< 1 Chronicles 5 >

1 And the sons of Reuben the firstborn of Israel, for, he, was the firstborn, but because he defiled the couch of his father, his birthright was given to the sons of Joseph son of Israel, —and he is not to be enrolled in the place of firstborn,
Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Reubeni, àkọ́bí Israẹli. (Nítorí òun ni àkọ́bí; ṣùgbọ́n, bí ó ti ṣe pé ó ba ibùsùn baba rẹ̀ jẹ́, a fi ogún ìbí rẹ̀ fún àwọn ọmọ Josẹfu ọmọ Israẹli: a kì yóò sì ka ìtàn ìdílé náà gẹ́gẹ́ bí ipò ìbí.
2 for, Judah, prevailed over his brethren, so that, even the prince, is from him, —although, the birthright, pertaineth to Joseph;
Nítorí Juda borí àwọn arákùnrin rẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni aláṣẹ ti ń jáde wá; ṣùgbọ́n ogún ìbí jẹ́ ti Josẹfu),
3 the sons of Reuben the firstborn of Israel, Hanoch and Pallu, Hezron and Carmi.
àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku àti Pallu, Hesroni àti Karmi.
4 The sons of Joel, Shemaiah his son, Gog his son, Shimei his son;
Àwọn ọmọ Joẹli: Ṣemaiah ọmọ rẹ̀, Gogu ọmọ rẹ̀, Ṣimei ọmọ rẹ̀.
5 Micah his son, Reaiah his son, Baal his son;
Mika ọmọ rẹ̀, Reaiah ọmọ rẹ̀, Baali ọmọ rẹ̀.
6 Beerah his son, whom Tilgath-pilneser king of Assyria carried away captive, —he, was a leader to the Reubenites;
Beera ọmọ rẹ̀, tí Tiglat-Pileseri ọba Asiria kó ní ìgbèkùn lọ. Ìjòyè àwọn ọmọ Reubeni ni Beera jẹ́.
7 and his brethren, by his families, in the genealogical registering, by their generations, —the chief Jeiel, and Zechariah;
Àti àwọn arákùnrin rẹ̀ nípa ìdílé wọn, nígbà tí a ń ka ìtàn ìdílé ìran wọn: Jeieli àti Sekariah ni olórí,
8 and Bela, the son of Azaz, the son of Shema, the son of Joel, —he, dwelt in Aroer, even as far as Nebo, and Baal-meon;
àti Bela ọmọ Asasi ọmọ Ṣema, ọmọ Joẹli. Wọ́n tí ń gbé Aroeri àní títí dé Nebo àti Baali-Meoni.
9 and, eastward, dwelt he as far as the entering in of the desert, from the river Euphrates, —because, their cattle, were multiplied in the land of Gilead;
Àti níhà àríwá, o tẹ̀dó lọ títí dé àtiwọ aginjù láti odò Eufurate; nítorí tí ẹran ọ̀sìn wọn pọ̀ sí i ní ilẹ̀ Gileadi.
10 and, in the days of Saul, they made war with the Hagrites, who fell by their hand, —so they dwelt in their tents, over all the face of the land east of Gilead.
Àti ní ọjọ́ Saulu, wọ́n bá àwọn ọmọ Hagari jagun, ẹni tí ó ṣubú nípa ọwọ́ wọn; wọ́n sì ń gbé inú àgọ́ wọn ní gbogbo ilẹ̀ àríwá Gileadi.
11 And, the sons of Gad, over against them, dwelt, in the land of Bashan, as far as Salecah:
Àti àwọn ọmọ Gadi ń gbé lékè wọn, ní ilẹ̀ Baṣani títí dé Saleka:
12 Joel the chief, and Shapham, the second, —and Janai and Shaphat, in Bashan;
Joẹli jẹ́ olórí, Ṣafamu ìran ọmọ Janai, àti Ṣafati ni Baṣani.
13 and their brethren of their ancestral house, Michael and Meshullam and Sheba and Jorai and Jacan and Zia and Eber, seven.
Àti àwọn arákùnrin wọn ti ilẹ̀ àwọn baba wọn ní: Mikaeli, Meṣullamu Ṣeba, Jorai, Jaka, Sia àti Eberi méje.
14 These, were the sons of Abihail, son of Huri, son of Jaroah, son of Gilead, son of Michael, son of Jehishai, son of Jahdo, son of Buz,
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Abihaili, ọmọ Huri, ọmọ Jeroa, ọmọ Gileadi, ọmọ Mikaeli, ọmọ Jeṣiṣai, ọmọ Jado, ọmọ Busi.
15 Ahi son of Abdiel, son of Guni, chief of their ancestral house;
Ahi, ọmọ Adbeeli, ọmọ Guni, olórí ilé àwọn baba wọn.
16 and they dwelt in Gilead—in Bashan, and in her villages, —and in all the pasture-lands of Sharon, up to their outgoings.
Wọ́n sì ń gbé Gileadi ní Baṣani àti nínú àwọn ìlú rẹ̀, àti nínú gbogbo ìgbèríko Ṣaroni, ní agbègbè wọn.
17 All of them, were genealogically registered in the days of Jotham king of Judah, —and in the days of Jeroboam king of Israel.
Gbogbo wọ̀nyí ni a kà nípa ìtàn ìdílé, ní ọjọ́ Jotamu ọba Juda, àti ní ọjọ́ Jeroboamu ọba Israẹli.
18 the sons of Reuben and Gad, and half tribe of Manasseh, of the sons of valour, men bearing shield and sword and bending the bow, and instructed in war, were forty-four thousand and seven hundred and sixty, ready to go forth in the host.
Àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, nínú àwọn ọkùnrin alágbára tí wọ́n ń gbé asà àti idà, tí wọ́n sì ń fi ọrun tafà, tí wọ́n sì mòye ogun, jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹgbẹ̀rìnlélógún dín ogójì ènìyàn, tí ó jáde lọ sí ogún náà.
19 So they made war with the Hagrites, —and Jetur and Naphish, and Nodab;
Wọ́n sì bá àwọn ọmọ Hagari jagun, pẹ̀lú Jeturi, àti Nafiṣi àti Nadabu.
20 and were helped against them, and the Hagrites and all that were with them were delivered into their hand, —for, unto God, made they outcry, in the war, and he suffered himself to be entreated by them, because they put their trust in him;
Nígbà tí wọ́n sì rí ìrànlọ́wọ́ gbà si, a sì fi àwọn ọmọ Hagari lé wọn lọ́wọ́, àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn; nítorí tiwọn ké pe Ọlọ́run ní ogun náà, òun sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn; nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.
21 and they captured their cattle—their camels, fifty thousand, and, flocks, two hundred and fifty thousand, and, asses, two thousand, —and, persons of men, a hundred thousand;
Wọ́n sì kó ẹran ọ̀sìn wọn lọ; ìbákasẹ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àti àgùntàn ọ̀kẹ́ méjìlá ó lé ẹgbàárùn-ún, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì, àti ènìyàn ọ̀kẹ́ márùn-ún.
22 for, many slain, fell, for, of God, was the war, —and they dwelt in their stead, until the captivity.
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ṣubú tí a pa, nítorí láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni ogun náà, wọ́n sì jókòó ní ipò wọn títí di ìgbà ìkólọ sí ìgbèkùn.
23 And, the sons of the half tribe of Manasseh, dwelt in the land, —from Bashan, as far as to Baal-hermon and Senir and Mount Hermon, they, were multiplied.
Àwọn ọmọkùnrin ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ń gbé ní ilẹ̀ náà: wọ́n bí sí i láti Baṣani títí dé Baali-Hermoni, àti Seniri àti títí dé òkè Hermoni.
24 And, these, were the heads of their ancestral house, —Epher and Ishi and Eliel and Azriel and Jeremiah and Hodaviah and Jahdiel, men who were heroes of valour, men of renown, chiefs to their ancestral house.
Wọ̀nyí sì ni àwọn olórí ilé àwọn baba wọn. Eferi, Iṣi, Elieli, Asrieli, Jeremiah, Hodafiah àti Jahdieli àwọn alágbára akọni ọkùnrin, ọkùnrin olókìkí, àti olórí ilé àwọn baba wọn.
25 But they dealt unfaithfully with the God of their fathers, —and went unchastely after the gods of the peoples of the land, whom God destroyed from before them;
Wọ́n sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run àwọn baba wọn, wọ́n sì ṣe àgbèrè tọ àwọn ọlọ́run ènìyàn ilẹ̀ náà lẹ́yìn, tí Ọlọ́run ti parun ní iwájú wọn.
26 so the God of Israel stirred up the spirit of Pul king of Assyria, and the spirit of Tilgath-pilneser king of Assyria, and he took them away captive, even the Reubenites and the Gadites and the half tribe of Manasseh, —and brought them in unto Halah, and Habor, and Hara, and to the river of Gozan, unto this day.
Nítorí náà Ọlọ́run Israẹli ru ẹ̀mí Pulu ọba Asiria sókè (èyí ni Tiglat-Pileseri ọba Asiria), ó si kó wọn lọ, àní àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase lọ sí ìgbèkùn. Ó sì kó wọn wá sí Hala, àti Habori, àti Harani, àti sí etí odò Gosani; títí dí òní yìí.

< 1 Chronicles 5 >