< 2 Samuel 4 >
1 Now, when Ish-bosheth son of Saul heard that Abner had died in Hebron, his hands became feeble, —and, all Israel, were dismayed.
Nígbà tí ọmọ Saulu sì gbọ́ pé, Abneri kú ní Hebroni, ọwọ́ rẹ̀ sì rọ, gbogbo Israẹli sì rẹ̀wẹ̀sì.
2 And two men, captains of bands, pertained to Ish-bosheth son of Saul—the name of the one, was Baanah, and, the name of the other, Rechab—sons of Rimmon the Beerothite, of the sons of Benjamin, —for, even Beeroth, used to be reckoned unto Benjamin;
Ọmọ Saulu sì ní ọkùnrin méjì tí í ṣe olórí ẹgbẹ́ ogun: a ń pe orúkọ ọ̀kan ní Baanah, àti orúkọ èkejì ní Rekabu, àwọn ọmọ Rimoni ará Beeroti ti àwọn ọmọ Benjamini (nítorí pé a sì ka Beeroti pẹ̀lú Benjamini).
3 and the Beerothites fled to Gittaim, —and have been sojourners there, until this day.
Àwọn ará Beeroti sì ti sálọ sí Gittaimu, wọ́n sì ṣe àtìpó níbẹ̀ títí ó fi di ọjọ́ òní yìí.
4 And, Jonathan, son of Saul, had a son, lame of his feet, —five years old, was he, when tidings came in of Saul and Jonathan from Jezreel, so his nurse took him up, and fled, and it came to pass, when she started up to flee, that he fell and was lamed, and, his name, was, Mephibosheth.
(Jonatani ọmọ Saulu sì ti bí ọmọkùnrin kan tí ẹsẹ̀ rẹ̀ rọ, òun sì jẹ́ ọdún márùn-ún, nígbà tí ìròyìn dé ní ti Saulu àti Jonatani láti Jesreeli wá, olùtọ́ rẹ̀ sì gbé e, o sì sálọ, ó sì ṣe, bí ó sì ti ń yára láti sálọ, òun sì ṣubú, ó sì ya arọ. Orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Mefiboṣeti.)
5 So then the sons of Rimmon the Beerothite, Rechab and Baanah, took their journey and came in, about the heat of the day, unto the house of Ish-bosheth, —when, he, was lying on his noonday couch;
Àwọn ọmọ Rimoni, ará Beeroti, Rekabu àti Baanah sì lọ wọ́n sì wá síh ilé Iṣboṣeti ní ọ̀sán gangan, òun sì sinmi lórí ibùsùn kan ní ọjọ́-kanrí.
6 and, thither, entered they as fro as the middle of the house, to fetch wheat, and they smote him in the belly, —and, Rechab and Baanah his brother, escaped.
Sì wò ó, bí olùṣọ́ ẹnu-ọ̀nà ilé náà ti ń gbọn àwọn pàǹtí, ó tòògbé ó sì sùn lọ, wọ́n sì wá sí àárín ilé náà, wọ́n sì ṣe bí ẹni pé wọ́n ń fẹ́ mú alikama; wọ́n sì gún un lábẹ́ inú. Rekabu àti Baanah arákùnrin rẹ̀ sì sálọ.
7 Thus they entered the house when, he, was lying on his bed, in his sleeping-chamber, and smote him, and slew him, and beheaded him, —and took his head, and journeyed by way of the waste plain all the night;
Nígbà tí wọ́n wọ ilé náà lọ, òun sì dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀ nínú iyàrá rẹ̀, wọ́n sì pa á, wọ́n sì bẹ́ ẹ lórí, wọ́n gbé orí sálọ, wọ́n sì fi gbogbo òru rìn ni pẹ̀tẹ́lẹ̀ náà.
8 and brought in the head of Ish-bosheth unto David, at Hebron, and said unto the king, Lo! the head of Ish-bosheth son of Saul, thine enemy, who sought thy life: so hath Yahweh given to my lord the king, avengement this day, on Saul and on his seed.
Wọ́n sì gbé orí Iṣboṣeti tọ Dafidi wá ní Hebroni, wọ́n sì wí fún ọba pé, “Wò ó, orí Iṣboṣeti ọmọ Saulu ọ̀tá rẹ, tí ó ti ń wá ẹ̀mí rẹ kiri, Olúwa ti gbẹ̀san fún ọba olúwa mi lónìí lára Saulu àti lára irú-ọmọ rẹ̀.”
9 Then David responded to Rechab and Baanah his brother, sons of Rimmon the Beerothite, and said unto them, —By the life of Yahweh, who hath redeemed my soul out of all distress,
Dafidi sì dá Rekabu àti Baanah arákùnrin rẹ̀, àwọn ọmọ Rimoni ará Beeroti lóhùn, ó sì wí fún wọn pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ, ẹni tí ó gba ẹ̀mí mi lọ́wọ́ gbogbo ìpọ́njú.
10 when he that brought tidings to me, saying, Lo! Saul is dead, though, he, was as one that bringeth good tidings, in his own eyes, yet I seized him, and slew him in Ziklag, —which was how I gave him reward for his tidings:
Nígbà tí ẹnìkan rò fún mi pé, ‘Wò ó, Saulu ti kú,’ lójú ara rẹ̀ òun sì jásí ẹni tí ó mú ìyìnrere wá, èmi sì mú un, mo sì pa á ní Siklagi, ẹni tí ó ṣe bí òun ó rí nǹkan gbà nítorí ìròyìn rere rẹ̀.
11 how much more, when, lawless men, have slain a righteous person, in his own house, upon his bed? …Now, therefore, must I not require his blood at your hands, and so consume you, out of the earth?
Mélòó mélòó ni, nígbà tí àwọn ìkà ènìyàn pa olódodo ènìyàn kan ni ilé rẹ̀ lórí ibùsùn rẹ̀—ǹjẹ́ èmi ha sì lè ṣe aláìbéèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ yín bí? Kí èmi sì mú yín kúrò láààyè.”
12 David therefore commanded the young men, and they slew them, and cut off their hands, and their feet, and hanged them up over the pool, in Hebron, —but, the head of Ish-bosheth, took they, and buried in the grave of Abner, in Hebron.
Dafidi sì fi àṣẹ fún àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ̀, wọ́n sì pa wọ́n, wọ́n sì gé ọwọ́ àti ẹsẹ̀ wọn, a sì fi wọ́n há lórí igi ní Hebroni. Ṣùgbọ́n wọ́n mú orí Iṣboṣeti, wọ́n sì sin ín ní ibojì Abneri ní Hebroni.