< Job 28 >
1 Truly there is a vein for silver, And a place for gold, which men refine.
Nítòótọ́, koto fàdákà ń bẹ, àti ibi tí wọ́n ti máa ń da wúrà.
2 Iron is obtained from earth, And stone is melted into copper.
Nínú ilẹ̀ ni à ń gbé ń wa irin, bàbà ni a sì ń dà láti inú òkúta wá.
3 Man putteth an end to darkness; He searcheth to the lowest depths For the stone of darkness and the shadow of death.
Ènìyàn ni ó fi òpin si òkùnkùn, ó sì ṣe àwárí ìṣúra láti inú òjìji ikú sí ìhà gbogbo.
4 From the place where they dwell they open a shaft; Forgotten by the feet, They hang down, they swing away from men.
Wọ́n wa ihò ilẹ̀ tí ó jì sí àwọn tí ń gbé òkè, àwọn tí ẹsẹ̀ ènìyàn gbàgbé wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀, wọ́n rọ́ sí ìsàlẹ̀ jìnnà sí àwọn ènìyàn.
5 The earth, out of which cometh bread, Is torn up underneath, as it were by fire.
Bí ó ṣe ti ilẹ̀ ni, nínú rẹ̀ ni oúnjẹ ti ń jáde wá, àti ohun tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni ó yí padà bi iná;
6 Her stones are the place of sapphires, And she hath clods of gold for man.
òkúta ibẹ̀ ni ibi òkúta safire, o sì ní erùpẹ̀ wúrà.
7 The path thereto no bird knoweth, And the vulture's eye hath not seen it;
Ipa ọ̀nà náà ni ẹyẹ kò mọ̀, àti ojú gúnnugún kò rí i rí.
8 The fierce wild beast hath not trodden it; The lion hath not passed over it.
Àwọn ẹranko agbéraga kò rìn ibẹ̀ rí, bẹ́ẹ̀ ni kìnnìún tí ń ké ramúramù kò kọjá níbẹ̀ rí.
9 Man layeth his hand upon the rock; He upturneth mountains from their roots;
Ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé akọ òkúta, ó yí òkè ńlá po láti ìdí rẹ̀ wá.
10 He cleaveth out streams in the rocks, And his eye seeth every precious thing;
Ó sì la ipa odò ṣíṣàn nínú àpáta, ojú inú rẹ̀ sì rí ohun iyebíye gbogbo.
11 He bindeth up the streams, that they trickle not, And bringeth hidden things to light.
Ó sì ṣe ìṣàn odò kí ó má ṣe kún àkúnya, ó sì mú ohun tí ó pamọ́ hàn jáde wá sí ìmọ́lẹ̀.
12 But where shall wisdom be found? And where is the place of understanding?
Ṣùgbọ́n níbo ni á ó gbé wá ọgbọ́n rí, níbo sì ni òye ń gbe?
13 Man knoweth not the price thereof, Nor can it be found in the land of the living.
Ènìyàn kò mọ iye rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è rí i ní ilẹ̀ àwọn alààyè.
14 The deep saith, It is not in me; And the sea saith, It is not with me.
Ọ̀gbun wí pé, “Kò sí nínú mi”; omi òkun sì wí pé, “Kò si nínú mi.”
15 It cannot be gotten for gold, Nor shall silver be weighed out as the price thereof.
A kò le è fi wúrà rà á, bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi òsùwọ̀n wọn fàdákà ní iye rẹ̀.
16 It cannot be bought with the gold of Ophir, With the precious onyx or the sapphire.
A kò le è fi wúrà Ofiri, tàbí òkúta óníkìsì iyebíye, tàbí òkúta safire díye lé e.
17 Gold and crystal are not to be compared with it; Nor can it be purchased with jewels of fine gold.
Wúrà àti òkúta kristali kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le è fi ohun èlò wúrà ṣe pàṣípàrọ̀ rẹ̀.
18 No mention shall be made of coral or of crystal; For wisdom is more precious than pearls.
A kò lè dárúkọ iyùn tàbí òkúta jasperi; iye ọgbọ́n sì ju iyùn lọ.
19 The topaz of Ethiopia cannot equal it, Nor can it be purchased with pure gold.
Òkúta topasi ti Kuṣi kò tó ẹgbẹ́ rẹ̀; bẹ́ẹ̀ ni a kò le fi wúrà dáradára díwọ̀n iye rẹ̀.
20 Whence then cometh wisdom? And where is the place of understanding?
Níbo ha ni ọgbọ́n ti jáde wá? Tàbí níbo ni òye ń gbé?
21 Since it is hidden from the eyes of all living, And kept close from the fowls of the air.
A rí i pé, ó fi ara sinko kúrò ní ojú àwọn alààyè gbogbo, ó sì fi ara sin fún ẹyẹ ojú ọ̀run.
22 Destruction and Death say, We have heard a rumor of it with our ears.
Ibi ìparun àti ikú wí pé, àwa ti fi etí wa gbúròó rẹ̀.
23 God knoweth the way to it; He knoweth its dwelling-place.
Ọlọ́run ni ó mọ òye ipa ọ̀nà rẹ̀, òun ni ó sì mọ ibi tí ó ń gbé.
24 For he seeth to the ends of the earth, And surveyeth all things under the whole heaven.
Nítorí pé ó wòye dé òpin ayé, ó sì rí gbogbo ìsàlẹ̀ ọ̀run,
25 When he gave the winds their weight, And meted out the waters by measure;
láti dà òsùwọ̀n fún afẹ́fẹ́, ó sì fi òsùwọ̀n wọ́n omi.
26 When he prescribed a law to the rain, And a path to the thunder-flash, —
Nígbà tí ó pàṣẹ fún òjò, tí ó sì la ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
27 Then did he see it, and make it known; He established it, and searched it out.
nígbà náà ni ó rí i, ó sì sọ ọ́ jáde; ó pèsè rẹ̀ sílẹ̀, ó sì ṣe ìwádìí rẹ̀ rí.
28 But he said unto man, Behold, the fear of the Lord, that is wisdom, And to depart from evil is understanding.
Àti fún ènìyàn ni ó wí pé, “Kíyèsi i, ẹ̀rù Olúwa èyí ni ọgbọ́n, àti láti jáde kúrò nínú ìwà búburú èyí ni òye.”