< Job 8 >

1 Then answered Bildad the Shuhite, and said:
Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, sì dáhùn wí pé,
2 How long wilt thou speak such things? How long shall the words of thy mouth be like a strong wind?
“Ìwọ yóò ti máa sọ nǹkan wọ̀nyí pẹ́ tó? Tí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ yóò sì máa bí ẹ̀fúùfù ńlá?
3 Will God pervert judgment? Or will the Almighty pervert justice?
Ọlọ́run a ha máa yí ìdájọ́ po bí? Tàbí Olódùmarè a máa gbé ẹ̀bi fún aláre?
4 As thy children sinned against him, He hath given them up to their transgression.
Nígbà tí àwọn ọmọ rẹ̀ ṣẹ̀ sí i, ó sì gbá wọn kúrò nítorí ìrékọjá wọn.
5 But if thou wilt seek early to God, And make thy supplication to the Almighty, —
Bí ìwọ bá sì ké pe Ọlọ́run ní àkókò, tí ìwọ sì gbàdúrà ẹ̀bẹ̀ sí Olódùmarè.
6 If thou wilt be pure and upright, Surely he will yet arise for thee, And prosper thy righteous habitation;
Ìwọ ìbá jẹ́ mímọ, kí ó sì dúró ṣinṣin: ǹjẹ́ nítòótọ́ nísinsin yìí òun yóò tají fún ọ, òun a sì sọ ibùjókòó òdodo rẹ di púpọ̀.
7 So that thy beginning shall be small, And thy latter end very great.
Ìpilẹ̀ṣẹ̀ rẹ ìbá tilẹ̀ kéré si í, bẹ́ẹ̀ ìgbẹ̀yìn rẹ ìbá pọ̀ sí i gidigidi.
8 For inquire, I pray thee, of the former age, And mark what hath been searched out by their fathers;
“Èmi bẹ̀ ọ́ ǹjẹ́, béèrè lọ́wọ́ àwọn ará ìgbà nì kí o sì kíyèsi ìwádìí àwọn baba wọn.
9 (For we are of yesterday and know nothing, Since our days upon the earth are but a shadow; )
Nítorí pé ọmọ-àná ni àwa, a kò sì mọ nǹkan, nítorí pé òjìji ni ọjọ́ wa ni ayé.
10 Will not they instruct thee, and tell thee, And utter words from their understanding?
Àwọn kì yóò wa kọ ọ́, wọn kì yóò sì sọ fún ọ? Wọn kì yóò sì sọ̀rọ̀ láti inú òye wọn jáde wá?
11 “Can the paper-reed grow up without mire? Can the bulrush grow without water?
Papirusi ha lè dàgbà láìní ẹrẹ̀ tàbí eèsún ha lè dàgbà láìlómi?
12 While it is yet in its greenness, and is not cut down, It withereth before any other herb.
Nígbà tí ó wà ní tútù, tí a kò ké e lulẹ̀, ó rọ dànù, ewéko gbogbo mìíràn hù dípò rẹ̀.
13 Such is the fate of all who forget God; So perisheth the hope of the ungodly.
Bẹ́ẹ̀ ni ipa ọ̀nà gbogbo àwọn tí ó gbàgbé Ọlọ́run, bẹ́ẹ̀ ni ìrètí àwọn àgàbàgebè yóò di òfo.
14 His confidence shall come to nought, And his trust shall prove a spider's web.
Àbá ẹni tí a ó kèé kúrò, àti ìgbẹ́kẹ̀lé ẹni tí ó dàbí ilé aláǹtakùn.
15 He shall lean upon his house, and it shall not stand; He shall lay fast hold on it, but it shall not endure.
Yóò fi ara ti ilé rẹ̀, ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró, yóò fi di ara rẹ̀ mú ṣinṣin ṣùgbọ́n kì yóò lè dúró pẹ́.
16 He is in full green before the sun, And his branches shoot forth over his garden;
Ó tutù bí irúgbìn tí a bomirin níwájú oòrùn, ẹ̀ka rẹ̀ sì yọ jáde nínú ọgbà rẹ̀.
17 His roots are entwined about the heap, And he seeth the place of stones;
Gbòǹgbò rẹ̀ ta yí ebè ká, ó sì wó ibi òkúta wọ̀n-ọn-nì.
18 When he shall be destroyed from his place, It shall deny him, saying, 'I never saw thee.'
Bí ó bá sì pa á run kúrò ní ipò rẹ̀, nígbà náà ni ipò náà yóò sọ, ‘Èmi kò ri ọ rí!’
19 Lo! such is the joy of his course! And others shall spring up from his place”
Kíyèsi i, ayé rẹ̀ gbẹ dànù àti láti inú ilẹ̀ ní irúgbìn òmíràn yóò hù jáde wá.
20 Behold, God will not cast away an upright man; Nor will he help the evil-doers.
“Kíyèsi i, Ọlọ́run kì yóò ta ẹni òtítọ́ nù, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ran oníwà búburú lọ́wọ́
21 While he filleth thy mouth with laughter, And thy lips with gladness,
títí yóò fi fi ẹ̀rín kún ọ ní ẹnu, àti ètè rẹ pẹ̀lú ìhó ayọ̀,
22 They that hate thee shall be clothed with shame, And the dwelling-place of the wicked shall come to nought.
ìtìjú ní a o fi bo àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, àti ibùjókòó ènìyàn búburú kì yóò sí mọ́.”

< Job 8 >