< Micah 2 >

1 Woe to them that devise iniquity, And contrive evil upon their beds; When the morning is light, they practise it, Because it is in the power of their hand.
Ègbé ni fún àwọn tí ń gbèrò àìṣedéédéé tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ibi lórí ibùsùn wọn! Nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́, wọn yóò gbé e jáde nítorí ó wà ní agbára wọn láti ṣe é.
2 They covet fields, and take them by violence; Houses, and take them from their owners. They defraud a man of his house; Yea, a man of his inheritance.
Wọ́n sì ń ṣe ojúkòkòrò oko, wọ́n sì fi agbára wọn gbà wọ́n, àti àwọn ilé, wọ́n sì gbà wọ́n. Wọ́n sì ni ènìyàn àti ilẹ̀ rẹ̀ lára àní ènìyàn àti ohun ìní rẹ̀.
3 Therefore, thus saith Jehovah: Behold, against this race do I meditate evil. From which ye shall not remove your necks, nor lift up your heads; For it shall be a time of evil.
Nítorí náà, Olúwa wí pé: “Èmi ń gbèrò ibi sí àwọn ìdílé wọ̀nyí, nínú èyí tí wọn kì yóò le è gba ara wọn là. Ìwọ kì yóò sì lè máa rìn ní ìgbéraga mọ́, nítorí yóò jẹ́ àkókò ibi.
4 In that day shall this song be uttered concerning thee. And this sad lamentation be made: “We are utterly laid waste; He hath changed the portion of my people; How hath he torn it from me! He hath taken away and distributed our fields.”
Ní ọjọ́ náà ni ẹnìkan yóò pa òwe kan sí yín; wọn yóò sì pohùnréré ẹkún kíkorò pé: ‘Ní kíkó a ti kó wọn tán; Olúwa ti pín ohun ìní àwọn ènìyàn mi; Ó ti mú un kúrò lọ́dọ̀ mi! Ó fi oko wa lé àwọn ọlọ̀tẹ̀ lọ́wọ́.’”
5 Behold, thou shalt have no one henceforth Who shall draw out a line for a portion, In the congregation of Jehovah.
Nítorí náà, ìwọ kò ní ní ẹnìkankan tí yóò ta okùn nínú ìjọ Olúwa, tí yóò pín ilẹ̀ nípa ìbò.
6 “Prophesy not,” [[say they, ]] “O ye that prophesy!” If they prophesy not concerning these things, The shame will not depart.
“Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀,” ni àwọn wòlíì wọn wí. “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀ nípa nǹkan wọ̀nyí; kí ìtìjú má ṣe le bá wa.”
7 O ye that are called the house of Jacob, Is the spirit of Jehovah impatient? Are these his doings? Are not my words kind to him that walketh uprightly?
Ṣé kí á sọ ọ́, ìwọ ilé Jakọbu: “Ǹjẹ́ ẹ̀mí Olúwa ha ń bínú bí? Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ ha nìwọ̀nyí?” “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ mi kò ha ń ṣe rere fún ẹni tí ń rìn déédé bí?
8 But long since hath my people risen against me, as an enemy; Ye strip the mantle from the garment of those that pass by securely, as men returning from war.
Láìpẹ́ àwọn ènìyàn mi dìde bí ọ̀tá sí mi. Ìwọ bọ́ aṣọ ọlọ́rọ̀ kúrò lára àwọn tí ń kọjá lọ ní àìléwu, bí àwọn ẹni tí ó padà bọ̀ láti ojú ogun.
9 The women of my people ye cast out from their pleasant abodes; Ye deprive their children forever of the glory which I gave them.
Ẹ̀yin sì lé obìnrin àwọn ènìyàn mi kúrò nínú ilé ayọ̀ wọn, ẹ̀yin sì ti gba ògo mi, kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ wọn láéláé.
10 Arise and depart; This land is not your rest! On account of its pollution shall it be wasted, And given to utter destruction.
Ẹ dìde, kí ẹ sì máa lọ! Nítorí èyí kì í ṣe ibi ìsinmi yín, nítorí tí a ti sọ ọ́ di àìmọ́ yóò pa yín run, àní ìparun kíkorò.
11 If a man follow wind, and invent falsehood, and say, “I will prophesy to thee of wine and strong drink!” He will be the prophet for this people.
Tí òpùrọ́ àti ẹlẹ́tàn bá wà tí wọ́n sì wí pé, ‘Èmi yóò sọtẹ́lẹ̀ fún ọ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ wáìnì àti ọtí líle,’ òun ni yóò tilẹ̀ ṣe wòlíì àwọn ènìyàn wọ̀nyí!
12 Yet will I fully gather thee, O Jacob, I will surely assemble the residue of Israel! I will put them together like sheep in a fold; Like a flock in their fold shall they be in a tumult on account of the multitude of men.
“Èmi yóò kó gbogbo yín jọ, ìwọ Jakọbu; Èmi yóò gbá ìyókù Israẹli jọ. Èmi yóò kó wọn jọ pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú agbo ẹran, gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nínú agbo wọn, ibẹ̀ yóò sì pariwo nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn.
13 He that forceth a way goeth before them; They force their way, and pass through the gate, And go forth by it; And their king goeth before them, Even Jehovah at the head of them.
Ẹni tí ó ń fọ ọ̀nà yóò lọ sókè níwájú wọn; wọn yóò fọ láti ẹnu ibodè, wọn yóò sì jáde lọ. Àwọn ọba wọn yóò sì kọjá lọ níwájú wọn, Olúwa ni yóò sì ṣe olórí wọn.”

< Micah 2 >