< 2 Chronicles 22 >

1 And the inhabitants of Jerusalem made Ahaziah his youngest son king, in his stead, for, all the elder sons, had the band of men slain who came in with the Arabians into the camp, —so Ahaziah son of Jehoram king of Judah reigned.
Àwọn ènìyàn Jerusalẹmu mú Ahasiah, ọmọ Jehoramu tí ó kéré jùlọ, jẹ ọba ní ipò rẹ̀, láti ìgbà tí àwọn onísùnmọ̀mí, tí ó wá pẹ̀lú àwọn ará Arabia sínú ibùdó, tí wọn sì ti pa àwọn ọmọkùnrin àgbà. Bẹ́ẹ̀ ni Ahasiah ọmọ Jehoramu ọba Juda bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ ọba.
2 Forty-two years old, was Ahaziah when he began to reign, and, one year, reigned he in Jerusalem, —and, the name of his mother, was Athaliah, daughter of Omri.
Ahasiah jẹ́ ẹni ọdún méjìlélógún nígbà tí ó di ọba. Ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún kan. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Ataliah, ọmọ ọmọbìnrin Omri.
3 He too, walked in the ways of the house of Ahab, —for, his mother, became his counselor, to work lawlessness.
Ó mú ìrìn ní ọ̀nà ilé Ahabu. Nítorí tí ìyá rẹ̀ kì í láyà nínú ṣíṣe búburú.
4 Wherefore he did the thing that was wicked in the eyes of Yahweh, like the house of Ahab, —for, they, became his counselors, after the death of his father, to his destruction.
Ó ṣe búburú ní ojú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ilé Ahabu ti ṣe, nítorí lẹ́yìn ikú baba a rẹ̀, wọ́n di olùgbani nímọ̀ràn rẹ̀ sí ṣíṣe rẹ̀.
5 Even in their counsel, he walked, and went with Jehoram son of Ahab king of Israel, to war against Hazael king of Syria, in Ramoth-gilead, —and the Syrians smote Joram.
Ó tẹ̀lé ìgbìmọ̀ wọn nígbà tí ó lọ pẹ̀lú Joramu ọmọ Ahabu ọba Israẹli láti gbógun ti Hasaeli ọba Aramu ní Ramoti Gileadi. Àwọn ará Aramu ṣá Joramu ní ọgbẹ́;
6 And he returned to be healed in Jezreel, because of the wounds wherewith they smote him in Ramah, when he fought with Hazael, king of Syria, —and, Azariah son of Jehoram king of Judah, went down to see Jehoram son of Ahab in Jezreel, because, sick, was he!
bẹ́ẹ̀ ni ó padà sí Jesreeli láti wo ọgbẹ́ rẹ̀ sàn tí wọ́n ti dá sí i lára ní Rama ní ojú ogun rẹ̀ pẹ̀lú Hasaeli ọba Siria. Nígbà náà, Ahasiah, ọmọ Jehoramu ọba Juda lọ sí Jesreeli láti lọ rí Joramu ọmọ Ahabu nítorí a ti ṣá a lọ́gbẹ́.
7 But, from God, came the downfall of Azariah, through his coming to Joram, —and because, through his coming, he went out with Jehoram against Jehu son of Nimshi, whom Yahweh had anointed to cut off the house of Ahab.
Ní gbogbo ìgbà ìbẹ̀wò Ahasiah sí Joramu, Ọlọ́run mú ìṣubú Ahasiah wá. Nígbà tí Ahasiah dé, ó jáde lọ pẹ̀lú Jehoramu láti lọ bá Jehu ọmọ Nimṣi, ẹni tí Olúwa ti fi àmì òróró yàn láti pa ìdílé Ahabu run.
8 And so it came to pass, when Jehu was executing judgment upon the house of Ahab, —and found the rulers of Judah and the sons of the brethren of Ahaziah ministering to Ahaziah, that he slew them.
Nígbà tí Jehu ń ṣe ìdájọ́ lórí ilé Ahabu, ó rí àwọn ọmọbìnrin ọba ti Juda àti àwọn ọmọkùnrin ìbátan Ahasi, tí ó ń tọ́jú Ahasiah, ó sì pa wọ́n.
9 And he sought Ahaziah, and they captured him, he, having hid himself in Samaria, and they brought him unto Jehu, and he put him to death, and they buried him, because, said they, he is, the son of Jehoshaphat, who sought Yahweh with all his heart, —and, no one of the house of Ahaziah, had ability for the kingdom.
Ó lọ láti wá Ahasiah, àti àwọn ọkùnrin rẹ̀. Àwọn arákùnrin rẹ̀ ṣẹ́gun rẹ̀ nígbà tí ó sá pamọ́ ní Samaria. A gbé e wá sí ọ̀dọ̀ Jehu, a sì pa á. Wọ́n sin ín nítorí wọ́n wí pé, “Ọmọkùnrin Jehoṣafati ni, ẹni tí ó wá Olúwa pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkan ní ilé Ahasiah tí ó lágbára láti gbé ìjọba náà dúró.
10 But, when, Athaliah mother of Ahaziah, saw that her son was dead, she rose up and destroyed all the seed royal of the house of Judah.
Nígbà tí Ataliah ìyá Ahasiah rí i wí pé ọmọkùnrin rẹ̀ ti kú, ó tẹ̀síwájú láti pa gbogbo ìdílé ọba ti ilẹ̀ Juda run.
11 But Jehoshabeath, daughter of the king, took Joash son of Ahaziah, and stole him from among the sons of the king who were being slain, and put him and his nurse in a bedchamber, —so Jehoshabeath daughter of King Jehoram—wife of Jehoiada the priest, for, she, was the sister of Ahaziah—hid him from the face of Athaliah so that she slew him not.
Ṣùgbọ́n Jehoṣeba ọmọbìnrin ọba Jehoramu mú Joaṣi, ọmọkùnrin Ahasiah ó sì jí gbé lọ kúrò láàrín àwọn ọmọbìnrin ọba, àwọn tí ó kù díẹ̀ kí wọn pa. Wọn gbé òun àti olùtọ́jú rẹ̀ sínú ìyẹ̀wù. Nítorí Jehoṣeba ọmọbìnrin ọba Jehoramu àti ìyàwó àlùfáà Jehoiada jẹ́ arábìnrin Ahasiah. Ó fi ọmọ náà pamọ́ kúrò fún Ataliah, kí ó má ba à pa á.
12 And it came to pass that he was with them, in the house of God, hidden six years, -while, Athaliah, was reigning over the land.
Ó wà ní ìpamọ́ pẹ̀lú wọn ni ilé Ọlọ́run fún ọdún mẹ́fà nígbà tí Ataliah ṣàkóso ilẹ̀ náà.

< 2 Chronicles 22 >