< Numbers 2 >

1 Jehovah spoke to Moses and to Aaron, saying,
Olúwa sọ fún Mose àti Aaroni pé,
2 "The children of Israel shall camp every man by his own standard, with the banners of their fathers' houses: at a distance from the Tent of Meeting shall they camp around it."
“Kí àwọn ọmọ Israẹli pa àgọ́ wọn yí àgọ́ ìpàdé ká, kí wọ́n jẹ́ kí àgọ́ wọn jìnnà sí i díẹ̀, oníkálùkù lábẹ́ ọ̀págun pẹ̀lú àsíá ìdílé wọn.”
3 Those who camp on the east side toward the sunrise shall be of the standard of the camp of Judah, according to their divisions: and the prince of the people of Judah shall be Nahshon the son of Amminadab.
Ní ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ àtiyọ oòrùn: ni kí ìpín ti Juda pa ibùdó wọn sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Juda ni Nahiṣoni ọmọ Amminadabu.
4 His division, and those who were numbered of them, were seventy-four thousand six hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlógójì ó lé ẹgbẹ̀ta.
5 Those who camp next to him shall be the tribe of Issachar: and the prince of the people of Issachar shall be Nethanel the son of Zuar.
Ẹ̀yà Isakari ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Isakari ni Netaneli ọmọ Suari.
6 His division, and those who were numbered of it, were fifty-four thousand four hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàdínlọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
7 The tribe of Zebulun: and the prince of the people of Zebulun shall be Eliab the son of Helon.
Ẹ̀yà Sebuluni ni yóò tẹ̀lé e. Olórí Sebuluni ni Eliabu ọmọ Heloni.
8 His division, and those who were numbered of it, were fifty-seven thousand four hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
9 All who were numbered of the camp of Judah were one hundred eighty-six thousand four hundred, according to their divisions. They shall set out first.
Gbogbo àwọn tí a yàn sí ibùdó Juda, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàléláàdọ́rùn-ún ó lé irinwó. Àwọn ni yóò kọ́kọ́ ṣáájú.
10 "On the south side shall be the standard of the camp of Reuben according to their divisions. The prince of the people of Reuben shall be Elizur the son of Shedeur.
Ní ìhà gúúsù: ni ìpín ti Reubeni pa ibùdó sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Reubeni ni Elisuri ọmọ Ṣedeuri.
11 His division, and those who were numbered of it, were forty-six thousand five hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́tàlélógún ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
12 "Those who camp next to him shall be the tribe of Simeon. The prince of the people of Simeon shall be Shelumiel the son of Zurishaddai.
Ẹ̀yà Simeoni ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Simoni ni Ṣelumieli ọmọ Suriṣaddai.
13 His division, and those who were numbered of them, were fifty-nine thousand three hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mọ́kàndínlọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbéje.
14 "The tribe of Gad: and the prince of the people of Gad shall be Eliasaph the son of Reuel.
Ẹ̀yà Gadi ló tẹ̀lé wọn. Olórí Gadi ni Eliasafu ọmọ Deueli.
15 His division, and those who were numbered of them, were forty-five thousand six hundred fifty.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé àádọ́talélẹ́gbẹ̀jọ.
16 "All who were numbered of the camp of Reuben were one hundred fifty-one thousand four hundred fifty, according to their armies. They shall set out second.
Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Reubeni, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá márùndínlọ́gọ́rin ó lé àádọ́talélégbèje. Àwọn ni yóò jáde sìkéjì.
17 "Then the Tent of Meeting shall set out, with the camp of the Levites in the midst of the camps. As they camp, so shall they set out, every man in his place, by their standards.
Nígbà náà ni àwọn ọmọ Lefi àti àgọ́ ìpàdé yóò tẹ̀síwájú láàrín ibùdó àwọn ènìyàn, wọn yóò tẹ̀síwájú ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé gẹ́gẹ́ bí wọn ṣe pa ibùdó, olúkúlùkù láààyè rẹ̀, àti lábẹ́ ọ̀págun rẹ̀.
18 "On the west side shall be the standard of the camp of Ephraim according to their divisions: and the prince of the people of Ephraim shall be Elishama the son of Ammihud.
Ní ìhà ìlà-oòrùn: ni ìpín Efraimu yóò pa ibùdó rẹ̀ sí lábẹ́ ọ̀págun rẹ̀. Olórí Efraimu ni Eliṣama ọmọ Ammihudu.
19 His division, and those who were numbered of them, were forty thousand five hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì lé ó lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
20 "Next to him shall be the tribe of Manasseh: and the prince of the people of Manasseh shall be Gamaliel the son of Pedahzur.
Ẹ̀yà Manase ni yóò tẹ̀lé wọn. Olórí Manase ni Gamalieli ọmọ Pedasuri.
21 His division, and those who were numbered of them, were thirty-two thousand two hundred.
Iye ìpín rẹ̀ ni ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé igba.
22 "The tribe of Benjamin: and the prince of the people of Benjamin shall be Abidan the son of Gideoni.
Ẹ̀yà Benjamini ni yóò tẹ̀lé e. Olórí Benjamini ni Abidani ọmọ Gideoni.
23 His army, and those who were numbered of them, were thirty-five thousand four hundred.
Iye ìpín rẹ̀ ni ẹgbàá mẹ́tàdínlógún ó lé egbèje.
24 "All who were numbered of the camp of Ephraim were one hundred eight thousand one hundred, according to their divisions. They shall set out third.
Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Efraimu, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, àpapọ̀ iye wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìnléláàádọ́ta ó lé ọgọ́rùn-ún. Àwọn ni yóò jáde sìkẹ́ta.
25 "On the north side shall be the standard of the camp of Dan according to their divisions: and the prince of the people of Dan shall be Ahiezer the son of Ammishaddai.
Ní ìhà àríwá: ni ìpín Dani yóò pa ibùdó sí lábẹ́ ọ̀págun wọn. Olórí Dani ni Ahieseri ọmọ Ammiṣaddai.
26 His division, and those who were numbered of them, were sixty-two thousand seven hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélọ́gbọ̀n ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
27 "Those who camp next to him shall be the tribe of Asher: and the prince of the people of Asher shall be Pagiel the son of Ochran.
Ẹ̀yà Aṣeri ni yóò pa ibùdó tẹ̀lé wọn. Olórí Aṣeri ni Pagieli ọmọ Okanri.
28 His division, and those who were numbered of them, were forty-one thousand and five hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀jọ.
29 "The tribe of Naphtali: and the prince of the people of Naphtali shall be Ahira the son of Enan.
Ẹ̀yà Naftali ni yóò kàn lẹ́yìn wọn. Olórí Naftali ni Ahira ọmọ Enani.
30 His division, and those who were numbered of them, were fifty-three thousand four hundred.
Iye ìpín rẹ̀ jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé egbèje.
31 "All who were numbered of the camp of Dan were one hundred fifty-seven thousand six hundred. They shall set out last by their standards."
Gbogbo ènìyàn tí a yàn sí ibùdó Dani jẹ́ ẹgbàá méjìdínlọ́gọ̀rin ó lé ẹgbẹ̀jọ. Àwọn ni yóò jáde kẹ́yìn lábẹ́ ọ̀págun wọn.
32 These are those who were numbered of the children of Israel by their fathers' houses. All who were numbered of the camps according to their armies were six hundred three thousand five hundred fifty.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n kà nípa ìdílé wọn. Gbogbo àwọn tó wà ní ibùdó, gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn, wọ́n jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé egbèjìdínlógún dín làádọ́ta.
33 But the Levites were not numbered among the children of Israel; as Jehovah commanded Moses.
Ṣùgbọ́n a kò ka àwọn ọmọ Lefi papọ̀ mọ́ àwọn Israẹli gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún Mose.
34 Thus the children of Israel did. According to all that Jehovah commanded Moses, so they camped by their standards, and so they set out, everyone by their families, according to their fathers' houses.
Àwọn ọmọ Israẹli ṣe gbogbo ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mose, báyìí ni wọ́n ṣe pa ibùdó lábẹ́ ọ̀págun wọn, bẹ́ẹ̀ náà sì ni wọ́n ṣe jáde, oníkálùkù pẹ̀lú ẹbí àti ìdílé rẹ̀.

< Numbers 2 >