< Psalms 68 >

1 For the Chief Musician. A Psalm of David, a Song. Let God arise, let his enemies be scattered; let them also that hate him flee before him.
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Saamu. Orin. Kí Ọlọ́run kí ó dìde, kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó fọ́nká; kí àwọn ọ̀tá rẹ̀ kí ó sá níwájú rẹ̀.
2 As smoke is driven away, so drive them away: as wax melteth before the fire, so let the wicked perish at the presence of God.
Bí ìjì ti ń fẹ́ èéfín lọ, kí ó fẹ́ wọn lọ; bí ìda ti í yọ́ níwájú iná, kí olùṣe búburú ṣègbé níwájú Ọlọ́run.
3 But let the righteous be glad; let them exult before God: yea, let them rejoice with gladness.
Ṣùgbọ́n kí inú olódodo kí ó dùn kí ó sì kún fún ayọ̀ níwájú Ọlọ́run; kí inú wọn kí ó dùn, kí ó sì kún fún ayọ̀.
4 Sing unto God, sing praises to his name: cast up a highway for him that rideth through the deserts; his name is JAH; and exult ye before him.
Ẹ kọrin sí Ọlọ́run, ẹ kọrin ìyìn sí i, ẹ la ọ̀nà fún ẹni tí ń rékọjá ní aginjù. Olúwa ni orúkọ rẹ̀, kí ẹ sì máa yọ̀ níwájú rẹ̀.
5 A father of the fatherless, and a judge of the widows, is God in his holy habitation.
Baba àwọn aláìní baba àti onídàájọ́ àwọn opó ni Ọlọ́run ní ibùgbé rẹ̀ mímọ́
6 God setteth the solitary in families: he bringeth out the prisoners into prosperity: but the rebellious dwell in a parched land.
Ọlọ́run gbé aláìlera kalẹ̀ nínú ìdílé, ó darí àwọn ẹlẹ́wọ̀n pẹ̀lú orin, ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́tẹ̀ ní ń gbé nínú ilẹ̀ gbígbẹ.
7 O God, when thou wentest forth before thy people, when thou didst march through the wilderness; (Selah)
Nígbà tí ìwọ bá jáde lónìí níwájú àwọn ènìyàn rẹ, Ọlọ́run, tí ń kọjá lọ láàrín aginjù, (Sela)
8 The earth trembled, the heavens also dropped at the presence of God: [even] yon Sinai [trembled] at the presence of God, the God of Israel.
Ilẹ̀ mì títí, àwọn ọ̀run ń rọ òjò jáde, níwájú Ọlọ́run, ẹni Sinai, níwájú Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
9 Thou, O God, didst send a plentiful rain, thou didst confirm thine inheritance, when it was weary.
Ìwọ fún wa ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ òjò, Ọlọ́run; ìwọ tu ilẹ̀ ìní rẹ̀ lára nígbà tí ó rẹ̀ ẹ́ tan.
10 Thy congregation dwelt therein: thou, O God, didst prepare of thy goodness for the poor.
Àwọn ènìyàn rẹ tẹ̀dó síbẹ̀ nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìní rẹ, Ọlọ́run, ìwọ pèsè fún àwọn aláìní.
11 The Lord giveth the word: the women that publish the tidings are a great host.
Olúwa ti pàṣẹ ọ̀rọ̀, púpọ̀ ní ogun àwọn ẹni tí ó ń ròyìn rẹ̀.
12 Kings of armies flee, they flee: and she that tarrieth at home divideth the spoil.
“Àwọn ọba àti àwọn ológun yára sálọ; obìnrin tí ó sì jókòó ni ilé ní ń pín ìkógun náà.
13 Will ye lie among the sheepfolds, [as] the wings of a dove covered with silver, and her pinions with yellow gold?
Nígbà tí ẹ̀yin dùbúlẹ̀ láàrín agbo ẹran, nígbà náà ni ẹ̀yin ó dàbí ìyẹ́ àdàbà ti a bò ní fàdákà, àti ìyẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú wúrà pupa.”
14 When the Almighty scattered kings therein, [it was as when] it snoweth in Zalmon.
Nígbà tí Olódùmarè fọ́n àwọn ọba ká ní ilẹ̀ náà, ó dàbí òjò dídi ní Salmoni.
15 A mountain of God is the mountain of Bashan; an high mountain is the mountain of Bashan.
Òkè Baṣani jẹ́ òkè Ọlọ́run; òkè tí ó ní orí púpọ̀ ni òkè Baṣani.
16 Why look ye askance, ye high mountains, at the mountain which God hath desired for his abode? yea, the LORD will dwell [in it] for ever.
Kí ló dé tí ẹ̀yin fi ń ṣe ìlara, ẹ̀yin òkè wúwo, òkè tí Ọlọ́run ti fẹ́ láti jẹ ọba níbi tí Olúwa fúnra rẹ̀ yóò máa gbé títí láé?
17 The chariots of God are twenty thousand, even thousands upon thousands: the Lord is among them, [as in] Sinai, in the sanctuary.
Ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ni kẹ̀kẹ́ ogun Ọlọ́run ẹgbẹ̀rún lọ́nà ẹgbẹ̀rún; Olúwa ń bẹ láàrín wọn, ní Sinai ni ibi mímọ́ rẹ̀.
18 Thou hast ascended on high, thou hast led [thy] captivity captive; thou hast received gifts among men, yea, [among] the rebellious also, that the LORD God might dwell [with them].
Ìwọ ti gòkè sí ibi gíga ìwọ ti di ìgbèkùn ní ìgbèkùn lọ; ìwọ ti gba ẹ̀bùn fún ènìyàn: nítòótọ́, fún àwọn ọlọ̀tẹ̀ pẹ̀lú, kí Olúwa Ọlọ́run lè máa bá wọn gbé.
19 Blessed be the Lord, who daily beareth our burden, even the God who is our salvation. (Selah)
Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run Olùgbàlà wa, ẹni tí ó ń fi ojoojúmọ́ gba ẹrù wa rù. (Sela)
20 God is unto us a God of deliverances; and unto JEHOVAH the Lord belong the issues from death.
Ọlọ́run wa jẹ́ Ọlọ́run tó ń gbàlà àti sí Olúwa Olódùmarè ni ó ń gbà wá lọ́wọ́ ikú.
21 But God shall smite through the head of his enemies, the hairy scalp of such an one as goeth on still in his guiltiness.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò tẹ orí àwọn ọ̀tá rẹ̀, àti agbárí onírun àwọn tó ń tẹ̀síwájú nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn
22 The Lord said, I will bring again from Bashan, I will bring [them] again from the depths of the sea:
Olúwa wí pé, “Èmi ó mú wọn wá láti Baṣani; èmi ó mú wọn wá láti ibú omi Òkun,
23 That thou mayest dip thy foot in blood, that the tongue of thy dogs may have its portion from [thine] enemies.
kí ẹsẹ̀ rẹ kí ó le pọ́n ní inú ẹ̀jẹ̀ àwọn ọ̀tá rẹ, àti ahọ́n àwọn ajá rẹ ní ìpín tiwọn lára àwọn ọ̀tá rẹ.”
24 They have seen thy goings, O God, even the goings of my God, my King, into the sanctuary.
Wọ́n ti rí ìrìn rẹ, Ọlọ́run, ìrìn Ọlọ́run mi àti ọba mi ní ibi mímọ́ rẹ̀.
25 The singers went before, the minstrels followed after, in the midst of the damsels playing with timbrels.
Àwọn akọrin wà ní iwájú, àwọn olórin wà lẹ́yìn; àwọn ọmọbìnrin tí ń lu ṣaworo sì wà pẹ̀lú wọn.
26 Bless ye God in the congregations, even the Lord, [ye that are] of the fountain of Israel.
Ẹ fi ìyìn fún Olúwa ní ẹgbẹgbẹ́; àní fún Olúwa ẹ̀yin tí ó ti orísun Israẹli wá.
27 There is little Benjamin their ruler, the princes of Judah [and] their council, the princes of Zebulun, the princes of Naphtali.
Níbẹ̀ ní ẹ̀yà kékeré Benjamini wà, tí ó ń darí wọn, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Juda, níbẹ̀ ni àwọn ọmọ-aládé Sebuluni àti tí Naftali.
28 Thy God hath commanded thy strength: strengthen, O God, that which thou hast wrought for us.
Pàṣẹ agbára rẹ, Ọlọ́run; fi agbára rẹ hàn wá, Ọlọ́run, gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti ṣe ní ìṣáájú.
29 Because of thy temple at Jerusalem kings shall bring presents unto thee.
Nítorí tẹmpili rẹ ni Jerusalẹmu àwọn ọba yóò mú ẹ̀bùn wá fún ọ.
30 Rebuke the wild beast of the reeds, the multitude of the bulls, with the calves of the peoples, trampling under foot the pieces of silver; he hath scattered the peoples that delight in war.
Bá àwọn ẹranko búburú wí, tí ń gbé láàrín eèsún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn akọ màlúù pẹ̀lú àwọn ọmọ màlúù títí olúkúlùkù yóò fi foríbalẹ̀ pẹ̀lú ìwọ̀n fàdákà: tú àwọn ènìyàn tí ń ṣe inú dídùn sí ogun ká.
31 Princes shall come out of Egypt; Ethiopia shall haste to stretch out her hands unto God.
Àwọn ọmọ-aládé yóò wá láti Ejibiti; Etiopia yóò na ọwọ́ rẹ̀ sí Ọlọ́run.
32 Sing unto God, ye kingdoms of the earth; O sing praises unto the Lord; (Selah)
Kọrin sí Ọlọ́run, ẹ̀yin ìjọba ayé, kọrin ìyìn sí Olúwa, (Sela)
33 To him that rideth upon the heavens of heavens, which are of old; lo, he uttereth his voice, [and that] a mighty voice.
Sí ẹni tí ń gun ọ̀run dé ọ̀run àtijọ́ lókè, tó ń fọhùn rẹ̀, ohùn ńlá.
34 Ascribe ye strength unto God: his excellency is over Israel, and his strength is in the skies.
Kéde agbára Ọlọ́run, ọláńlá rẹ̀ wà lórí Israẹli, tí agbára rẹ̀ wà lójú ọ̀run.
35 O God, [thou art] terrible out of thy holy places: the God of Israel, he giveth strength and power unto [his] people. Blessed be God.
Ìwọ ní ẹ̀rù, Ọlọ́run, ní ibi mímọ́ rẹ; Ọlọ́run Israẹli fi agbára àti okun fún àwọn ènìyàn rẹ. Olùbùkún ní Ọlọ́run!

< Psalms 68 >