< Psalms 116 >

1 I LOVE the LORD, because he hath heard my voice and my supplications.
Èmi fẹ́ràn Olúwa, nítorí ó gbọ́ ohùn mi; ó gbọ́ ẹkún mi fún àánú.
2 Because he hath inclined his ear unto me, therefore will I call [upon him] as long as I live.
Nítorí ó yí etí rẹ̀ padà sí mi, èmi yóò máa pè é ni wọ́n ìgbà tí mo wà láààyè.
3 The cords of death compassed me, and the pains of Sheol gat hold upon me: I found trouble and sorrow. (Sheol h7585)
Okùn ikú yí mi ká, ìrora isà òkú wá sórí mi; ìyọnu àti ìbànújẹ́ borí mi. (Sheol h7585)
4 Then called I upon the name of the LORD; O LORD, I beseech thee, deliver my soul.
Nígbà náà ni mo ké pe orúkọ Olúwa: “Olúwa, èmi bẹ̀ ọ́, gba ọkàn mi!”
5 Gracious is the LORD, and righteous; yea, our God is merciful.
Olúwa ní oore-ọ̀fẹ́, ó sì ní òdodo; Ọlọ́run wa kún fún àánú.
6 The LORD preserveth the simple: I was brought low, and he saved me.
Olúwa pa àwọn ọlọ́kàn fífúyẹ́ mọ́ nígbà tí mo wà nínú àìní ńlá, ó gbà mí.
7 Return unto thy rest, O my soul; for the LORD hath dealt bountifully with thee.
Padà, ìwọ ọkàn mi, sí ibi ìsinmi rẹ, nítorí Olúwa ṣe dáradára sí ọ.
8 For thou hast delivered my soul from death, mine eyes from tears, [and] my feet from falling.
Nítorí ìwọ, Olúwa, ti gba ọkàn mi kúrò lọ́wọ́ ikú, ojú mi kúrò lọ́wọ́ omijé, àti ẹsẹ̀ mi kúrò lọ́wọ́ ìṣubú,
9 I will walk before the LORD in the land of the living.
nítorí èmi yóò máa rìn níwájú Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
10 I believe, for I will speak: I was greatly afflicted:
Èmi gbàgbọ́; nítorí náà mo wí pé, “èmi rí ìpọ́njú púpọ̀”.
11 I said in my haste, All men are a lie.
Àti nínú ìdààmú mi mo wí pé, “Èké ni gbogbo ènìyàn”.
12 What shall I render unto the LORD for all his benefits toward me?
Kí ni èmi yóò san fún Olúwa nítorí gbogbo rere rẹ̀ sí mi?
13 I will take the cup of salvation, and call upon the name of the LORD.
Èmi yóò gbé ago ìgbàlà sókè èmi yóò sì máa ké pe orúkọ Olúwa.
14 I will pay my vows unto the LORD, yea, in the presence of all his people.
Èmi yóò mú ìlérí mi ṣẹ sí Olúwa ní ojú àwọn ènìyàn rẹ̀.
15 Precious in the sight of the LORD is the death of his saints.
Iyebíye ní ojú Olúwa àti ikú àwọn ẹni mímọ́ rẹ̀.
16 O LORD, truly I am thy servant: I am thy servant, the son of thine handmaid; thou hast loosed my bonds.
Olúwa, nítòótọ́ ìránṣẹ́ rẹ ni mo jẹ́; èmi ni ìránṣẹ́ rẹ, ọmọ ìránṣẹ́bìnrin rẹ; ó ti tú mi sílẹ̀ nínú ìdè mi.
17 I will offer to thee the sacrifice of thanksgiving, and will call upon the name of the LORD.
Èmi yóò rú ẹbọ ọpẹ́ sí ọ èmi yóò sì ké pe orúkọ Olúwa.
18 I will pay my vows unto the LORD, yea, in the presence of all his people.
Èmi yóò mú ìlérí mi sẹ sí Olúwa ní ojú gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀,
19 In the courts of the LORD’S house, in the midst of thee, O Jerusalem. Praise ye the LORD.
nínú àgbàlá ilé Olúwa ní àárín rẹ̀, ìwọ Jerusalẹmu. Ẹ yin Olúwa.

< Psalms 116 >