< Psalms 29 >

1 [A Psalm by David.] Ascribe to the LORD, you sons of the mighty, ascribe to the LORD glory and strength.
Saamu ti Dafidi. Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.
2 Ascribe to the LORD the glory due to his name. Worship the LORD in holy array.
Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀; sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.
3 The voice of the LORD is on the waters. The God of glory thunders, even the LORD on many waters.
Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, Olúwa san ara.
4 The voice of the LORD is powerful. The voice of the LORD is full of majesty.
Ohùn Olúwa ní agbára; ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
5 The voice of the LORD breaks the cedars. Yes, the LORD breaks in pieces the cedars of Lebanon.
Ohùn Olúwa fa igi kedari; Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
6 He makes them also to skip like a calf; Lebanon and Sirion like a young, wild ox.
Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù, àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
7 The voice of the LORD strikes with flashes of lightning.
Ohùn Olúwa ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà.
8 The voice of the LORD shakes the wilderness. The LORD shakes the wilderness of Kadesh.
Ohùn Olúwa ń mi aginjù. Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
9 The voice of the LORD makes the large trees tremble, and strips the forests bare. In his temple everything says, "Glory."
Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí, ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò. Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!”
10 The LORD sat enthroned at the Flood. Yes, the LORD sits as King forever.
Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi; Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
11 The LORD will give strength to his people. The LORD will bless his people with peace.
Kí Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀; bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.

< Psalms 29 >