< Numbers 34 >

1 The LORD spoke to Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 "Command the children of Israel, and tell them, 'When you come into the land of Canaan (this is the land that shall fall to you for an inheritance, even the land of Canaan according to its borders),
“Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Tí ẹ bá wọ Kenaani, ilẹ̀ tí a ó fi fún yín, gẹ́gẹ́ bí ogún yín yóò ní ààlà wọn yí:
3 then your south quarter shall be from the wilderness of Zin along by the side of Edom, and your south border shall be from the end of the Salt Sea eastward;
“‘Ìhà gúúsù yín yóò bọ́ sí ara aginjù Sini lẹ́bàá Edomu, àti ìlà-oòrùn, ààlà ìhà gúúsù yóò bẹ̀rẹ̀ láti òpin Òkun Iyọ̀,
4 and your border shall turn about southward of the ascent of Akrabbim, and pass along to Zin; and the goings out of it shall be southward of Kadesh Barnea; and it shall go forth to Hazar Addar, and pass along to Azmon;
kọjá lọ sí gúúsù Akrabbimu, tẹ̀síwájú lọ si Sini, kó bọ́ si gúúsù Kadeṣi-Barnea, kí o sì dé Hasari-Addari, kí o sì kọjá sí Asmoni.
5 and the border shall turn about from Azmon to the Wadi of Egypt, and the goings out of it shall be at the sea.
Kí òpin ilẹ̀ rẹ̀ kí ó sì yíká láti Asmoni lọ dé odò Ejibiti, Òkun Ńlá ni yóò sì jẹ òpin rẹ.
6 "'For the western border, the Great Sea shall be a border to you; this shall be your west border.
Ìhà ìwọ̀-oòrùn yín yóò jẹ́ òpin lórí Òkun Ńlá. Èyí yóò jẹ́ ààlà yín lórí ìhà ìwọ̀-oòrùn.
7 "'This shall be your north border: from the Great Sea you shall mark out for you Mount Hor;
Fún ààlà ìhà àríwá, fa ìlà láti Òkun Ńlá lọ sí orí òkè Hori,
8 from Mount Hor you shall mark out to Lebo Hamath; and the goings out of the border shall be at Zedad;
àti láti orí òkè Hori sí Lebo-Hamati. Nígbà náà ààlà náà yóò lọ sí Sedadi,
9 and the border shall go forth to Ziphron, and the goings out of it shall be at Hazar Enan: this shall be your north border.
tẹ̀síwájú lọ sí Sifroni, kí o sì fò pín si ní Hasari-Enani, èyí yóò jẹ́ ààlà tìrẹ ní ìhà àríwá.
10 "'You shall mark out your east border from Hazar Enan to Shepham;
Kí ẹ sì sàmì sí ilẹ̀ tiyín ní ìhà ìlà-oòrùn láti Hasari-Enani lọ dé Ṣefamu.
11 and the border shall go down from Shepham to Riblah, on the east side of Ain; and the border shall go down, and shall reach to the side of the sea of Kinnereth eastward;
Ààlà náà yóò ti Ṣefamu sọ̀kalẹ̀ wá lọ sí Ribla ní ìhà ìlà-oòrùn Aini, kí o sì sọ̀kalẹ̀ lọ dé ìhà Òkun Kinnereti ní ìhà ìlà-oòrùn.
12 and the border shall go down to the Jordan, and the goings out of it shall be at the Salt Sea. This shall be your land according to its borders around it.'"
Nígbà náà, ààlà náà yóò sọ̀kalẹ̀ lọ sí apá Jordani, yóò sì dópin nínú Òkun Iyọ̀. “‘Èyí yóò jẹ́ ilẹ̀ yín, pẹ̀lú ààlà tirẹ̀ ní gbogbo ọ̀nà.’”
13 Moses commanded the children of Israel, saying, "This is the land which you shall inherit by lot, which the LORD has commanded to give to the nine tribes, and to the half-tribe;
Mose pa á láṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Yan ilẹ̀ yìí pẹ̀lú kèké gẹ́gẹ́ bí ìní ogún: Olúwa ti pàṣẹ láti fi fún ẹ̀yà mẹ́sàn-án, àti ààbọ̀.
14 for the tribe of the people of Reuben according to their fathers' houses, and the tribe of the people of Gad according to their fathers' houses, have received, and the half-tribe of Manasseh have received, their inheritance:
Nítorí ará ilẹ̀ ẹ̀yà ti Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ẹ̀yà ààbọ̀ ti Manase ti gba ogún tiwọn.
15 the two tribes and the half-tribe have received their inheritance beyond the Jordan at Jericho eastward, toward the sunrise."
Ẹ̀yà méjèèjì àti ààbọ̀ yìí ti gba ogún tiwọn ní ìhà ìhín Jordani létí i Jeriko, ní ìhà ìlà-oòrùn, ní ìdojúkọ Jordani.”
16 The LORD spoke to Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
17 "These are the names of the men who shall divide the land to you for inheritance: Eleazar the priest, and Joshua the son of Nun.
“Èyí ni orúkọ àwọn ọkùnrin náà tí yóò pín ilẹ̀, náà fún yín gẹ́gẹ́ bí ogún: Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni.
18 You shall take one prince of every tribe, to divide the land for inheritance.
Kí o sì yan olórí kan nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan láti pín ilẹ̀ náà.
19 These are the names of the men: Of the tribe of Judah, Caleb the son of Jephunneh.
“Èyí ni orúkọ wọn: “Kalebu ọmọ Jefunne, láti ẹ̀yà Juda;
20 Of the tribe of the people of Simeon, Shemuel the son of Ammihud.
Ṣemueli ọmọ Ammihudu, láti ẹ̀yà Simeoni;
21 Of the tribe of Benjamin, Elidad the son of Chislon.
Elidadi ọmọ Kisloni, láti ẹ̀yà Benjamini;
22 Of the tribe of the people of Dan a prince, Bukki the son of Jogli.
Bukki ọmọ Jogli, láti ẹ̀yà olórí àwọn ọmọ Dani;
23 Of the people of Joseph: of the tribe of the people of Manasseh a prince, Hanniel the son of Ephod.
Hannieli ọmọ Efodu, láti ẹ̀yà Manase, olórí àwọn ọmọ Josẹfu,
24 Of the tribe of the people of Ephraim a prince, Kemuel the son of Shiphtan.
Kemueli ọmọ Ṣiftani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ, Efraimu, ọmọ Josẹfu;
25 Of the tribe of the people of Zebulun a prince, Elizaphan the son of Parnach.
Elisafani ọmọ Parnaki, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Sebuluni;
26 Of the tribe of the people of Issachar a prince, Paltiel the son of Azzan.
Paltieli ọmọ Assani, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Isakari;
27 Of the tribe of the people of Asher a prince, Ahihud the son of Shelomi.
Ahihudu ọmọ Ṣelomi, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Aṣeri;
28 Of the tribe of the people of Naphtali a prince, Pedahel the son of Ammihud."
Pedaheli ọmọ Ammihudu, olórí ẹ̀yà àwọn ọmọ Naftali.”
29 These are they whom the LORD commanded to divide the inheritance to the children of Israel in the land of Canaan.
Èyí ni àwọn ẹni tí Olúwa yàn láti pín ogún náà fún àwọn ọmọ Israẹli ní ilẹ̀ Kenaani.

< Numbers 34 >