< 2 Samuel 17 >
1 Then said Ahithophel unto Absolom: I pray thee, let me choose for myself, twelve thousand men, and arise, and pursue David to-night;
Ahitofeli sì wí fún Absalomu pé, “Èmi ó yan ẹgbàá mẹ́fà ọkùnrin èmi ó sì dìde, èmi ó sì lépa Dafidi lóru yìí.
2 and let me come upon him, when, he, is weary, and weak-handed, so shall I strike him with terror, and all the people who are with him shall flee, —then will I smite the king alone:
Èmi ó sì yọ sí i nígbà tí àárẹ̀ bá mú un tí ọwọ́ rẹ̀ sì ṣe aláìle, èmi ó sì dá a ní ìjì, gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ yóò sì sá, èmi ó sì kọlu ọba nìkan ṣoṣo.
3 that I may bring back all the people unto thee, —when all return—[save] the man whom thou art seeking, all the people, will be at peace.
Èmi ó sì mú gbogbo àwọn ènìyàn padà sọ́dọ̀ rẹ bi ìgbà tí ìyàwó bá padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ rẹ̀. Ọkàn ẹnìkan ṣoṣo tí ìwọ ń wá yìí ni ó túmọ̀ sí ìpadàbọ̀ gbogbo wọn; gbogbo àwọn ènìyàn yóò sì wà ní àlàáfíà.”
4 And the saying was right in the eyes of Absolom, —and in the eyes of all the elders of Israel.
Ọ̀rọ̀ náà sì tọ́ lójú Absalomu, àti lójú gbogbo àwọn àgbàgbà Israẹli.
5 Then said Absolom, I pray you, call ye Hushai the Archite also, —and let us hear what is in, his, mouth, also.
Absalomu sì wí pé, “Ǹjẹ́ pe Huṣai ará Arki, àwa ó sì gbọ́ èyí tí ó wà lẹ́nu rẹ̀ pẹ̀lú.”
6 And, when Hushai came in unto Absolom, Absolom spake unto him, saying—After this manner, hath Ahithophel spoken, shall we do what he saith? if not, thou, speak.
Huṣai sì dé ọ̀dọ̀ Absalomu, Absalomu sì wí fún un pé, “Báyìí ni Ahitofeli wí, kí àwa ṣe bí ọ̀rọ̀ rẹ bí? Bí ko bá sì tọ́ bẹ́ẹ̀, ìwọ wí.”
7 Then said Hushai unto Absolom, —Not good, is the counsel that Ahithophel hath given—at this time.
Huṣai sì wí fún Absalomu pé, “Ìmọ̀ tí Ahitofeli gbà yìí, kò dára nísinsin yìí.”
8 And Hushai said—Thou, knowest thy father and his men—that, men of might, they are, and, embittered in soul, they are, like a bear bereaved of her young, in the field, —thy father also, is a man of war, and will not lodge with the people.
Huṣai sì wí pé, “Ìwọ mọ baba rẹ àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé alágbára ni wọ́n, wọ́n sì wà ní kíkorò ọkàn bí àmọ̀tẹ́kùn tí a gbà ní ọmọ ni pápá, baba rẹ sì jẹ́ jagunjagun ọkùnrin kì yóò bá àwọn ènìyàn náà gbé pọ̀ lóru.
9 Lo! by this time, hath, he, hidden himself in some pit, or other place, —and it shall be, as soon as he falleth upon them at the first, that he that hearkeneth for tidings will hear [of it], and will say—There is a defeat among the people that are following Absolom:
Kíyèsi i, ó ti fi ara rẹ̀ pamọ́ nísinsin yìí ni ihò kan, tàbí ní ibòmíràn: yóò sì ṣe, nígbà tí díẹ̀ nínú wọn bá kọ́ ṣubú, ẹnikẹ́ni tí ó bá gbọ́ yóò sì wí pé, ‘Ìparun sì ń bẹ́ nínú àwọn ènìyàn tí ń tọ Absalomu lẹ́yìn.’
10 then will, even the son of valour himself, whose heart is as the heart of a lion, utterly melt, —for all Israel do know that, a man of might, is thy father, and that, sons of valour, are they who are with him.
Ẹni tí ó sì ṣe alágbára, tí ọkàn rẹ̀ sì dàbí ọkàn kìnnìún, yóò sì rẹ̀ ẹ́: nítorí gbogbo Israẹli ti mọ̀ pé alágbára ni baba rẹ, àti pé, àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ jẹ́ alágbára.
11 Therefore I counsel—that there be a general gathering together unto thee of all Israel, from Dan even unto Beer-sheba, as the sand that is by the sea for multitude, —and that, thine own presence, be going on in their midst.
“Nítorí náà èmi dámọ̀ràn pé, kí gbogbo Israẹli wọ́jọ pọ̀ sọ́dọ̀ rẹ, láti Dani títí dé Beerṣeba, gẹ́gẹ́ bí iyanrìn létí òkun fún ọ̀pọ̀lọpọ̀; àti pé, kí ìwọ tìkára rẹ̀ ó lọ sí ogun náà.
12 So shall we come upon him in some place where he hath been found, yea, we, shall be upon him, as when the dew falleth upon the ground, —and there shall not be left of him, or of the men that are with him, so much as one.
Àwa ó sì yọ sí i níbikíbi tí àwa o gbé rí i, àwa ó sì yí i ká bí ìrì ti ń ṣẹ̀ sí ilẹ̀ àní, ọkàn kan kì yóò kù pẹ̀lú rẹ̀ nínú gbogbo àwọn ọmọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀.
13 But, if, into a city, he withdraw, then will all Israel bring up unto that city, ropes, —and we will drag it down unto the ravine, until there be not found in that place, so much as a small stone.
Bí o bá sì bọ́ sí ìlú kan, gbogbo Israẹli yóò mú okùn wá sí ìlú náà, àwa ó sì fà á lọ sí odò, títí a kì yóò fi rí òkúta kéékèèké kan níbẹ̀.”
14 Then said Absolom and all the men of Israel, Better, is the counsel of Hushai the Archite, than the counsel of Ahithophel. Yahweh, indeed, had given charge to frustrate the wise counsel of Ahithophel, to the intent that Yahweh might bring upon Absolom, ruin.
Absalomu àti gbogbo ọkùnrin Israẹli sì wí pé, “Ìmọ̀ Huṣai ará Arki sàn ju ìmọ̀ Ahitofeli lọ! Nítorí Olúwa fẹ́ láti yí ìmọ̀ rere ti Ahitofeli po.” Nítorí kí Olúwa lè mú ibi wá sórí Absalomu.
15 So Hushai said unto Zadok and unto Abiathar the priests, Thus and thus, did Ahithophel counsel Absolom and the elders of Israel, —and, thus and thus, have, I, counselled.
Huṣai sì wí fún Sadoku àti fún Abiatari àwọn àlùfáà pé, “Báyìí ni Ahitofeli ti bá Absalomu àti àwọn àgbàgbà Israẹli dámọ̀ràn, báyìí lèmi sì bá a dámọ̀ràn.
16 Now, therefore, send quickly, and tell David, saying, —Do not lodge to-night in the waste plains of the wilderness, thou must, even pass over, lest the king be swallowed up, and all the people who are with him.
Nítorí náà yára ránṣẹ́ nísinsin yìí kí o sì sọ fún Dafidi pé, ‘Má ṣe dúró ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ijù náà lálẹ́ yìí, ṣùgbọ́n yára rékọjá kí a má bá a gbé ọba mì, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ.’”
17 Now, Jonathan and Ahimaaz, were staying by En-rogel, and a maidservant was to go and tell them, and, they, were to go and tell King David, —for they might not be seen to enter the city.
Jonatani àti Ahimasi sì dúró ní En-Rogeli ọ̀dọ́mọdébìnrin kan sì lọ, ó sì sọ fún wọn, wọ́n sì lọ wọ́n sọ fún Dafidi ọba nítorí pé kí a má bá à rí wọn pé wọ́n wọ ìlú.
18 And, though a young man did see them, and told Absolom, yet they both departed quickly, and entered the house of a man in Bahurim, and, he, had a well in his court, into which they went down;
Ṣùgbọ́n ọ̀dọ́mọdékùnrin kan rí wọn, ó sì wí fún Absalomu, ṣùgbọ́n àwọn méjèèjì sì yára lọ kúrò, wọ́n sì wá sí ilé ọkùnrin kan ní Bahurimu, ẹni tí ó ní kànga kan ní ọgbà rẹ̀, wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ sí ibẹ̀.
19 and the woman took and spread the cover over the face of the well, and spread thereon her pounded corn, —so nothing was known.
Obìnrin rẹ̀ sì mú nǹkan ó fi bo kànga náà, ó sì sá àgbàdo sórí rẹ̀, a kò sì mọ̀.
20 Then came the servants of Absolom unto the woman in the house, and said—Where are Ahimaaz and Jonathan? And the woman said to them—They have passed over the stream of water. And, when they had searched and not found, they returned to Jerusalem.
Àwọn ìránṣẹ́ Absalomu sì tọ obìnrin náà wá sí ilé náà, wọ́n sì béèrè pé, “Níbo ni Ahimasi àti Jonatani gbé wà?” Obìnrin náà sì wí fún wọn pé, “Wọ́n ti gòkè rékọjá ìṣàn odò náà.” Wọ́n sì wá wọn kiri, wọn kò sì rí wọn, wọ́n sì yípadà sí Jerusalẹmu.
21 And it came to pass, after those had gone, that these came up out of the well, and went, and told King David, —and said unto David, —Arise ye and pass quickly over the water, for, thus and thus, hath Ahithophel counselled against you.
Ó sì ṣe lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti lọ tán, àwọn ọkùnrin náà sì jáde kúrò nínú kànga, wọ́n sì lọ wọ́n sì rò fún Dafidi ọba. Wọ́n sọ fún Dafidi pé, “Dìde kí o sì gòkè odò kánkán, nítorí pé báyìí ni Ahitofeli gbìmọ̀ sí ọ.”
22 So David arose, and all the people who were with him, and passed over the Jordan, by the morning light, so much as one, was not lacking, who had not passed over the Jordan.
Dafidi sì dìde, àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì gòkè odò Jordani: kí ilẹ̀ tó mọ́, ènìyàn kò kù tí kò gòkè odò Jordani.
23 Now, when, Ahithophel, saw that his counsel was not followed, he saddled his ass, and arose and went unto his own house, unto his own city, and gave charge unto his household, and hanged himself, and died, and was buried in the grave of his father.
Nígbà tí Ahitofeli sì rí i pé wọn kò fi ìmọ̀ tirẹ̀ ṣe, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ni gàárì, ó sì dìde, ó lọ ilé rẹ̀, ó sì palẹ̀ ilé rẹ̀ mọ̀, ó sì so, ó sì kú, a sì sin ín sí ibojì baba rẹ̀. Absalomu gbógun ti Dafidi.
24 When, David, had come to Mahanaim, Absolom, had passed over the Jordan, he and all the men of Israel with him.
Dafidi sì wá sí Mahanaimu, Absalomu sì gòkè odò Jordani, òun àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli pẹ̀lú rẹ̀.
25 Now Absolom had appointed, Amasa, instead of Joab, over the army, —Amasa, being the son of a man whose name was Ithra the Ishmaelite, who went in unto Abigail, daughter of Nahash, sister of Zeruiah, mother of Joab.
Absalomu sì fi Amasa ṣe olórí ogun ní ipò Joabu: Amasa ẹni tí í ṣe ọmọ ẹnìkan, orúkọ ẹni tí a ń pè ní Itira, ará Israẹli, tí ó wọlé tọ Abigaili ọmọbìnrin Nahaṣi, arábìnrin Seruiah, ìyá Joabu.
26 And Israel and Absolom encamped in the land of Gilead.
Israẹli àti Absalomu sì dó ní ilẹ̀ Gileadi.
27 And it came to pass, when David entered Mahanaim, that Shobi son of Nahash of Rabbah of the sons of Ammon and Machir son of Ammiel of Lo-debar, and Barzillai the Gileadite, of Rogelim,
Nígbà tí Dafidi sì wá sí Mahanaimu, Ṣobi ọmọ Nahaṣi ti Rabba tí àwọn ọmọ Ammoni, àti Makiri ọmọ Ammieli ti Lo-Debari, àti Barsillai ará Gileadi ti Rogelimu.
28 brought, sleeping rugs, and basins, and earthen vessels, and wheat and barley, and meal and roasted corn, —and beans and lentils, and parched pulse;
Mú àwọn àkéte, àti àwọn àwo, àti ìkòkò amọ̀, àti alikama, àti ọkà barle, àti ìyẹ̀fun, àti àgbàdo díndín, àti ẹ̀wà, àti erèé, àti lẹntili.
29 and honey and cream, and sheep, and cheese of kine, for David, and for the people that were with him, to eat, —for they said, The people, are hungry and weary and thirsty, in the wilderness.
Àti oyin, àti òrí-àmọ́, àti àgùntàn, àti wàràǹkàṣì màlúù, wá fún Dafidi àti fún àwọn ènìyàn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀, láti jẹ: nítorí tí wọ́n wí pé, “Ebi ń pa àwọn ènìyàn, ó sì rẹ̀ wọ́n, òǹgbẹ sì ń gbẹ wọ́n ní aginjù.”