< 2 Samuel 2 >

1 And it came to pass, after this, that David enquired of Yahweh, saying—Shall I go up into one of the cities of Judah? And Yahweh said unto him, Go up. And David said—Whither shall I go up? And he said—Unto Hebron.
Lẹ́yìn àkókò yìí, Dafidi wádìí lọ́wọ́ Olúwa. Ó sì béèrè pé, “Ṣé èmi lè gòkè lọ sí ọ̀kan lára àwọn ìlú Juda?” Olúwa sì wí pé, “Gòkè lọ.” Dafidi sì béèrè pé, “Ní ibo ni kí èmi kí ó lọ?” Olúwa sì dá a lóhùn pé, “Sí Hebroni.”
2 So David went up thither, and his two wives also, —Ahinoam, the Jezreelitess, and Abigail, wife of Nabal the Carmelite.
Nígbà náà ni Dafidi gòkè lọ síbẹ̀ pẹ̀lú ìyàwó rẹ̀ méjì Ahinoamu ará Jesreeli, àti Abigaili obìnrin opó Nabali ti Karmeli.
3 His men also who were with him, did David bring up, every man with his household, —and they dwelt in the cities of Hebron.
Dafidi sì mú àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀, olúkúlùkù pẹ̀lú ìdílé rẹ̀, wọ́n sì ń gbé ní Hebroni àti ìlú rẹ̀ mìíràn.
4 Then came the men of Judah, and anointed David there, to be king over the house of Judah. And they told David, saying, Men of Jabesh-gilead, were they who buried Saul.
Nígbà náà àwọn ọkùnrin ará Juda wá sí Hebroni, níbẹ̀ ni wọ́n ti fi àmì òróró yan Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba lórí ilé Juda. Nígbà tí wọ́n sọ fún Dafidi pé, àwọn ọkùnrin ti Jabesi Gileadi ni ó sin òkú Saulu,
5 So David sent messengers unto the men of Jabesh-gilead, —and said unto them—Blessed, be ye of Yahweh, that ye did this lovingkindness unto your lord, unto Saul, and buried him.
Dafidi rán oníṣẹ́ sí àwọn ọkùnrin Jabesi Gileadi láti sọ fún wọn pé, “Olúwa bùkún un yín fún fífi inú rere yín hàn sí Saulu ọ̀gá yín nípa sí sin ín.
6 Now, therefore, Yahweh requite you with lovingkindness and truth, —moreover also, I, will requite you, for this noble deed, in that ye did this thing.
Kí Olúwa kí ó fi inú rere àti òtítọ́ fún un yín, èmi náà yóò sì san oore yìí fún un yín, nítorí tí ẹ̀yin ti ṣe èyí.
7 Now, therefore, let your hands be made firm, and become ye sons of valour, for your lord Saul is dead, —and, me, moreover have the house of Judah anointed, to be king over them.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ mú ara yín le, kí ẹ sì ní ìgboyà, nítorí Saulu ọba yín ti kú, ilé Juda sì ti fi àmì òróró yàn mí ní ọba lórí wọn.”
8 But, Abner son of Ner, prince of the host that pertained unto Saul, took Ish-bosheth, son of Saul, and brought him over to Mahanaim;
Lákòókò yìí, Abneri ọmọ Neri olórí ogun Saulu ti mú Iṣboṣeti ọmọ Saulu, ó sì mú un kọjá sí Mahanaimu.
9 and made him king for Gilead, and for the Ashurites, and for Jezreel, —and over Ephraim, and over Benjamin, and over, all Israel.
Ó sì fi jẹ ọba lórí Gileadi Aṣuri àti Jesreeli àti lórí Efraimu àti lórí Benjamini àti lórí gbogbo Israẹli.
10 Forty years old, was Ish-bosheth son of Saul, when he began to reign over Israel, and, two years, reigned he, —but, the house of Judah, followed David.
Iṣboṣeti ọmọ Saulu sì jẹ́ ọmọ ogójì ọdún nígbà tí ó jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì jẹ ọba fún ọdún méjì. Ilé Juda sì ń tọ Dafidi lẹ́yìn.
11 And it came to pass, that, the number of the days that David was king in Hebron, over the house of Judah, was seven years and six months.
Gbogbo àkókò tí Dafidi fi jẹ ọba ní Hebroni lórí ilé Juda sì jẹ́ ọdún méje àti oṣù mẹ́fà.
12 And Abner son of Ner, and the servants of Ish-bosheth, son of Saul, came out from Mahanaim to Gibeon.
Abneri ọmọ Neri pẹ̀lú àwọn ọkùnrin ti Iṣboṣeti ọmọkùnrin Saulu kúrò ní Mahanaimu, wọ́n sì lọ sí Gibeoni.
13 And, Joab son of Zeruiah, and the servants of David, went out from Hebron and met, by the pool of Gibeon, together, —and they sat down, these, by the pool, on the one side, and, those, by the pool, on the other side.
Joabu ọmọ Seruiah pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Dafidi jáde lọ láti lọ bá wọn ní adágún Gibeoni. Ẹgbẹ́ kan sì jókòó ní apá kan adágún, àti ẹgbẹ́ kejì ní apá kejì adágún.
14 Then said Abner unto Joab, Let the young men arise, I pray thee, and make sport before us. And Joab said—Let them arise.
Nígbà náà, Abneri sọ fún Joabu pé, “Jẹ́ kí díẹ̀ nínú àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yìí ó dìde láti bá ara wọn jà níwájú wa.” Joabu sì dáhùn pé, “Ó dára, jẹ́ kí wọ́n ṣe é.”
15 Then there arose, and went over by number, —twelve of Benjamin, pertaining to Ish-bosheth, son of Saul, and twelve, of the servants of David.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dìde sókè, a sì kà wọ́n sí ọkùnrin méjìlá fún Benjamini àti Iṣboṣeti ọmọ Saulu àti méjìlá fún Dafidi.
16 And they caught every one his fellow by the head, with his sword in his fellow’s side, so they fell, together, —and that place was called Helkath-hazzadim ["Field of Plotters"], which is in Gideon.
Nígbà náà olúkúlùkù ọkùnrin gbá ẹnìkejì rẹ̀ mú ní orí, ó sì fi idà gún ẹnìkejì rẹ̀ lẹ́gbẹ̀ẹ́, wọ́n sì ṣubú lulẹ̀ papọ̀. Bẹ́ẹ̀ ni ibẹ̀ ni Gibeoni ti à ń pè ni Helikatihu Hasurimu.
17 So the battle became exceeding obstinate, on that day, —and Abner and the men of Israel were defeated before the servants of David.
Ogun náà ní ọjọ́ náà gbóná. Àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì ṣẹ́gun Abneri pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Israẹli.
18 Now there were there, three sons of Zeruiah, Joab, and Abishai, and Asahel, —and, Asahel, was light of foot as a wild gazelle.
Àwọn ọmọkùnrin Seruiah mẹ́tẹ̀ẹ̀ta ni ó wà níbẹ̀: Joabu, Abiṣai àti Asaheli. Nísinsin yìí ẹsẹ̀ Asaheli sì fẹ́rẹ̀ bí ẹsẹ̀ èsúró tí ó wà ní pápá.
19 And Asahel pursued Abner, —and turned not, in going, to the right hand or to the left, from pursuing Abner.
Asaheli sì ń lépa Abneri, bí òun tí ń lọ kò sì yípadà sí ọ̀tún tàbí sí òsì láti máa tọ́ Abneri lẹ́yìn.
20 Then Abner looked behind him, and said—Art thou Asahel? And he said—I am.
Abneri bojú wo ẹ̀yìn rẹ̀, Ó sì béèrè pé, “Ṣé ìwọ Asaheli ni?” Ó dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni.”
21 Then Abner said to him—Turn thee aside, to thy right hand, or to thy left, and lay thee hold on one of the young men, and take thee his armour. But Asahel would not turn aside from pursuing him.
Nígbà náà, Abneri sọ fún un pé, “Yípadà sí ọ̀tún tàbí òsì; mú ọ̀kan lára àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin kí o sì bọ́ ìhámọ́ra rẹ.” Ṣùgbọ́n Asaheli kọ̀ láti dẹ́kun lílépa rẹ̀.
22 And Abner said, yet again, unto Asahel, Turn thee aside from pursuing me, —wherefore should I smite thee to the earth? how then should I lift up my face unto Joab, thy brother?
Abneri tún kìlọ̀ fún Asaheli, “Dẹ́kun lílépa mi! Èéṣe tí èmi yóò fi lù ọ́ bolẹ̀? Báwo ni èmi yóò ti wo arákùnrin rẹ Joabu lójú?”
23 Howbeit he refused to turn aside, wherefore Abner smote him with the hinder end of the spear, in the belly, that the spear came out behind him, and he fell there, and died on the spot, —and so it was, that, as many as came up to the place where Asahel fell and died, stood still.
Ṣùgbọ́n ó sí kọ̀ láti padà, Abneri sì fi òdì ọ̀kọ̀ gún un lábẹ́ inú, ọ̀kọ̀ náà sì jáde ní ẹ̀yìn rẹ̀: òun sì ṣubú lulẹ̀ níbẹ̀, ó sì kú ní ibi kan náà; ó sí ṣe gbogbo ènìyàn tí ó dé ibi tí Asaheli gbé ṣubú si, tí ó sì kú, sì dúró jẹ́.
24 Then Joab and Abishai pursued Abner, —but, the sun, had gone in by the time, they, had come as far as the hill of Ammah, that overlooketh Giah, by way of the wilderness of Gibeon.
Joabu àti Abiṣai sì lépa Abneri: oòrùn sì wọ̀, wọ́n sì dé òkè ti Amima tí o wà níwájú Giah lọ́nà ijù Gibeoni.
25 And, when the sons of Benjamin had gathered themselves together after Abner, and become one band, —and had taken their stand on the top of a certain hill,
Àwọn ọmọ Benjamini sì kó ara wọn jọ wọ́n tẹ̀lé Abneri, wọ́n sì wá di ẹgbẹ́ kan, wọ́n sì dúró lórí òkè kan.
26 then Abner cried aloud unto Joab, and said—To the uttermost, must the sword devour? Dost thou not well know that, bitter, shall it be, in the latter end? How long, then, wilt thou not bid the people turn back from pursuing their own brethren?
Abneri sì pe Joabu, ó sì bi í léèrè pé, “Idà yóò máa parun títí láéláé bí? Ǹjẹ́ ìwọ kò ì tí ì mọ̀ pé yóò korò níkẹyìn? Ǹjẹ́ yóò ha ti pẹ́ tó kí ìwọ tó sọ fún àwọn ènìyàn náà, kí wọ́n dẹ́kun láti máa lépa arákùnrin wọn.”
27 Then said Joab—As God liveth, surely, if thou hadst not spoken, then in the morning, the people would of themselves have gone up, every man from pursuing his brother.
Joabu sì wí pé, “Bí Ọlọ́run ti ń bẹ, bí kò ṣe bí ìwọ ti wí, nítòótọ́ ní òwúrọ̀ ni àwọn ènìyàn náà ìbá padà lẹ́yìn arákùnrin wọn.”
28 So Joab blew with the horn, and all the people stood still, and they neither pursued Israel further, —nor fought any more.
Joabu sì fọ́n ìpè, gbogbo ènìyàn sì dúró jẹ́ẹ́, wọn kò sì lépa Israẹli mọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì tún jà mọ́.
29 And, Abner and his men, journeyed through the waste plain all that night, —and crossed the Jordan, and went through all the Bithron, and entered Mahanaim.
Abneri àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì fi gbogbo òru náà rìn ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, wọ́n sì kọjá Jordani, wọ́n sì rìn ní gbogbo Bitironi, wọ́n sì wá sí Mahanaimu.
30 And, Joab, returned from pursuing Abner, and, when he had gathered together all the people, there were missing of the servants of David—nineteen men, and Asahel;
Joabu sì dẹ́kun àti máa tọ Abneri lẹ́yìn: ó sì kó gbogbo àwọn ènìyàn náà jọ, ènìyàn mọ́kàndínlógún ni ó kú pẹ̀lú Asaheli nínú àwọn ìránṣẹ́ Dafidi.
31 but, the servants of David, had smitten of Benjamin, of the men of Abner, —[so that] three hundred and sixty men, had died.
Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì pa nínú àwọn ènìyàn Benjamini: nínú àwọn ọmọkùnrin Abneri; òjìdínnírinwó ènìyàn.
32 And they carried Asahel, and buried him in the grave of his father, which was in Bethlehem, —and Joab and his men journeyed all the night, and had daylight in Hebron.
Wọ́n si gbé Asaheli wọ́n sì sin ín sínú ibojì baba rẹ̀ tí ó wà ní Bẹtilẹhẹmu. Joabu àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ fi gbogbo òru náà rìn, ilẹ̀ sì mọ́ wọn sí Hebroni.

< 2 Samuel 2 >