< Psalms 33 >
1 Rejoice, O ye righteous, in the LORD! For praise becometh the upright.
Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olódodo; ìyìn si yẹ fún ẹni dídúró ṣinṣin.
2 Praise the LORD with the harp; Sing to him with the ten-stringed psaltery!
Ẹ yin Olúwa pẹ̀lú dùùrù; ẹ máa fi ohun èlò olókùn mẹ́wàá kọrin sí i.
3 Sing to him a new song; Play skilfully amid the sound of trumpets!
Ẹ kọ orin tuntun sí i; ẹ máa fi ọgbọọgbọ́n lu ohun èlò orin sí i, pẹ̀lú ariwo.
4 For the word of the LORD is right, And all his acts are faithful.
Nítorí pé ọ̀rọ̀ Olúwa dúró ṣinṣin, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ni à ń ṣe nínú òtítọ́.
5 He loveth justice and equity; The earth is full of the goodness of the LORD.
Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́; ilé ayé kún fún ìdúró ṣinṣin àti àánú Olúwa.
6 By the word of the LORD were the heavens made, And all the hosts of them by the breath of his mouth.
Nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ṣe dá àwọn ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹgbẹ́ ogun wọn nípa ìmísí ẹnu rẹ̀.
7 He gathereth the waters of the sea, as a heap; He layeth up the deep in storehouses.
Ó kó àwọn omi òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò; ó sì fi ibú ṣe ilé ìṣúra gbogbo.
8 Let all the earth fear the LORD; Let all the inhabitants of the world stand in awe of him!
Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù Olúwa: jẹ́ kí gbogbo àwọn olùgbé ayé kí ó wà nínú ìbẹ̀rù rẹ̀.
9 For he spake, and it was done; He commanded, and it stood fast.
Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀; ó pàṣẹ ó sì dúró ṣinṣin.
10 The LORD bringeth the devices of the nations to nothing; He frustrateth the designs of kingdoms.
Olúwa ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀-èdè wá sí asán; ó sì mú àrékérekè àwọn ènìyàn di ṣíṣákì í.
11 The purposes of the LORD stand for ever; The designs of his heart, to all generations.
Ìgbìmọ̀ Olúwa dúró títí ayérayé, àní ìrò inú rẹ̀ láti ìrandíran ni.
12 Happy the nation whose God is Jehovah; The people whom he hath chosen for his inheritance.
Ìbùkún ni fún orílẹ̀-èdè náà, Ọlọ́run ẹni tí Olúwa jẹ́ tirẹ̀, àti àwọn ènìyàn náà tí ó ti yàn ṣe ìní rẹ̀.
13 The LORD looketh down from heaven; He beholdeth all the children of men;
Olúwa wò láti ọ̀run wá; Ó sì rí gbogbo ìran ènìyàn.
14 From his dwelling-place he beholdeth all the inhabitants of the earth, —
Níbi tí ó ti jókòó lórí ìtẹ́ Ó wo gbogbo àwọn olùgbé ayé
15 He that formed the hearts of all, And observeth all their works.
ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà, ó sì kíyèsi ìṣe wọn.
16 A king is not saved by the number of his forces, Nor a hero by the greatness of his strength.
A kò gba ọba kan là nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun; kò sì sí jagunjagun tí a gbà sílẹ̀ nípa agbára ńlá rẹ̀.
17 The horse is a vain thing for safety, Nor can he deliver his master by his great strength.
Ohun asán ni ẹṣin fún ìṣẹ́gun; bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fi agbára ńlá rẹ̀ gbani sílẹ̀.
18 Behold, the eye of the LORD is upon them that fear him, —Upon them that trust in his goodness;
Wò ó, ojú Olúwa wà lára àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti lára àwọn tí ó ní ìrètí nínú ìfẹ́ rẹ̀ tí ó dúró ṣinṣin.
19 To save them from the power of death, And keep them alive in famine.
Láti gba ọkàn wọn kúrò lọ́wọ́ ikú àti láti pa wọ́n mọ́ láààyè lọ́wọ́ ìyàn.
20 The hope of our souls is in the LORD; He is our help and our shield.
Ọkàn wa dúró de Olúwa; òun ni ìrànlọ́wọ́ wa àti asà wa.
21 Yea, in him doth our heart rejoice; In his holy name we have confidence.
Ọkàn wa yọ̀ nínú rẹ̀, nítorí pé, àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ rẹ mímọ́.
22 May thy goodness be upon us, O LORD! According as we trust in thee!
Kí àánú rẹ, Olúwa, kí ó wà lára wa, àní gẹ́gẹ́ bí àwa ti ń ṣe ìrètí nínú rẹ.