< Psalms 86 >
1 “A prayer of David.” Incline thine ear, O LORD! and hear me, For I am poor and distressed!
Àdúrà ti Dafidi. Gbọ́, Olúwa, kí o sì dá mi lóhùn, nítorí mo jẹ́ tálákà àti aláìní.
2 Preserve my life, for I am devoted to thee! Save, O thou my God! thy servant who trusteth in thee!
Dáàbò bò ayé mi, nítorí a ti yà mí sọ́tọ̀ fún ọ: ìwọ ni Ọlọ́run mi, gbà ìránṣẹ́ rẹ là tí ó gbẹ́kẹ̀lé ọ.
3 Have pity upon me, O Lord! For to thee do I cry daily!
Ṣàánú fún mi, Olúwa, nítorí èmi ń pè ọ́ ní gbogbo ọjọ́.
4 Revive the soul of thy servant, For to thee, O Lord! do I lift up my soul!
Mú ayọ̀ wà fún ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ, Olúwa, ni mo gbé ọkàn mí sókè sí.
5 For thou, Lord, art good, and ready to forgive; Yea, rich in mercy to all that call upon thee!
Ìwọ ń dáríjì, ìwọ sì dára, Olúwa, ìwọ sì ṣàánú fún gbogbo àwọn tí ń ké pè ọ́.
6 Give ear, O LORD! to my prayer, And attend to the voice of my supplication!
Gbọ́ àdúrà mi, Olúwa; tẹ́tí sí ẹkún mi fún àánú.
7 In the day of my trouble I call upon thee, For thou dost answer me!
Ní ọjọ́ ìpọ́njú mi èmi yóò pè ọ́, nítorí ìwọ yóò dá mi lóhùn.
8 Among the gods there is none like thee, O Lord! And there are no works like thy works!
Nínú àwọn òrìṣà kò sí ẹni tí ó dàbí i rẹ, Olúwa: kò sí àwọn iṣẹ́ tí a lè fiwé tìrẹ.
9 All the nations which thou hast made must come and worship before thee, O Lord! And glorify thy name!
Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ dá yóò wá láti wá jọ́sìn níwájú rẹ, Olúwa; wọn ó mú ògo wà fún orúkọ rẹ̀.
10 For great art thou, and wondrous are thy works; Thou alone art God!
Nítorí pé ìwọ tóbi, ìwọ sì ń ṣe ohun ìyanu; ìwọ nìkan ni Ọlọ́run.
11 Teach me, O LORD! thy way, That I may walk in thy truth; Unite all my heart to fear thy name!
Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, èmi ó sì máa rìn nínú òtítọ́ rẹ; fún mi ní ọkàn tí kì í yapa, kí èmi kí ó ba lè bẹ̀rù orúkọ rẹ.
12 I will praise thee, O Lord, my God! with my whole heart; I will give glory to thy name for ever!
Èmi ó yìn ọ́, Olúwa Ọlọ́run mi, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó fògo fún orúkọ rẹ títí láé.
13 For thy kindness to me hath been great; Thou hast delivered me from the depths of the underworld! (Sheol )
Nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ si mi; ìwọ ti gbà mí kúrò nínú ọ̀gbun isà òkú. (Sheol )
14 O God! the proud have risen against me; Bands of cruel men seek my life, And set not thee before their eyes.
Àwọn onígbèéraga ń dojúkọ mí, Ọlọ́run; àti ìjọ àwọn alágbára ń wá ọkàn mi kiri, wọn kò sì fi ọ́ pè.
15 But thou, O Lord! art a God full of compassion and kindness, Long-suffering, rich in mercy and truth!
Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, jẹ́ aláàánú àti Ọlọ́run olójúrere, Ó lọ́ra láti bínú, Ó sì pọ̀ ní ìfẹ́ àti òtítọ́.
16 Look upon me, and have compassion upon me! Give thy strength to thy servant, And save the son of thy handmaid!
Yípadà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi; fún àwọn ènìyàn rẹ ní agbára kí o sì gba ọ̀dọ́mọkùnrin ìránṣẹ́bìnrin rẹ là.
17 Show me a token for good, That my enemies may see it and be confounded; Because thou, O LORD! helpest and comfortest me!
Fi àmì hàn mí fún rere, kí àwọn tí ó kórìíra mi lè ri, kí ojú lè tì wọ́n, nítorí ìwọ Olúwa ni ó ti tù mí nínú.