< Hebrews 3 >

1 Therefore, holy brothers, comrades of a heavenly calling, fix your thoughts then upon Jesus, the Apostle and High Priest of our confession.
Nítorí náà ẹ̀yin ará mímọ́, alábápín ìpè ọ̀run, ẹ gba ti aposteli àti olórí àlùfáà ìjẹ́wọ́ wa rò, àní Jesu;
2 How faithful he was to the God who appointed him! For while Moses also was faithful in all God’s house,
ẹni tí o ṣe olóòtítọ́ si ẹni tí ó yàn án, bí Mose pẹ̀lú tí ṣe olóòtítọ́ nínú iṣẹ́ rẹ̀ gbogbo nínú ilé Ọlọ́run.
3 Jesus has been counted worthy of greater glory than Moses, inasmuch as he who has built a house has higher honor than the house itself.
Nítorí a ka ọkùnrin yìí ni yíyẹ sí ògo ju Mose lọ níwọ̀n bí ẹni tí ó kọ́ ilé ti lọ́lá ju ilé lọ.
4 For every house has its builder; but he who built the universe is God.
Láti ọwọ́ ènìyàn kan ni a sá à ti kọ́ olúkúlùkù ilé; ṣùgbọ́n ẹni tí ó kọ́ ohun gbogbo ni Ọlọ́run.
5 And Moses indeed was faithful in all his house as a servant, bearing testimony to a witness about to be spoken;
Mose nítòótọ́ sì ṣe olóòtítọ́ nínú gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ nínú ilé Ọlọ́run, bí ìránṣẹ́, fún ẹ̀rí ohun tí a ó sọ̀rọ̀ wọ́n ní ìgbà ìkẹyìn.
6 but Christ as a Son in his own house; and we are that house, if we retain the cheerful courage and pride of our hope firm unto the end.
Ṣùgbọ́n Kristi jẹ́ olóòtítọ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọ lórí ilé Ọlọ́run; ilé ẹni tí àwa jẹ́, bí àwa bá gbẹ́kẹ̀lé e, tí a sì di ìṣògo ìrètí wa mu ṣinṣin títí dé òpin.
7 Therefore, as the Holy Spirit says. If you hear God’s voice today,
Nítorí náà gẹ́gẹ́ bi Ẹ̀mí Mímọ́ tí wí: “Lónìí bí ẹ̀yin bá gbọ́ ohùn rẹ̀,
8 Continue not to harden your hearts as in the Provocation, On the day of temptation in the wilderness,
ẹ má ṣe sé ọkàn yín le, bí ìgbà ìṣọ̀tẹ̀, bí i ní ọjọ́ ìdánwò ní aginjù,
9 When your forefathers tried my forbearance And saw my deeds for forty years.
níbi tí àwọn baba yín ti dán mi wò, tí wọ́n sì rí iṣẹ́ mi ní ogójì ọdún.
10 For this reason I was sore displeased with that generation, And said, "They are always wandering in their hearts; They have never learned my ways";
Nítorí náà a mú inú bí mi si ìran náà, mo sì wí pé, ‘Nígbà gbogbo ni wọn ṣìnà ní ọkàn wọn; wọn kò sì mọ ọ̀nà mi.’
11 So I swore in my wrath, "They shall never enter into my rest."
Bí mo tí búra nínú ìbínú mi, ‘Wọn kí yóò wọ inú ìsinmi mi.’”
12 See to it, brothers, that there shall never be in any one of you an evil and unbelieving heart, manifesting itself in apostasy from the living God.
Ẹ kíyèsára, ará, kí ọkàn búburú ti àìgbàgbọ́ má ṣe wà nínú ẹnikẹ́ni yín, ní lílọ kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run alààyè.
13 On the contrary, encourage each other daily, so long as there is a "Today," so that no one of you is hindered by the deceitfulness of sin.
Ṣùgbọ́n ẹ máa gba ara yín ní ìyànjú ní ojoojúmọ́, níwọ̀n ìgbà tí a bá ń pè ní “Òní,” kí a má ba à sé ọkàn ẹnikẹ́ni nínú yín le nípa ẹ̀tàn ẹ̀ṣẹ̀.
14 For we are become comrades of the Christ, if we hold our first title deed firm until the very end.
Nítorí àwa di alábápín pẹ̀lú Kristi, bí àwa bá di ìpilẹ̀ṣẹ̀ ìgbẹ́kẹ̀lé wa mú ṣinṣin títí dé òpin.
15 In the words of Scripture, Today, if you hear his voice, Do not continue to harden your hearts as at the Provocation.
Nígbà tí a ń wí pé, “Lónìí bí ẹ̀yin bá gbọ́ ohùn rẹ̀, ẹ má sé ọkàn yin le, bí ìgbà ìṣọ̀tẹ̀.”
16 For who were they that heard and yet provoked him? Was it not all who came out of Egypt under the leadership of Moses?
Àwọn ta ni ó gbọ́ tí ó sì tún ṣọ̀tẹ̀? Kì í ha ṣe gbogbo àwọn tí o jáde kúrò ní Ejibiti ní abẹ́ àkóso Mose?
17 And with whom was he grieved for forty years? Was it not with those who had sinned, and whose dead bodies fell in the wilderness?
Àwọn ta ni ó sì bínú sí fún ogójì ọdún? Kì í ha ṣe sí àwọn tí ó dẹ́ṣẹ̀, òkú àwọn tí ó sùn ní aginjù?
18 And to whom did he swear that they should never enter into his rest, if not to those who had proved faithless?
Àwọn wo ni ó búra fún pé wọn kì yóò wọ inú ìsinmi òun, bí kò ṣe fún àwọn tí ó ṣe àìgbọ́ràn?
19 So you see that it was through unbelief that they were not able to enter in.
Àwa sì rí i pé wọn kò lè wọ inú rẹ̀ nítorí àìgbàgbọ́.

< Hebrews 3 >