< 2 Kings 16 >
1 In the seventeenth year of Pekah son of Remaliah, began Ahaz son of Jotham king of Judah to reign.
Ní ọdún kẹtàdínlógún Peka ọmọ Remaliah, Ahasi ọmọ Jotamu ọba Juda bẹ̀rẹ̀ sí i jẹ ọba.
2 Twenty years old, was Ahaz when he began to reign, and, sixteen years, reigned he in Jerusalem. And he did not that which was right in the eyes of Yahweh his God, like David his father;
Ẹni ogún ọdún ni Ahasi nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ sí jẹ ọba, ó sì jẹ ọba ọdún mẹ́rìndínlógún ní Jerusalẹmu, kò sì ṣe èyí tí ó tọ́ lójú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Dafidi baba rẹ̀.
3 but walked in the way of the kings of Israel, —moreover also, me made, his son, pass through the fire, according to the abominable practices of the nations, whom Yahweh dispossessed from before the sons of Israel;
Ṣùgbọ́n ó rìn ní ọ̀nà àwọn ọba Israẹli, nítòótọ́, ó sì sun ọmọ rẹ̀ nínú iná, gẹ́gẹ́ bí ohun ìríra àwọn orílẹ̀-èdè, tí Olúwa lé jáde níwájú àwọn ọmọ Israẹli.
4 and he offered sacrifice and burned incense in the high places, and on the hills, —and under every green tree.
Ó sì rú ẹbọ, ó sì sun tùràrí ní àwọn ibi gíga, àti lórí àwọn òkè kéékèèké àti lábẹ́ gbogbo igi tútù.
5 then, came up Rezin king of Syria, and Pekah son of Remaliah king of Israel, unto Jerusalem, to make war, —and they laid siege against Ahaz, but could not overcome [him].
Nígbà náà ni Resini ọba Siria àti Peka ọmọ Remaliah ọba Israẹli gòkè wá sí Jerusalẹmu láti jagun: wọ́n dó ti Ahasi, ṣùgbọ́n wọn kò lè borí rẹ̀.
6 At that time, Rezin king of Syria recovered Elath, to Syria, and wholly cleared out the Jews from Eloth, —and, the Syrians, entered Elath, and have dwelt there, unto this day.
Ní àkókò náà, Resini ọba Siria gba Elati padà fún Siria, ó sì lé àwọn ènìyàn Juda kúrò ní Elati: àwọn ará Siria sì wá sí Elati, wọ́n sì ń gbé ibẹ̀ títí di òní yìí.
7 So Ahaz sent messengers unto Tiglath-pileser king of Assyria, saying, Thy servant and thy son, I am, —Come up and save me, out of the hand of the king of Syria, and out of the hand of the king of Israel, who are rising up against me.
Ahasi sì rán oníṣẹ́ sọ́dọ̀ Tiglat-Pileseri ọba Asiria wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni èmi, àti ọmọ rẹ; gòkè wá, kí o sì gbà mi lọ́wọ́ ọba Siria, àti lọ́wọ́ ọba Israẹli tí ó dìde sí mi.”
8 And Ahaz took the silver and the gold that was found in the house of Yahweh, and in the treasuries of the house of the king, —and sent them to the king of Assyria, as a bribe.
Ahasi sì mú fàdákà àti wúrà tí a rí ní ilé Olúwa, àti nínú ìṣúra ilé ọba, ó sì rán an sí ọba Asiria ní ọrẹ.
9 So the king of Assyria hearkened unto him, and the king of Assyria came up unto Damascus, and seized it, and carried away the people thereof captive to Kir, —and put Rezin, to death.
Ọba Asiria sì gbọ́ tirẹ̀: nítorí ọba Asiria gòkè wá sí Damasku, ó sì kó o, ó sì mú un ní ìgbèkùn lọ sí Kiri, ó sì pa Resini.
10 So then King Ahaz went to meet Tiglath-pileser king of Assyria, in Damascus, and saw the altar which was in Damascus, —and King Ahaz, sent unto Urijah the priest, a likeness of the altar, and a model thereof, according to all the workmanship thereof;
Ọba sì lọ sí Damasku láti pàdé Tiglat-Pileseri, ọba Asiria, ó sì rí pẹpẹ kan tí ó wà ní Damasku: Ahasi ọba sì rán àwòrán pẹpẹ náà, àti àpẹẹrẹ rẹ̀ sí Uriah àlùfáà, gẹ́gẹ́ bí gbogbo iṣẹ́ ọ̀nà rẹ̀.
11 and Urijah the priest built an altar, —according to all that King Ahaz sent from Damascus, so, did Urijah the priest make it, by the time King Ahaz came from Damascus.
Uriah àlùfáà sì kọ́ pẹpẹ náà gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí Ahasi ọba fi ránṣẹ́ sí i láti Damasku; bẹ́ẹ̀ ni Uriah àlùfáà ṣe é dé ìpadàbọ̀ Ahasi ọba láti Damasku.
12 And, when the king came from Damascus, then the king saw the altar, —so the king drew near unto the altar, and caused offerings to ascend thereupon.
Nígbà tí ọba sì ti Damasku dé, ọba sì rí pẹpẹ náà: ọba sì súnmọ́ pẹpẹ náà, ó sì rú ẹbọ lórí rẹ̀.
13 And he made perfume with his ascending-sacrifice, and with his meal-offering, and poured out his drink-offering, —and dashed the blood of the peace-offerings which he had, upon the altar.
Ó sì sun ẹbọ sísun rẹ̀ àti ọrẹ-jíjẹ rẹ̀, o si ta ohun mímu rẹ̀ sílẹ̀, ó sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ ọrẹ àlàáfíà rẹ̀ sí ara pẹpẹ náà.
14 And, the altar of bronze which was before Yahweh, he brought away from the forefront of the house, from between the altar, and the house of Yahweh, —and put it at the side of the altar northward.
Ṣùgbọ́n ó mú pẹpẹ idẹ tí ó wà níwájú Olúwa kúrò láti iwájú ilé náà, láti àárín méjì pẹpẹ náà, àti ilé Olúwa, ó sì fi í sí apá àríwá pẹpẹ náà.
15 And King Ahaz commanded Urijah the priest, saying—Upon the great altar, make thou perfume with the ascending-sacrifice of the morning, and with the meal-offering of the evening, and with the ascending-sacrifice of the king and with his meal-offering, and with the ascending-sacrifice of all the people of the land, and their meal-offering and their drink-offering, and, all the blood of the ascending-offering, and all the blood of the [peace] offering, thereupon, shalt thou dash, —but, the altar of bronze, shall be for me to inquire [into].
Ahasi ọba sì pàṣẹ fún Uriah àlùfáà, wí pé, “Lórí pẹpẹ ńlá náà ni kó o máa sun ẹbọ sísun òròwúrọ̀ àti ọrẹ-jíjẹ alaalẹ́, àti ẹbọ sísun ti ọba, àti ọrẹ-jíjẹ rẹ̀, pẹ̀lú ẹbọ sísun tí gbogbo àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, àti ọrẹ-jíjẹ wọn, àti ọrẹ ohun mímu wọn; kí o sì wọ́n gbogbo ẹ̀jẹ̀ ẹbọ sísun náà lórí rẹ̀, àti gbogbo ẹ̀jẹ̀ ẹbọ mìíràn, ṣùgbọ́n ní ti pẹpẹ idẹ náà èmi ó máa gbèrò ohun tí èmi ó fi ṣe.”
16 So Urijah the priest did according to all that King Ahaz commanded.
Báyìí ni Uriah àlùfáà ṣe, gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Ahasi ọba pàṣẹ.
17 And King Ahaz cut off the side walls of the stands, and took away from off them the laver, and, the sea, took he down from off the oxen of bronze, which were under it, —and set it on a pavement of stones.
Ahasi ọba sì gé igi-ìpílẹ̀ àwọn àgbédúró náà, ó ṣí agbada náà kúrò lára wọn; ó sì gbé agbada ńlá náà kalẹ̀ kúrò lára àwọn màlúù idẹ tí ń bẹ lábẹ́ rẹ̀, ó sì gbé e ka ilẹ̀ tí a fi òkúta tẹ́.
18 Also, the covered walk for the Sabbath, which they had built in the house, and the outer entrance for the king, he changed in the house of Yahweh, —because of the king of Assyria.
Ibi ààbò fún ọjọ́ ìsinmi tí a kọ́ nínú ilé náà, àti ọ̀nà ìjáde sí òde ọba, ni ó yípadà kúrò ní ilé Olúwa nítorí ọba Asiria.
19 Now, the rest of the story of Ahaz, what he did, is, it, not written in the book of the Chronicles of the Kings of Judah?
Àti ìyókù ìṣe Ahasi tí ó ṣe, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ọ̀rọ̀ ọjọ́ àwọn ọba Juda?
20 And Ahaz slept with his fathers, and was buried with his fathers, in the city of David, —and, Hezekiah his son, reigned, in his stead.
Ahasi sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀ ní ìlú Dafidi: Hesekiah ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.