< Psalms 87 >
1 A Psalm of the sons of Korah; a Song. His foundation is in the holy mountains.
Ti àwọn ọmọ Kora. Saamu. Orin. Ó ti fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ sọlẹ̀ sórí òkè mímọ́;
2 The LORD loveth the gates of Zion more than all the dwellings of Jacob.
Olúwa fẹ́ràn ẹnu-ọ̀nà Sioni ju gbogbo ibùgbé Jakọbu lọ.
3 Glorious things are spoken of thee, O city of God. (Selah)
Ohun ológo ni a sọ nípa rẹ̀, ìlú Ọlọ́run,
4 I will make mention of Rahab and Babylon as among them that know me: behold Philistia, and Tyre, with Ethiopia; this one was born there.
“Èmi ó dárúkọ Rahabu àti Babeli láàrín àwọn tí ó jẹ́wọ́ mi: Filistia pẹ̀lú, àti Tire, pẹ̀lú Kuṣi, yóò sọ pé, ‘Èyí ni a bí ní Sioni.’”
5 Yea, of Zion it shall be said, This one and that one was born in her; and the Most High himself shall establish her.
Nítòótọ́, ti Sioni ni a ó sọ, “Eléyìí àti eléyìí ni a bí nínú rẹ̀, àti Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo ni yóò fìdí rẹ̀ múlẹ̀.”
6 The LORD shall count, when he writeth up the peoples, this one was born there. (Selah)
Olúwa yóò kọ nínú àkọsílẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀: “Eléyìí ni a bí ní Sioni.”
7 They that sing as well as they that dance [shall say], All my fountains are in thee.
Àti àwọn olórin àti àwọn tí ń lu ohun èlò orin yóò wí pé, “Gbogbo orísun mi ń bẹ nínú rẹ.”