< Psalms 126 >

1 [A Song of Ascents.] When the LORD brought back those who returned to Zion, we were like those who dream.
Orin fún ìgòkè. Nígbà tí Olúwa mú ìkólọ Sioni padà, àwa dàbí ẹni tí ó ń lá àlá.
2 Then our mouth was filled with laughter, and our tongue with singing. Then they said among the nations, "The LORD has done great things for them."
Nígbà náà ni ẹnu wa kún fún ẹ̀rín, àti ahọ́n wa kọ orin; nígbà náà ni wọ́n wí nínú àwọn kèfèrí pé, Olúwa ṣe ohun ńlá fún wọn.
3 The LORD has done great things for us, and we are glad.
Olúwa ṣe ohun ńlá fún wa; nítorí náà àwa ń yọ̀.
4 Restore our fortunes again, LORD, like the streams in the Negev.
Olúwa mú ìkólọ wa padà, bí ìṣàn omi ní gúúsù.
5 Those who sow in tears will reap in joy.
Àwọn tí ń fi omijé fún irúgbìn yóò fi ayọ̀ ka.
6 He who goes out weeping, carrying seed for sowing, will certainly come again with joy, carrying his sheaves.
Ẹni tí ń fi ẹkún rìn lọ, tí ó sì gbé irúgbìn lọ́wọ́, lóòtítọ́, yóò fi ayọ̀ padà wá, yóò sì ru ìtí rẹ̀.

< Psalms 126 >