< Numbers 33 >
1 These are the stages in the journeys of the children of Israel [God prevails], as they left the land of Egypt [Abode of slavery] divided into groups under the leadership of Moses [Drawn out] and Aaron [Light-bringer].
Wọ̀nyí ni ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli ní ẹsẹẹsẹ, nígbà tí wọ́n tí ilẹ̀ Ejibiti jáde wá pẹ̀lú àwọn ogun wọn, nípa ọwọ́ Mose àti Aaroni.
2 Moses [Drawn out] recorded each of the stages of their journeys by the order of Adonai. These are their journeys according to their goings out.
Mose sì kọ̀wé ìjáde lọ wọn ní ẹsẹẹsẹ gẹ́gẹ́ bí ìrìnàjò wọn, nípa àṣẹ Olúwa, wọ̀nyí sì ni ìrìnàjò wọn gẹ́gẹ́ bí ìjáde lọ wọn.
3 They traveled from Rameses in the first month Nissan ·Miracles (in Aramaic), 1·, on the fifteenth day of the first month Nissan ·Miracles (in Aramaic), 1·; on the next day after the Pesac ·Passover·, the children of Israel [God prevails] went out with a high hand in the sight of all the Egyptians [people from Abode of slavery],
Àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò láti Ramesesi ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kìn-ín-ní, ọjọ́ kan lẹ́yìn àjọ ìrékọjá. Wọ́n yan jáde pẹ̀lú ìgboyà níwájú gbogbo àwọn ará Ejibiti.
4 while the Egyptians [people from Abode of slavery] were burying all their firstborn, whom Adonai had struck among them. Adonai also executed judgments on their deities.
Tí wọ́n sì ń sin gbogbo àkọ́bí wọn, ẹni tí Olúwa ti gbé lulẹ̀ láàrín wọn; nítorí tí Olúwa ti mú ẹ̀san wá sórí àwọn òrìṣà wọn.
5 The children of Israel [God prevails] traveled from Rameses, and encamped in Sukkot.
Àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní Ramesesi wọ́n sì pàgọ́ sí Sukkoti.
6 They traveled from Sukkot, and encamped in Etham, which is in the edge of the wilderness.
Wọ́n kúrò ní Sukkoti, wọ́n sì pàgọ́ sí Etamu, ní ẹ̀bá aginjù.
7 They traveled from Etham, and turned back to Pihahiroth, which is before Baal Zephon: and they encamped before Migdol.
Wọ́n kúrò ní Etamu, wọ́n padà sí Pi-Hahirotu sí ìlà-oòrùn Baali-Ṣefoni, wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Migdoli.
8 They traveled from before Hahiroth, and crossed through the middle of the sea into the wilderness. They went three days’ journey in the wilderness of Etham, and encamped in Marah [Bitter].
Wọ́n sì dìde láti lọ kúrò ní iwájú Pi-Hahirotu, wọ́n sì la àárín òkun kọjá lọ sí aginjù. Wọ́n sì rin ìrìn ọjọ́ mẹ́ta ní aginjù Etamu, wọ́n sì pàgọ́ sí Mara.
9 They traveled from Marah [Bitter], and came to Elim. In Elim, there were twelve springs of water, and seventy palm trees; and they encamped there.
Wọ́n kúrò ní Mara wọ́n sì lọ sí Elimu, níbi tí orísun omi méjìlá àti igi ọ̀pẹ àádọ́rin gbé wà, wọ́n sì pàgọ́ níbẹ̀.
10 They traveled from Elim, and encamped by the Sea of Suf [Reed Sea].
Wọ́n kúrò ní Elimu wọ́n sì pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun Pupa.
11 They traveled from the Sea of Suf [Reed Sea], and encamped in the wilderness of Cin [Clay].
Wọ́n kúrò ní ẹ̀bá Òkun Pupa wọ́n sì pàgọ́ sínú aginjù Sini.
12 They traveled from the wilderness of Cin [Clay], and encamped in Dophkah.
Wọ́n kúrò nínú aginjù Sini wọ́n sì pàgọ́ sí aginjù Dofka.
13 They traveled from Dophkah, and encamped in Alush.
Wọ́n kúrò ní Dofka wọ́n sì pàgọ́ ní Aluṣi.
14 They traveled from Alush, and encamped in Rephidim, where there was no water for the people to drink.
Wọ́n kúrò ní Aluṣi wọ́n sì pàgọ́ ní Refidimu níbi tí kò sí omi fún àwọn ènìyàn náà láti mu.
15 They traveled from Rephidim, and encamped in the wilderness of Sinai [Thorn].
Wọ́n kúrò ní Refidimu wọ́n sì pàgọ́ ní aginjù Sinai.
16 They traveled from the wilderness of Sinai [Thorn], and encamped in Kibroth Hattaavah.
Wọ́n kúrò ní aginjù Sinai wọ́n sì pàgọ́ ní Kibirotu-Hattaafa.
17 They traveled from Kibroth Hattaavah, and encamped in Hazeroth.
Wọ́n kúrò ní Kibirotu-Hattaafa wọ́n sì pàgọ́ ní Haserotu.
18 They traveled from Hazeroth, and encamped in Rithmah.
Wọ́n kúrò ní Haserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Ritma.
19 They traveled from Rithmah, and encamped in Rimmon Perez.
Wọ́n kúrò ní Ritma wọ́n sì pàgọ́ ní Rimoni-Peresi.
20 They traveled from Rimmon Perez, and encamped in Libnah.
Wọ́n kúrò ní Rimoni-Peresi wọ́n sì pàgọ́ ní Libina.
21 They traveled from Libnah, and encamped in Rissah.
Wọ́n kúrò ní Libina wọ́n sì pàgọ́ ní Rissa.
22 They traveled from Rissah, and encamped in Kehelathah.
Wọ́n kúrò ní Rissa wọ́n sì pàgọ́ ní Kehelata.
23 They traveled from Kehelathah, and encamped in Mount Shepher.
Wọ́n kúrò ní Kehelata wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Ṣeferi.
24 They traveled from Mount Shepher, and encamped in Haradah.
Wọ́n kúrò lórí òkè Ṣeferi wọ́n sì pàgọ́ ní Harada.
25 They traveled from Haradah, and encamped in Makheloth.
Wọ́n kúrò ní Harada wọ́n sì pàgọ́ ní Makhelotu.
26 They traveled from Makheloth, and encamped in Tahath.
Wọ́n kúrò ní Makhelotu wọ́n sì pàgọ́ ní Tahati.
27 They traveled from Tahath, and encamped in Terah.
Wọ́n kúrò ní Tahati wọ́n sì pàgọ́ ní Tẹra.
28 They traveled from Terah, and encamped in Mithkah.
Wọ́n kúrò ní Tẹra wọ́n sì pàgọ́ ní Mitka.
29 They traveled from Mithkah, and encamped in Hashmonah.
Wọ́n kúrò ní Mitka wọ́n pàgọ́ ní Haṣmona.
30 They traveled from Hashmonah, and encamped in Moseroth.
Wọ́n kúrò ní Haṣmona wọ́n sì pàgọ́ ní Moserotu.
31 They traveled from Moseroth, and encamped in Bene Jaakan.
Wọ́n kúrò ní Moserotu wọ́n sì pàgọ́ ní Bene-Jaakani.
32 They traveled from Bene Jaakan, and encamped in Hor Haggidgad.
Wọ́n kúrò ní Bene-Jaakani wọ́n sì pàgọ́ ní Hori-Haggidgadi.
33 They traveled from Hor Haggidgad, and encamped in Jotbathah.
Wọ́n kúrò ní Hori-Haggidgadi wọ́n sí pàgọ́ ní Jotbata.
34 They traveled from Jotbathah, and encamped in Abronah.
Wọ́n kúrò ní Jotbata wọ́n sì pàgọ́ ní Abrona.
35 They traveled from Abronah, and encamped in Ezion Geber.
Wọ́n kúrò ní Abrona wọ́n sì pàgọ́ ní Esioni-Geberi.
36 They traveled from Ezion Geber, and encamped at Kadesh in the wilderness of Zin.
Wọ́n kúrò ní Esioni-Geberi wọ́n sì pàgọ́ ní Kadeṣi nínú aginjù Sini.
37 They traveled from Kadesh, and encamped in Mount Hor, in the edge of the land of Edom [Red].
Wọ́n kúrò ní Kadeṣi wọ́n sì pàgọ́ ní orí òkè Hori, lẹ́bàá Edomu.
38 At the order of Adonai, Aaron [Light-bringer] the priest went up into Mount Hor, and died there, in the fortieth year after the children of Israel [God prevails] had come out of the land of Egypt [Abode of slavery], in the fifth month Av ·Father, 5·, on the first day of the month.
Nípa àṣẹ Olúwa, Aaroni àlùfáà gùn orí òkè Hori, níbẹ̀ ni ó kú. Ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún, ọdún ogójì, lẹ́yìn tí àwọn ọmọ Israẹli ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá.
39 Aaron [Light-bringer] was one hundred twenty-three years old when he died in Mount Hor.
Aaroni jẹ́ ẹni ọgọ́fà ọdún ó lé mẹ́ta ní ìgbà tí ó kú sí orí òkè Hori.
40 The Canaanite [Descendant of Humbled], the king of Arad, who lived in the South in the land of Canaan [Humbled], sh'ma ·heard obeyed· of the coming of the children of Israel [God prevails].
Àwọn ará Kenaani, ọba Aradi, tí ń gbé ìhà gúúsù ní ilẹ̀ Kenaani gbọ́ pé àwọn ọmọ Israẹli ń bọ̀.
41 They traveled from Mount Hor, and encamped in Zalmonah.
Wọ́n kúrò ní orí òkè Hori, wọ́n sì pàgọ́ ní Salmona.
42 They traveled from Zalmonah, and encamped in Punon.
Wọ́n kúrò ní Salmona wọ́n sì pàgọ́ ní Punoni.
43 They traveled from Punon, and encamped in Oboth.
Wọ́n kúrò ní Punoni wọ́n sì pàgọ́ ní Obotu.
44 They traveled from Oboth, and encamped in Iye Abarim, in the border of Moab [From father].
Wọ́n kúrò ní Obotu wọ́n sì pàgọ́ ní Iye-Abarimu, ní agbègbè Moabu.
45 They traveled from Iyim, and encamped in Dibon Gad [Good fortune].
Wọ́n kúrò ní Iyimu, wọ́n sì pàgọ́ ní Diboni-Gadi.
46 They traveled from Dibon Gad [Good fortune], and encamped in Almon Diblathaim.
Wọ́n kúrò ní Diboni-Gadi wọ́n sì pàgọ́ ní Alimon-Diblataimu.
47 They traveled from Almon Diblathaim, and encamped in the mountains of Abarim, before Nebo.
Wọ́n kúrò ní Alimon-Diblataimu wọ́n sì pàgọ́ sí orí òkè Abarimu lẹ́bàá Nebo.
48 They traveled from the mountains of Abarim, and encamped in the plains of Moab [From father] by the Jordan [Descender] at Jericho [Fragrant, Moon].
Wọ́n kúrò ní orí òkè Abarimu wọ́n sì pàgọ́ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá Jordani ní ìkọjá Jeriko.
49 They encamped by the Jordan [Descender], from Beth Jeshimoth even to Abel [Vanity, Mourning] Shittim in the plains of Moab [From father].
Níbí ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n pàgọ́ lẹ́gbẹ́ Jordani láti Beti-Jeṣimoti títí dé Abeli-Ṣittimu.
50 Adonai spoke to Moses [Drawn out] in the plains of Moab [From father] by the Jordan [Descender] at Jericho [Fragrant, Moon], saying,
Ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu, lẹ́bàá Jordani, létí Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
51 Speak to the children of Israel [God prevails], and tell them, “When you pass over the Jordan [Descender] into the land of Canaan [Humbled],
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Ní ìgbà tí ẹ̀yin bá ń rékọjá odò Jordani lọ sí Kenaani,
52 then you shall drive out all the inhabitants of the land from before you, destroy all their stone idols, destroy all their molten images, and demolish all their high places.
lé gbogbo àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín. Run gbogbo àwòrán ère wọn àti gbogbo ère dídá wọn, kí ẹ sì wó gbogbo ibi gíga wọn palẹ̀.
53 You shall take possession of the land, and dwell therein; for I have given the land to you to possess it.
Ẹ gba ilẹ̀ náà, kí ẹ̀yin sì máa gbé inú rẹ̀, nítorí èmi ti fi ilẹ̀ náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ìní yín.
54 You shall inherit the land by lot according to your families; to the more you shall give the more inheritance, and to the fewer you shall give the less inheritance. Wherever the lot falls to any man, that shall be his. You shall inherit according to the tribes of your fathers.
Ẹ̀yin pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú kèké, gẹ́gẹ́ bí ìdílé yín. Fún ọ̀pọ̀ ni kí ẹ̀yin ó fi ilẹ̀ ìní púpọ̀ fún, àti fún díẹ̀, ni kí ẹ̀yin kí ó fi ilẹ̀ ìní díẹ̀ fún. Ohunkóhun tí ó bá bọ́ sí ọ̀dọ̀ wọn nípa kèké yóò jẹ́ tiwọn. Pín wọn gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà ìran wọn.
55 “But if you do not drive out the inhabitants of the land from before you, then those you let remain of them will be as pricks in your eyes and as thorns in your sides, and they will harass you in the land in which you dwell.
“‘Ṣùgbọ́n bí ẹ kò bá lé àwọn ará ilẹ̀ náà kúrò níwájú yín, àwọn tí ẹ bá jẹ́ kí ó kù yóò di ọfà nínú ojú yín, àti ẹ̀gún ní ìhà yín. Wọn yóò fún yín ní wàhálà ní ilẹ̀ náà tí ẹ̀yin yóò gbé.
56 It shall happen that as I thought to do to them, so will I do to you.”
Nígbà náà, èmi yóò ṣe sí yín, ohun tí mo ti rò láti ṣe sí wọn.’”