< Numbers 26 >

1 It happened after the plague, that the LORD spoke to Moses and to Eleazar the son of Aaron the priest, saying,
Lẹ́yìn àjàkálẹ̀-ààrùn Olúwa sọ fún Mose àti Eleasari ọmọ Aaroni, àlùfáà pé,
2 "Take a census of all the congregation of the children of Israel, from twenty years old and upward, by their fathers' houses, all who are able to go forth to war in Israel."
“Ka iye gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọ́n; láti ẹni ogun ọdún àti jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó lè jà lójú ogun ní Israẹli.”
3 Moses and Eleazar the priest spoke with them in the plains of Moab by the Jordan at Jericho, saying,
Lórí pẹ̀tẹ́lẹ̀ ti Moabu pẹ̀lú Jordani tí ó kọjá Jeriko, Mose àti Eleasari àlùfáà sọ̀rọ̀ pẹ̀lú wọn ó wí pé,
4 "Take a census, from twenty years old and upward; as the LORD commanded Moses and the children of Israel." These are those that came out of the land of Egypt.
“Ka iye àwọn ọkùnrin tí ó jẹ́ ọmọ-ogun ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.” Èyí ni àwọn ọmọ Israẹli tí ó jáde láti Ejibiti wá.
5 Reuben, the firstborn of Israel; the descendants of Reuben: of Hanoch, the family of the Hanochites; of Pallu, the family of the Palluites;
Àwọn ọmọ Reubeni, àkọ́bí ọmọkùnrin Israẹli, láti ẹni ti ìdílé Hanoku, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ìdílé Hanoku ti jáde wá, láti ìdílé Pallu, láti ọ̀dọ̀ ẹni tí ìdílé àwọn ọmọ Pallu ti jáde wá;
6 of Hezron, the family of the Hezronites; of Carmi, the family of the Carmites.
ti Hesroni, ìdílé àwọn ọmọ Hesroni; ti Karmi, ìdílé àwọn ọmọ Karmi.
7 These are the families of the Reubenites; and those who were numbered of them were forty-three thousand seven hundred thirty.
Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Reubeni; àwọn tí a sì kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé lẹ́gbẹ̀sán ó dín àádọ́rin.
8 The sons of Pallu: Eliab.
Àwọn ọmọkùnrin Pallu ni Eliabu,
9 The sons of Eliab: Nemuel, and Dathan, and Abiram. These are that Dathan and Abiram, who were called of the congregation, who strove against Moses and against Aaron in the company of Korah, when they strove against the LORD,
àwọn ọmọkùnrin Elifelehu ni Nemueli àti Eliabu, Datani àti Abiramu. Èyí ni Datani àti Abiramu náà tí wọ́n ní òkìkí nínú ìjọ tí ó jẹ́ ọlọ̀tẹ̀ sí Mose àti Aaroni tí ó sì wà lára àwọn ẹgbẹ́ Kora nígbà tí wọ́n bá Olúwa jà.
10 and the earth opened its mouth, and swallowed them up together with Korah, when that company died; what time the fire devoured two hundred fifty men, and they became a sign.
Ilẹ̀ sì la ẹnu rẹ̀, ó sì gbé wọn mì pọ̀ pẹ̀lú Kora, nígbà tí ẹgbẹ́ rẹ̀ kú níbi tí iná ti run àwọn àádọ́ta lé nígba ọkùnrin. Tí wọ́n sì di àmì ìkìlọ̀.
11 Notwithstanding, the sons of Korah did not die.
Àwọn ọmọ Kora, bí ó ti wù kí ó rí, wọn kò kú.
12 The descendants of Simeon after their families: of Jemuel, the family of the Jemuelites; of Jamin, the family of the Jaminites; of Jakin, the family of the Jakinites;
Àwọn ọmọ ìran Simeoni bí ìdílé wọn: ti Nemueli, ìdílé Nemueli; ti Jamini, ìdílé Jamini; ti Jakini, ìdílé Jakini;
13 of Zohar, the family of the Zoharites; of Shaul, the family of the Shaulites.
ti Sera, ìdílé Sera; tí Saulu, ìdílé Saulu.
14 These are the families of the Simeonites, twenty-two thousand two hundred.
Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Simeoni, ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé igba ọkùnrin.
15 The descendants of Gad after their families: of Zephon, the family of the Zephonites; of Haggi, the family of the Haggites; of Shuni, the family of the Shunites;
Àwọn ọmọ Gadi bí ìdílé wọn: ti Sefoni, ìdílé Sefoni; ti Haggi, ìdílé Haggi; ti Ṣuni, ìdílé Ṣuni;
16 of Ezbon, the family of the Ezbonites; of Eri, the family of the Erites;
ti Osni, ìdílé Osni; ti Eri, ìdílé Eri;
17 of Arodi, the family of the Arodites; of Areli, the family of the Arelites.
ti Arodi, ìdílé Arodi; ti Areli, ìdílé Areli.
18 These are the families of the sons of Gad according to those who were numbered of them, forty thousand and five hundred.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gadi tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
19 The sons of Judah: Er and Onan; and Er and Onan died in the land of Canaan.
Àwọn ọmọ Juda ni Eri àti Onani, ṣùgbọ́n Eri àti Onani kú ní ilẹ̀ Kenaani.
20 The descendants of Judah after their families were: of Shelah, the family of the Shelanites; of Perez, the family of the Perezites; of Zerah, the family of the Zerahites.
Àti àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Ṣela, ìdílé Ṣela; ti Peresi, ìdílé Peresi; ti Sera, ìdílé Sera.
21 The sons of Perez were: of Hezron, the family of the Hezronites; of Hamuel, the family of the Hamuelites.
Àwọn ọmọ Peresi: ti Hesroni, ìdílé Hesroni; ti Hamulu, ìdílé Hamulu.
22 These are the families of Judah according to those who were numbered of them, seventy-six thousand five hundred.
Wọ̀nyí ni ìdílé Juda; gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá méjìdínlógójì ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
23 The descendants of Issachar after their families: of Tola, the family of the Tolaites; of Puah, the family of the Puites;
Àwọn ọmọ Isakari gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Tola, ìdílé Tola; ti Pufa, ìdílé Pufa;
24 of Jashub, the family of the Jashubites; of Shimron, the family of the Shimronites.
ti Jaṣubu, ìdílé Jaṣubu; ti Ṣimroni, ìdílé Ṣimroni.
25 These are the families of Issachar according to those who were numbered of them, sixty-four thousand three hundred.
Wọ̀nyí ni ìdílé Isakari gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá méjìlélọ́gbọ̀n ó lé ọ̀ọ́dúnrún.
26 The descendants of Zebulun after their families: of Sered, the family of the Seredites; of Elon, the family of the Elonites; of Jahleel, the family of the Jahleelites.
Àwọn ọmọ Sebuluni gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Seredi, ìdílé Seredi; ti Eloni, ìdílé Eloni; ti Jaleeli, ìdílé Jaleeli.
27 These are the families of the Zebulunites according to those who were numbered of them, sixty thousand five hundred.
Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Sebuluni gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn tí iye wọn sì jẹ́ ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta.
28 The sons of Joseph after their families: Manasseh and Ephraim.
Àwọn ọmọ Josẹfu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; Manase àti Efraimu.
29 The descendants of Manasseh: of Makir, the family of the Makirites; and Makir became the father of Gilead; of Gilead, the family of the Gileadites.
Àwọn ọmọ Manase: ti Makiri, ìdílé Makiri (Makiri sì bí Gileadi); ti Gileadi, ìdílé àwọn ọmọ Gileadi.
30 These are the descendants of Gilead: of Abiezer, the family of the Abiezerites; of Helek, the family of the Helekites;
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Gileadi: ti Ieseri, ìdílé Ieseri; ti Heleki, ìdílé Heleki
31 and Asriel, the family of the Asrielites; and Shechem, the family of the Shechemites;
àti ti Asrieli, ìdílé Asrieli; àti ti Ṣekemu, ìdílé Ṣekemu;
32 and Shemida, the family of the Shemidaites; and Hepher, the family of the Hepherites.
àti Ṣemida, ìdílé àwọn ọmọ Ṣemida; àti ti Heferi, ìdílé àwọn ọmọ Heferi.
33 Zelophehad the son of Hepher had no sons, but daughters; and these are the names of the daughters of Zelophehad: Mahlah, and Noah, Hoglah, Milcah, and Tirzah.
(Selofehadi ọmọ Heferi kò sì ni ọmọkùnrin, bí kò ṣe ọmọbìnrin; orúkọ àwọn ọmọbìnrin ni Mahila, Noa, àti Hogla, Milka àti Tirsa).
34 These are the families of Manasseh; and those who were numbered of them were fifty-two thousand seven hundred.
Wọ̀nyí ni ìdílé Manase tí iye wọn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin.
35 These are the descendants of Ephraim after their families: of Shuthelah, the family of the Shuthelahites; of Beker, the family of the Bekerites; of Tahan, the family of the Tahanites.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Efraimu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: láti ọ̀dọ̀ Ṣutelahi, ìdílé àwọn ọmọ Ṣutelahi; ti Bekeri, ìdílé àwọn ọmọ Bekeri; ti Tahani, ìdílé àwọn ọmọ Tahani.
36 These are the descendants of Shuthelah: of Eden, the family of the Edenites.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ṣutelahi: ti Erani, ìdílé àwọn ọmọ Erani.
37 These are the families of the descendants of Ephraim according to those who were numbered of them, thirty-two thousand five hundred. These are the descendants of Joseph after their families.
Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Efraimu, àwọn tí a kà nínú wọn sì jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlógún ó lé lẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Josẹfu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
38 The descendants of Benjamin after their families: of Bela, the family of the Belaites; of Ashbel, the family of the Ashbelites; of Ahiram, the family of the Ahiramites;
Àwọn ọmọ Benjamini gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn nìyìí: tí Bela, ìdílé àwọn ọmọ Bela; ti Aṣbeli, ìdílé àwọn ọmọ Aṣbeli; ti Ahiramu, ìdílé àwọn ọmọ Ahiramu;
39 of Shuppim, the family of the Shuppimites; of Huppim, the family of the Huppimites.
ti Ṣufamu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣufamu; ti Hufamu, ìdílé àwọn ọmọ Hufamu.
40 The sons of Bela were Ard and Naaman: of Ard, the family of the Ardites; of Naaman, the family of the Naamanites.
Àwọn ọmọ Bela ní ipasẹ̀ Ardi àti Naamani nìyìí: ti Ardi, ìdílé àwọn ọmọ Ardi; ti Naamani, ìdílé àwọn ọmọ Naamani.
41 These are the descendants of Benjamin after their families; and those who were numbered of them were forty-five thousand six hundred.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Benjamini; gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn; àti àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé ẹgbẹ̀jọ.
42 These are the descendants of Dan after their families: of Shuham, the family of the Shuhamites. These are the families of Dan after their families.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Dani gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Ṣuhamu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣuhamu. Wọ̀nyí ni ìdílé Dani gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn.
43 All the families of the Shuhamites, according to those who were numbered of them, were sixty-four thousand four hundred.
Gbogbo ìdílé àwọn ọmọ Ṣuhamu, gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélọ́gbọ̀n ó lé irinwó.
44 The descendants of Asher after their families: of Imnah, the family of the Jimnaites; of Jishvi, the family of the Jishvites; of Beriah, the family of the Berites.
Ti àwọn ọmọ Aṣeri gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Imina, ìdílé àwọn ọmọ Imina; ti Iṣfi, ìdílé àwọn ọmọ Iṣfi; ti Beriah, ìdílé àwọn ọmọ Berii.
45 Of the descendants of Beriah: of Heber, the family of the Heberites; of Malkiel, the family of the Malkielites.
Ti àwọn ọmọ Beriah: ti Heberi, ìdílé àwọn ọmọ Heberi; ti Malkieli, ìdílé àwọn ọmọ Malkieli.
46 The name of the daughter of Asher was Serah.
(Orúkọ ọmọ Aṣeri obìnrin nì jẹ́ Sera.)
47 These are the families of the descendants of Asher according to those who were numbered of them, fifty-three thousand and four hundred.
Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Aṣeri gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá mẹ́rìndínlọ́gbọ̀n ó lé egbèje.
48 The descendants of Naphtali after their families: of Jahzeel, the family of the Jahzeelites; of Guni, the family of the Gunites;
Ti àwọn ọmọ Naftali gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Jasieli, ìdílé àwọn ọmọ Jaseeli: ti Guni, ìdílé àwọn ọmọ Guni;
49 of Jezer, the family of the Jezerites; of Shillem, the family of the Shillemites.
ti Jeseri, ìdílé àwọn ọmọ Jeṣeri; ti Ṣillemu, ìdílé àwọn ọmọ Ṣillemu.
50 These are the families of Naphtali according to their families; and those who were numbered of them were forty-five thousand four hundred.
Wọ̀nyí ni ìdílé ti Naftali gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, àwọn tí a kà nínú wọn jẹ́ ẹgbàá méjìlélógún ó lé egbèje.
51 These are those who were numbered of the children of Israel, six hundred one thousand seven hundred thirty.
Àpapọ̀ iye tí a kà nínú àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ ọgbọ̀n ọ̀kẹ́ ó lé ẹgbẹ̀sán dín làádọ́rin.
52 The LORD spoke to Moses, saying,
Olúwa sọ fún Mose pé,
53 "To these the land shall be divided for an inheritance according to the number of names.
“Ilẹ̀ náà gbọdọ̀ jẹ́ pínpín fún wọn gẹ́gẹ́ bí ogún wọn gẹ́gẹ́ bí iye orúkọ wọn.
54 To the more you shall give the more inheritance, and to the fewer you shall give the less inheritance: to everyone according to those who were numbered of him shall his inheritance be given.
Fún àwọn ọ̀pọ̀ ni kí ìwọ ó fún ní ogún ìlú púpọ̀ àti fún àwọn tí ó kéré ni kí ìwọ ó fi kékeré fún, ẹnìkọ̀ọ̀kan gbọdọ̀ gba ogún ìbí tirẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí a kọ.
55 Notwithstanding, the land shall be divided by lot: according to the names of the tribes of their fathers they shall inherit.
Rí dájú pé ilẹ̀ yìí gbọdọ̀ jẹ́ fífi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọn sì ti pọ̀ tó. Gẹ́gẹ́ bí orúkọ ẹ̀yà àwọn baba wọn ni kí wọn kí ó ni í.
56 According to the lot shall their inheritance be divided between the more and the fewer."
Olúkúlùkù ogún ìní ni a gbọdọ̀ fi ìbò pín gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti pọ̀ tó láàrín ńlá àti kékeré.”
57 These are those who were numbered of the Levites after their families: of Gershon, the family of the Gershonites; of Kohath, the family of the Kohathites; of Merari, the family of the Merarites.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Lefi tí a kà nínú wọn gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn: ti Gerṣoni, ìdílé àwọn ọmọ Gerṣoni; ti Kohati, ìdílé àwọn ọmọ Kohati; ti Merari, ìdílé àwọn ọmọ Merari.
58 These are the families of Levi: the family of the Libnites, the family of the Hebronites, the family of the Mahlites, the family of the Mushites, the family of the Korahites. Kohath became the father of Amram.
Wọ̀nyí ni ìdílé àwọn ọmọ Lefi; ìdílé àwọn ọmọ Libni, ìdílé àwọn ọmọ Hebroni, ìdílé àwọn ọmọ Mahili, ìdílé àwọn ọmọ Muṣi, ìdílé àwọn ọmọ Kora. (Kohati ni baba Amramu,
59 The name of Amram's wife was Jochebed, the daughter of Levi, who was born to Levi in Egypt: and she bore to Amram Aaron and Moses, and Miriam their sister.
orúkọ aya Amramu sì ń jẹ́ Jokebedi, ọmọbìnrin Lefi, tí ìyá rẹ̀ bí fún Lefi ní Ejibiti. Òun sì bí Aaroni, Mose, àti Miriamu arábìnrin wọn fún Amramu.
60 To Aaron were born Nadab and Abihu, Eleazar and Ithamar.
Aaroni ni baba Nadabu àti Abihu, Eleasari àti Itamari.
61 Nadab and Abihu died, when they offered strange fire before the LORD.
Ṣùgbọ́n Nadabu àti Abihu kú, nígbà tí wọ́n rú ẹbọ níwájú Olúwa nígbà tí wọ́n mú iná àjèjì wá.)
62 Those who were numbered of them were twenty-three thousand, every male from a month old and upward: for they were not numbered among the children of Israel, because there was no inheritance given them among the children of Israel.
Gbogbo àwọn ọmọkùnrin Lefi láti oṣù kan àti ju bẹ́ẹ̀ lọ ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ó lé lẹ́gbẹ̀rún. Wọn kò ka wọ́n mọ́ àwọn ọmọ Israẹli tókù nítorí tí wọ́n kò gba ogún ìní lára wọn.
63 These are those who were numbered by Moses and Eleazar the priest, who numbered the children of Israel in the plains of Moab by the Jordan at Jericho.
Àwọn wọ̀nyí ni Mose àti Eleasari àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Israẹli ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu lẹ́bàá odò Jordani létí Jeriko.
64 But among these there was not a man of them who were numbered by Moses and Aaron the priest, who numbered the children of Israel in the wilderness of Sinai.
Kò sí ẹnìkan nínú àwọn tí Mose àti Aaroni àlùfáà kà nígbà tí wọ́n ka àwọn ọmọ Israẹli ní aginjù Sinai.
65 For the LORD had said of them, They shall surely die in the wilderness. There was not left a man of them, except Caleb the son of Jephunneh, and Joshua the son of Nun.
Nítorí Olúwa ti sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kíkú ni wọn yóò kú sí aginjù, kò sì sí ẹnìkankan nínú wọn tí kò kú àfi Kalebu ọmọ Jefunne, àti Joṣua ọmọ Nuni.

< Numbers 26 >