< Zechariah 1 >
1 In the eighth month, in the second year of Darius, a word of YHWH has been to Zechariah, son of Berechiah, son of Iddo the prophet, saying,
Ní oṣù kẹjọ ọdún kejì ọba Dariusi, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah ọmọ Berekiah, ọmọ Iddo pé:
2 “YHWH was angry against your fathers—wrath!
“Olúwa ti bínú sí àwọn baba ńlá yín.
3 And you have said to them, Thus said YHWH of Hosts: Return to Me, A declaration of YHWH of Hosts, And I return to you, said YHWH of Hosts.
Nítorí náà sọ fún àwọn ènìyàn. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: ‘Ẹ padà sí ọ̀dọ̀ mi,’ báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘èmi náà yóò sì padà sí ọ̀dọ̀ yín,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
4 You will not be as your fathers, To whom the former prophets called, Saying, Thus said YHWH of Hosts: Please turn back from your evil ways and from your evil doings, And they did not listen, Nor attend to Me—a declaration of YHWH.
Ẹ má dàbí àwọn baba yín, àwọn tí àwọn wòlíì ìṣáájú ti ké sí wí pé, báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín,’ àti kúrò nínú ìwà búburú yín; ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fetí sí ti èmi, ni Olúwa wí.
5 Your fathers—where [are] they? And the prophets—do they live for all time?
Àwọn baba yín, níbo ni wọ́n wà? Àti àwọn wòlíì, wọ́n ha wà títí ayé?
6 Only, My words and My statutes, That I commanded My servants the prophets, Have they not overtaken your fathers? And they turn back and say: As YHWH of Hosts designed to do to us, According to our ways, and according to our doings, So He has done to us.”
Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi àti ìlànà mi, ti mo pa ní àṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì, kò ha tún bá àwọn baba yín? “Wọ́n sì padà wọ́n wí pé, ‘Gẹ́gẹ́ bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti rò láti ṣe sí wa, gẹ́gẹ́ bi ọ̀nà wa, àti gẹ́gẹ́ bí ìṣe wa, bẹ́ẹ̀ ní o ti ṣe sí wa.’”
7 On the twenty-fourth day of the eleventh month (it [is] the month of Sebat), in the second year of Darius, a word of YHWH has been to Zechariah, son of Berechiah, son of Iddo the prophet. [He was] saying:
Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kọkànlá, tí ó jẹ́, oṣù Sebati, ní ọdún kejì Dariusi, ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ wòlíì Sekariah, ọmọ Berekiah ọmọ Iddo wá, pé.
8 I have seen by night, and behold, one riding on a red horse, and he is standing between the myrtles that [are] in the shade, and behind him [are] horses, red, bay, and white.
Mo rí ìran kan ni òru, si wò ó, ọkùnrin kan ń gun ẹṣin pupa kan, òun sì dúró láàrín àwọn igi maritili tí ó wà ní ibi òòji; lẹ́yìn rẹ̀ sì ni ẹṣin pupa, adíkálà, àti funfun gbé wà.
9 And I say, “What [are] these, my lord?” And the messenger who is speaking with me says to me, “I show you what these [are].”
Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni wọ̀nyí olúwa mi?” Angẹli tí ń ba mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Èmi ó fi ohun tí àwọn wọ̀nyí jẹ́ hàn ọ́.”
10 And the one who is standing between the myrtles answers and says, “These [are] they whom YHWH has sent to walk up and down in the land.”
Ọkùnrin tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili sì dáhùn ó sì wí pé, “Wọ̀nyí ní àwọn tí Olúwa ti rán láti máa rìn sókè sódò ni ayé.”
11 And they answer the Messenger of YHWH who is standing between the myrtles, and say, “We have walked up and down in the land, and behold, all the land is sitting still, and at rest.”
Wọ́n si dá angẹli Olúwa tí ó dúró láàrín àwọn igi maritili náà lóhùn pé, “Àwa ti rìn sókè sódò já ayé, àwa sí ti rí i pé gbogbo ayé wà ní ìsinmi àti àlàáfíà.”
12 And the Messenger of YHWH answers and says, “YHWH of Hosts! Until when do You not pity Jerusalem, and the cities of Judah, that You have abhorred these seventy years?”
Nígbà náà ni angẹli Olúwa náà dáhùn ó sì wí pé, “Olúwa àwọn ọmọ-ogun, yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ kì yóò fi ṣàánú fún Jerusalẹmu, àti fún àwọn ìlú ńlá Juda, ti ìwọ ti bínú sí ni àádọ́rin ọdún wọ̀nyí?”
13 And YHWH answers the messenger, who is speaking with me, good words, comfortable words.
Olúwa sì fi ọ̀rọ̀ rere àti ọ̀rọ̀ ìtùnú dá angẹli tí ń bá mi sọ̀rọ̀ lóhùn.
14 And the messenger who is speaking with me, says to me, “Call, saying, Thus said YHWH of Hosts: I have been zealous for Jerusalem, And for Zion [with] great zeal.
Angẹli ti ń bá mi sọ̀rọ̀ sì wí fún mi pé, “Ìwọ kígbe wí pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi ń fi ìjowú ńlá jowú fún Jerusalẹmu àti fún Sioni.
15 And [with] great wrath I am angry against the nations who are at ease, For I was a little angry, and they assisted—for evil.
Èmi sì bínú púpọ̀púpọ̀ si àwọn orílẹ̀-èdè tí ó rò wí pé òun ní ààbò. Nítorí nígbà tí mo bínú díẹ̀, wọ́n ran ìparun lọ́wọ́ láti tẹ̀síwájú.’
16 Therefore, thus said YHWH: I have turned to Jerusalem with mercies, My house is built in it, A declaration of YHWH of Hosts, And a line is stretched over Jerusalem.
“Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí: ‘Mo padà tọ Jerusalẹmu wá pẹ̀lú àánú; ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, a ó kọ́ ilé mi sínú rẹ̀, a o sí ta okùn ìwọ̀n kan jáde sórí Jerusalẹmu.’
17 Again call, saying, Thus said YHWH of Hosts: Again My cities overflow from good, And YHWH has again comforted Zion, And He has fixed again on Jerusalem.”
“Máa ké síbẹ̀ pé, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘A o máa fi ìre kún ìlú ńlá mi síbẹ̀; Olúwa yóò sì máa tu Sioni nínú síbẹ̀, yóò sì yan Jerusalẹmu síbẹ̀.’”
18 And I lift up my eyes, and look, and behold, four horns.
Mo si gbé ojú sókè, mo sì rí, sì kíyèsi i, ìwo mẹ́rin.
19 And I say to the messenger who is speaking with me, “What [are] these?” And he says to me, “These [are] the horns that have scattered Judah, Israel, and Jerusalem.”
Mo sì sọ fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ pé, “Kí ni nǹkan wọ̀nyí?” Ó si dà mí lóhùn pé, “Àwọn ìwo wọ̀nyí ni ó tí tú Juda, Israẹli, àti Jerusalẹmu ká.”
20 And YHWH shows me four artisans.
Olúwa sì fi alágbẹ̀dẹ mẹ́rin kan hàn mí.
21 And I say, “What [are] these coming to do?” And He speaks, saying, “These [are] the horns that have scattered Judah, so that no one has lifted up his head, and these come to trouble them, to cast down the horns of the nations who are lifting up a horn against the land of Judah—to scatter it.”
Nígbà náà ni mo wí pé, “Kí ni àwọn wọ̀nyí wá ṣe?” O sì sọ wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìwo tí ó ti tú Juda ká, tó bẹ́ẹ̀ tí ẹnikẹ́ni kò fi gbé orí rẹ̀ sókè? Ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí wá láti dẹ́rùbà wọ́n, láti lé ìwo àwọn orílẹ̀-èdè jáde, ti wọ́n gbé ìwo wọn sórí ilẹ̀ Juda láti tú ènìyàn rẹ̀ ká.”