< 2 Timothy 1 >

1 Paul, an apostle of Christ Jesus, through the will of God, —according to the promise of life in Christ Jesus; —
Paulu, aposteli ti Jesu Kristi nípa ìfẹ́ Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìlérí ìyè ti ń bẹ nínú Kristi Jesu,
2 Unto Timothy, my beloved child: Favour, mercy, peace, from God our Father, and Christ Jesus our Lord.
Sí Timotiu, ọmọ mi olùfẹ́ ọ̀wọ́n: Oore-ọ̀fẹ́, àánú àti àlàáfíà láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run Baba wa, àti Kristi Jesu Olúwa wa.
3 Grateful, am I, unto God, —unto whom I am rendering divine service from my progenitors in a pure conscience, that, incessant, hold I the remembrance, concerning thee, in my supplications; day and night,
Mo dá ọpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run, ẹni tí èmi ń sìn pẹ̀lú ẹ̀rí ọkàn mímọ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn baba mi ti í ṣe, pé ni àìsimi lọ́sàn án àti lóru ni mo ń ṣe ìrántí rẹ nínú àdúrà mi.
4 longing to see thee, being mindful of thy tears, —in order that, with joy, I may be filled:
Bí mo ti rántí omijé rẹ, bẹ́ẹ̀ ni mo ń fẹ́ láti rí ọ kí èmi kí ó lè kún fún ayọ̀.
5 A reminder, having received, of the unfeigned faith, that is in thee, —such, as dwelt first in thy grandmother Lois, and in thy mother Eunice, —I am persuaded, moreover, that [it dwelleth], in thee also.
Nígbà ti mo bá rántí ìgbàgbọ́ àìṣẹ̀tàn rẹ, èyí ti ó kọ́kọ́ ń bẹ nínú Loisi ìyá ńlá rẹ, àti nínú Eunike ìyá rẹ̀ àti, èyí tí ó dá mi lójú pé ó ń gbé inú rẹ̀ pẹ̀lú.
6 For which cause, I put thee in remembrance, to be stirring up God’s gift of favour, which is in thee through means of the laying on of my hands;
Nítorí ìdí èyí ni mo ṣe ń ran ọ létí pé kí ó máa rú ẹ̀bùn Ọlọ́run sókè èyí ti ń bẹ nínú rẹ nípa ìgbọ́wọ́lé mi.
7 For God hath not given us a spirit of cowardice, but of power, and love, and correction.
Nítorí pé Ọlọ́run kò fún wa ni ẹ̀mí ìbẹ̀rù, bí kò ṣe ti agbára, àti ti ìfẹ́, àti ti ìsẹ́ra-ẹni ti ó yè kooro.
8 Be not thou, therefore, put to shame—with regard to the witness of our Lord, nor with regard to me his prisoner; but suffer hardship together with the glad-message according to the power of God, —
Nítorí náà, má ṣe tijú láti jẹ́rìí nípa Olúwa wa, tàbí èmi òǹdè rẹ̀; ṣùgbọ́n kí ìwọ ṣe alábápín nínú ìpọ́njú ìyìnrere nípa agbára Ọlọ́run,
9 Who hath saved us, and called us with a holy calling, not according to our works, but according to the peculiar purpose and favour—which was given to us in Christ Jesus before age-during times, (aiōnios g166)
ẹni ti ó gbà wá là, ti ó si pè wá sínú ìwà mímọ́—kì í ṣe nípa iṣẹ́ tí a ṣe ṣùgbọ́n nípasẹ̀ ète àti oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀. Oore-ọ̀fẹ́ yìí ni a fi fún wa nínú Kristi Jesu láti ìpìlẹ̀ ayérayé, (aiōnios g166)
10 But hath now been made manifest through means of the forthshining of our Saviour Christ Jesus, —Who, indeed, hath abolished death, and hath thrown light upon life and incorruptibility, through means of the glad-message:
ṣùgbọ́n tí a fihàn nísinsin yìí nípa ìfarahàn Jesu Kristi Olùgbàlà wa, ẹni ti ó pa ikú run, tí ó sì mú ìyè àti àìkú wá sí ìmọ́lẹ̀ nípasẹ̀ ìyìnrere.
11 Whereunto, I, have been appointed herald and apostle and teacher;
Fún ti ìyìnrere tí a yàn mi láti jẹ oníwàásù àti aposteli àti olùkọ́.
12 For which cause, these things also, am I suffering; nevertheless I am not being put to shame, for I know him whom I have believed, and am persuaded that he is, able, to guard, that which I have entrusted, [to him] unto, that, day.
Nítorí ìdí èyí ní èmi ṣe ń jìyà wọ̀nyí pẹ̀lú. Ṣùgbọ́n ojú kò tì mí, nítorí èmi mọ ẹni tí èmi gbàgbọ́, ó sì dá mi lójú pé, òun lè pa ohun ti mo fi lé e lọ́wọ́ mọ́ títí di ọjọ́ náà.
13 An outline, have thou, of healthful discourses which from me thou hast heard—with the faith and love which are in Christ Jesus:
Ohun tí ó gbọ́ láti ọ̀dọ̀ mi, pa a mọ́ gẹ́gẹ́ bí àpẹẹrẹ ẹ̀kọ́ rere nínú ìgbàgbọ́ àti ìfẹ́ Kristi Jesu.
14 The noble thing entrusted [to thee], do thou guard, through means of the Holy Spirit which dwelleth within us.
Pa ohun rere ti a ti fi lé ọ lọ́wọ́ mọ́ nípa Ẹ̀mí Mímọ́ ti ń gbé inú wa.
15 Thou knowest this—that all they who are in Asia have turned away from me, —of whom are Phygelus and Hermogenes.
Èyí ni ìwọ mọ̀ pé, gbogbo àwọn ti ó wà ni agbègbè Asia ti fi mí sílẹ̀, nínú àwọn ẹni tí Figeliu àti Hamogene gbé wà.
16 The Lord grant mercy unto the house, of Onesiphorus, in that, ofttimes, hath he refreshed me, and, as regardeth my chain, hath not been put to shame,
Kí Olúwa fi àánú fún ilé Onesiforu; nítorí ti ó máa ń tù mi lára nígbà púpọ̀, ẹ̀wọ̀n mi kò sì tì í lójú.
17 But, happening to be in Rome, he diligently sought out and found me, —
Ṣùgbọ́n nígbà tí ó wà ni Romu, ó fi ẹ̀sọ̀ wá mi, ó sì rí mi.
18 The Lord grant him to find mercy from [the] Lord in, that, day; —and, how many times, in Ephesus, he hath ministered, better art, thou, getting to know.
Kí Olúwa fi fún un kí ó lè rí àánú lọ́dọ̀ Olúwa ni ọjọ́ náà! Ìwọ tìkára rẹ sá à mọ̀ ọ̀nà gbogbo tí ó gbà ràn mí lọ́wọ́ ni Efesu.

< 2 Timothy 1 >