< Psalms 129 >

1 [A Song of Ascents.] Many times they have afflicted me from my youth up. Let Israel now say,
Orin fún ìgòkè. “Ìgbà púpọ̀ ni wọ́n ti pọ́n mi lójú láti ìgbà èwe mi wá,” jẹ́ kí Israẹli kí ó wí nísinsin yìí;
2 many times they have afflicted me from my youth up, yet they have not prevailed against me.
“Ìgbà púpọ̀ ni wọ́n ti pọ́n mi lójú láti ìgbà èwe mi wá; síbẹ̀ wọn kò tí ì borí mi.
3 The plowers plowed on my back. They made their furrows long.
Àwọn awalẹ̀ walẹ̀ sí ẹ̀yìn mi: wọ́n sì la aporo wọn gígùn.
4 Jehovah is righteous. He has cut apart the cords of the wicked.
Olódodo ni Olúwa: ó ti ké okùn àwọn ènìyàn búburú kúrò.”
5 Let them be disappointed and turned backward, all those who hate Zion.
Kí gbogbo àwọn tí ó kórìíra Sioni kí ó dààmú, kí wọn kí ó sì yí ẹ̀yìn padà.
6 Let them be as the grass on the housetops, which withers before it grows up;
Kí wọn kí ó dàbí koríko orí ilẹ̀ tí ó gbẹ dànù kí ó tó dàgbàsókè,
7 with which the reaper doesn't fill his hand, nor he who binds sheaves, his bosom.
èyí tí olóko pípa kó kún ọwọ́ rẹ̀: bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ń di ìtí, kó kún apá rẹ̀.
8 Neither do those who go by say, "The blessing of Jehovah be on you. We bless you in the name of Jehovah."
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ń kọjá lọ kò wí pé, ìbùkún Olúwa kí ó pẹ̀lú yín: àwa ń súre fún yin ní orúkọ Olúwa.

< Psalms 129 >