì bá ọ títí tí ìwọ yóò fi parun, nítorí ìwọ kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ìwọ kò sì kíyèsi àṣẹ àti òfin tí ó fi fún ọ.
46 and they shall be upon thee, for a sign, and for a wonder, and upon thy seed, unto times age-abiding.
Wọn yóò jẹ́ àmì àti ìyanu fún ọ àti fún irú-ọmọ rẹ títí láé.
47 Because thou servedst not Yahweh thy God, with rejoicing, and with gladness of heart, for abundance of all things,
Nítorí ìwọ kò sin Olúwa Ọlọ́run rẹ ní ayọ̀ àti inú dídùn ní àkókò àlàáfíà.
48 therefore shalt thou serve thine enemies, whom Yahweh will send against thee, with hunger and with thirst and with nakedness, and with want of all things, —and he, will put a yoke of iron upon thy neck, until he hath destroyed thee.
Nítorí náà nínú ebi àti òǹgbẹ, nínú ìhòhò àti àìní búburú, ìwọ yóò sin àwọn ọ̀tá à rẹ tí Olúwa rán sí ọ. Yóò sì fi àjàgà irin bọ̀ ọ́ ní ọrùn, títí yóò fi run ọ́.
49 Yahweh will bring against thee a nation from afar, from the end of the earth, as darteth a bird of prey, —a nation whose tongue thou canst not understand;
Olúwa yóò mú àwọn orílẹ̀-èdè wá sí ọ láti ọ̀nà jíjìn, bí òpin ayé, bí idì ti ń bẹ́ láti orí òkè sílẹ̀, orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò gbọ́ èdè wọn.
50 a nation of fierce countenance, —who wilt not respect an elder nor to the young, show favour;
Orílẹ̀-èdè tí ó rorò tí kò ní ojúrere fún àgbà tàbí àánú fún ọmọdé.
51 then shall he eat the young of thy cattle and the fruit of thy ground until thou art destroyed, who will not leave for thee corn, new wine or oil, the young of thy kine, or the ewes of thy flock, —until he hath caused thee to perish.
Wọn yóò jẹ ohun ọ̀sìn rẹ run àti àwọn èso ilẹ̀ rẹ títí tí ìwọ yóò fi parun. Wọn kì yóò fi hóró irúgbìn kan fún ọ, wáìnì tuntun tàbí òróró, tàbí agbo ẹran màlúù rẹ kankan tàbí ọ̀wọ́ ẹran àgùntàn rẹ títí ìwọ yóò fi run.
52 And he shall lay siege to thee in all thy gates, until thy high and fortified walls come down wherein thou wast trusting, in all thy land, —yea he will lay siege to thee in all thy gates, in all thy land which Yahweh thy God, hath given, unto thee.
Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú rẹ títí tí odi ìdáàbòbò gíga yẹn tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé yóò fi wó lulẹ̀. Wọn yóò gbógun ti gbogbo ìlú rẹ jákèjádò ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fún ọ.
53 And thou wilt eat the fruit of thy body, the flesh of thy sons and of thy daughters, whom Yahweh thy God hath given unto thee—in the siege and in the straitness wherewith thine enemy will straiten thee.
Ìwọ ó sì jẹ èso ọmọ inú rẹ̀, ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti ti àwọn ọmọ rẹ obìnrin tí Olúwa Ọlọ́run ti fi fún ọ; nínú ìdótì náà àti nínú ìhámọ́ náà tí àwọn ọ̀tá rẹ yóò há ọ mọ́.
54 The man that is tender among you, and exceedingly delicate, his eye will be jealous of his brother and of the wife of his bosom, and of the remnant of his sons, whom be might leave behind;
Ọkùnrin tí àwọ̀ rẹ̀ tutù nínú yín, tí ó sì ṣe ẹlẹgẹ́, ojú rẹ̀ yóò korò sí arákùnrin rẹ̀ àti sí aya oókan àyà rẹ̀, àti sí ìyókù ọmọ rẹ̀ tí òun jẹ kù.
55 so that he will not give to any one of them, of the flesh of his sons which he will eat, because he hath nothing at all left him, —in the siege and in the straitness wherewith thine enemy will straiten thee within all thy gates.
Bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fún ẹnikẹ́ni nínú ẹran-ara àwọn ọmọ rẹ̀ tí ó ń jẹ, nítorí kò sí ohun kan tí ó kù sílẹ̀ fún un nínú ìdótì náà àti ìhámọ́, tí àwọn ọ̀tá yóò fi há ọ mọ́ ní ibodè rẹ gbogbo.
56 The tender and delicate woman among you who hath never adventured the sole of her foot to set it upon the ground, through delicateness and through tenderness, her eye shall be jealous of the husband of her bosom, and of her own son, and of her own daughter;
Obìnrin tí àwọ̀ rẹ̀ tutù nínú yín, tí ó sì ṣe ẹlẹgẹ́, tí kò jẹ́ dáṣà láti fi àtẹ́lẹsẹ̀ ẹ rẹ̀ kan ilẹ̀ nítorí ìkẹ́ra àti ìwà ẹlẹgẹ́, ojú u rẹ̀ yóò korò sí ọkọ oókan àyà rẹ̀, àti sí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti ọmọ rẹ̀ obìnrin,
57 both as to her afterbirth that cometh forth from between her feet and as to her children which she shall bear, for she will eat them for want of all things secretly, —in the siege and in the straitness wherewith thine enemy will straiten thee within thine own gates.
àti sí ọmọ rẹ̀ tí ó ti agbede-méjì ẹsẹ̀ rẹ̀ jáde, àti sí àwọn ọmọ rẹ̀ tí yóò bí. Nítorí òun ó jẹ wọ́n ní ìkọ̀kọ̀, nítorí àìní ohunkóhun nínú ìdótì àti ìhámọ́ náà, tí àwọn ọ̀tá yóò fi há ọ mọ́ ní ibodè rẹ.
58 If thou wilt not take heed to do all the words of this law, which are written in this scroll, —to revere this glorious and reverend name, Yahweh thy God,
Bí ìwọ kò bá rọra tẹ̀lé gbogbo àwọn ọ̀rọ̀ òfin yìí, tí a kọ sínú ìwé yìí, tí ìwọ kò sì bu ọlá fún ògo yìí àti orúkọ dáradára: orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ,
59 then will Yahweh make thy plagues wonderful, and the plagues of thy seed, —plagues great and lasting, and diseases grievous and lasting;
Olúwa yóò sọ ìyọnu rẹ di ìyanu, àti ìyọnu irú-ọmọ ọ̀ rẹ, àní àwọn ìyọnu ńlá èyí tí yóò pẹ́, àti ààrùn búburú èyí tí yóò pẹ́.
60 and he will bring back on thee all the sickness of Egypt, because of which thou wast afraid, —and they shall cleave unto thee;
Olúwa yóò mú gbogbo ààrùn Ejibiti tí ó mú ẹ̀rù bà ọ́ wá padà bá ọ, wọn yóò sì lẹ̀ mọ́ ọ.
61 even every disease and, every plague, which are not written in this scroll of the law, will Yahweh bring up against thee, until thou art destroyed,
Olúwa yóò tún mú onírúurú àìsàn àti ìpọ́njú tí a kò kọ sínú ìwé òfin yìí wá sórí rẹ, títí ìwọ yóò fi run.
62 And ye shall be left men few in number, whereas ye had become as the stars of the heavens for multitude, —because thou hast not hearkened unto the voice of Yahweh thy God.
Ìwọ tí ó dàbí àìmoye bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run yóò ṣẹ́ku kékeré níye, nítorí tí o kò ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run rẹ.
63 And it shall come to pass that as Yahweh rejoiced over you to do you good and to multiply you, so, will Yahweh rejoice over you, to cause you to perish and to destroy you, —and ye shall be torn away, from off the soil, whither thou art going in to possess it;
Gẹ́gẹ́ bí ó ti dùn mọ́ Olúwa nínú láti mú ọ ṣe rere àti láti pọ̀ si ní iye, bẹ́ẹ̀ ni yóò dùn mọ́ ọ nínú láti bì ọ́ ṣubú kí ó sì pa ọ́ run. Ìwọ yóò di fífà tu kúrò lórí ilẹ̀ tí ò ń wọ̀ lọ láti ní.
64 and Yahweh will scatter thee among all the peoples, from one end of the earth even unto the other end of the earth, —and thou wilt serve there other gods whom thou hast not known—thou nor thy fathers, —of wood and of stone.
Nígbà náà ni Olúwa yóò fọ́n ọ ká láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè, láti òpin kan ní ayé sí òmíràn. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò ti sin ọlọ́run mìíràn: ọlọ́run igi àti ti òkúta. Èyí tí ìwọ àti àwọn baba rẹ kò mọ̀.
65 And among those nations, shalt thou find no ease, neither shall there be a place of rest for the sole of thy foot, —but Yahweh will give unto thee there a trembling heart, and a failing of eyes and faintness of soul.
Ìwọ kì yóò sinmi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà, kò sí ibi ìsinmi fún àtẹ́lẹsẹ̀ rẹ. Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti fún ọ ní ọkàn ìnàngà, àárẹ̀ ojú, àti àìnírètí àyà.
66 And thy life will be hung up for thee in front, —and thou wilt be in dread by night and by day, and wilt not trust in thy life.
Ìwọ yóò gbé ní ìdádúró ṣinṣin, kún fún ìbẹ̀rùbojo lọ́sàn án àti lóru, bẹ́ẹ̀ kọ́ láé ni ìwọ yóò rí i ní àrídájú wíwà láyé rẹ.
67 In the morning, thou wilt say—Oh that it were evening! and in the evening, thou wilt say—Oh that it were morning! because of the dread of thy heart which thou wilt dread, and because of the sight of thine eyes which thou wilt see.
Ìwọ yóò wí ní òwúrọ̀ pé, “Bí ó tilẹ̀ lè jẹ́ pé ìrọ̀lẹ́ nìkan ni!” Nítorí ẹ̀rù tí yóò gba ọkàn rẹ àti ìran tí ojú rẹ yóò máa rí.
68 And Yahweh will take thee back again to Egypt in ships, by the way whereof I said unto thee, Thou shalt not again any more see it. And ye will offer yourselves there for sale unto thine enemies as servants and as handmaids with no one to buy.
Olúwa yóò rán ọ padà nínú ọkọ̀ sí Ejibiti sí ìrìnàjò tí mo ní ìwọ kì yóò lọ mọ́. Níbẹ̀ ni ìwọ yóò tún fi ara rẹ fún àwọn ọ̀tá à rẹ gẹ́gẹ́ bí ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí yóò rà ọ́.

< Deuteronomy 28 >